Pakistan: Àgbájọ èèyàn sẹkúpa ọkùnrin kan lórí ẹ̀sùn pé ó dáná sun Kurani

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Agbarijọpọ àwọn eeyan kan ti ṣekupa ọkunrin kan ni aaringbungbun Pakistan lori ẹsun pe o dana sun awọn abala Kurani kan.
Ileeṣẹ ọlọpaa ni awọn ti ọwọ ofin mu ọgọrin eeyan lori iṣẹlẹ naa to waye lọjọ Abamẹta lẹkun Khanewal ni Punjab.
Iroyin kan tiẹ sọ agọ ọlọpaa ni ọkunrin naa wa ki awọn ero kan to lọ ji gbe lati ṣekupa a.
Ileeṣẹ ọlọpaa ti gbe oku ọkunrin naa fun awọn ẹbi rẹ fun eto isinku lọjọ Aiku.
- Kọmísánnà ọlọ́pàá ní London kọ̀wé fi ipò sílẹ̀ torí ìkéde a kò nígbẹkẹ̀lé nínú rẹ mọ́
- Àwọn jàndùkú agbébọn tún kọlu ilé Sunday Igboho, èèyàn kan dèrò ọ̀run
- Igi ẹ̀fọ́, ojú ẹlẹ́gba àti oríṣi orúkọ̀ míì ní wọ́n ń pè mí nítorí pé Òbí mi kọlà sí ojú mi- Damilola
- Eló ló lè mú ọ kópa nínú idíje ata jíjẹ?
- Aáyán d'owó, kà nípa àgbẹ̀ tó di olówó nípasẹ̀ ọ̀sìn aáyán
- Ìjọba Guinea-Bissau di ẹbi ìdìtẹ̀gbàjọba tó foríṣánpọ́n rú àwọn tó ń ṣe fàyàwọ́ oògùn olóró
- Ìdí tí mo fi ní ọ́jọ́ ikú ni ọ̀la ọjọ́ 'Valentine' fún àwọn kan- Mike Bamiloye
Olootu ijọba Pakistan sọrọ lori iṣẹlẹ naa
Ẹwẹ, olootu ijọba orilẹede Pakistan, Imran Khan ti ṣeleri pe iwadii yoo waye lori iṣẹlẹ naa.
Khan ti wa beere lọwọ ileeṣẹ ọlọpaa lati foun ni orukọ awọn ọlọpaa to yẹ ki wọn daabo bo ọkunrin naa ṣugbọn ti wọn kuna lati ṣiṣẹ wọn.
Olootu ijọba Pakistan ni ijọba oun ko ni fi oju ire wo ẹnikẹni to ba n tapa sofin ilẹ naa.
Ileeṣẹ ọlọpaa ṣalaye bi iṣẹlẹ naa ti waye
Ọkan lara awọn ọlọpaa, Munawar Hussain ṣalaye pe niṣe lawọn kan ri pe ọkunrin naa ko le sọrọ mọ nibi ti wọn ti de e mọ igi.
Hussain ni ''awọn eeayan ilu naa mu kondo, aake ati irin dani eleyii ti wọn fi pa ọkunrin naa.
Ori igi kan ni wọn gbe oku rẹ si.
Munawar Gujjar, to jẹ ọga ọlọpaa ni Tulamba nibi ti iṣẹlẹ naa ti waye sọ fawọn akọroyin pe ọkunrin ọhun ti larun ọpọlọ fun bi ọdun mẹdoogun.
- Ìjọba Guinea-Bissau di ẹbi ìdìtẹ̀gbàjọba tó foríṣánpọ́n rú àwọn tó ń ṣe fàyàwọ́ oògùn olóró
- Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ tọkọtaya tó gbé ẹ̀yà ara ènìyàn pamọ́ sínú yàrá l'Ogun
- Ọ̀pọ̀ àgbà òṣèré tíátà péjú sí Ede láti sin Tafa Oloyede déle ìkẹyìn
- Kọmísánnà ọlọ́pàá ní London kọ̀wé fi ipò sílẹ̀ torí ìkéde a kò nígbẹkẹ̀lé nínú rẹ mọ́
- Ẹgbẹ́ Olùkọ́ Fásitì ASUU bẹ̀rẹ̀ ìyanṣẹ́lódì olóṣù kan lónìí
- Tí o bá ń pẹ́ jẹun alẹ́, o lè ní àrùn jẹjẹrẹ ọyàn àti asétọ̀
Iṣẹlẹ yii waye lẹyin oṣu meji tawọn eeyan kan lu ọga ileeṣẹ kan pa ni ileeṣẹ Sri Lanka kan ti wọn si tun dana sun un lori ẹsun pe o sọrọ idi tako ẹsin niluu Sialkot eyi to wa ni ẹkun Punjab kan naa.
Ijiya fun ẹni to ba sọrọ odi si ẹsin Islam ni Pakistan le jasi iku.
Amọ, ọpọ lo ti bu ẹnu atẹ lu ofin naa pe idẹyẹsi lo jẹ si awọn ti kii ṣe ẹlẹsin Islam.
Ofin yii ni wọn n lo lati yanju ede-ai-yede to ba ṣẹlẹ laarin awọn eeyan ṣugbọn ti ko ni ohun kan ṣe pẹlu ẹsin.





















