Nnamdi Kanu court trial: Iléẹjọ́ tún sún ìgbẹ́jọ́ olórí ẹgbẹ́ IPOB Nnamdi Kanu síwájú

Ileẹjọ tun ti sun igbẹjọ olori ẹgbẹ ajijagbara nilẹ Ibo, IPOB, Nnamdi Kanu niluu Abuja siwaju.
Kanu foju ba ileẹjọ ni Ọjọru lori ẹsun igbesunmọmi, pipe fun iyapa ẹya Ibo lara Naijiria ati gbigbe irọ kiri nipa aarẹ Muhammadu Buhari.
Ijọba tun fikun awọn ẹsun ti wọn kan Kanu ninu igbẹjọ to waye ni oṣu kinni ọdun 2022 yii.
- Afurasí tọkọtaya ta ẹ̀yà ara ní ẹgbẹ̀rún lọ́nà àádọ́rin náírà- Ọlọ́pàá
- Awakọ̀ dáná sun ara rẹ̀ lórí bí àwọn 'task force' ṣe mu l'Eko
- Títí di àsìkò yìí, a kò tíì mọ̀ eèyàn ti òkú náà jẹ́ ṣùgbọ́n a ti bẹ̀rẹ̀ ìgbésẹ̀ ìwádìí tó yẹ Ogá Ọlọ́pàá Ogun
- Àgbáríjọpọ̀ èèyàn sẹkúpa ọkùnrin kan lórí ẹ̀sùn pé ó dáná sun Kurani
- Àwọn tọ́ọ̀gì Aregbesola ló da wàhálà sílẹ̀ l'Osun - Ọlọ́pàá
- Olaleye Paul rí ẹ̀wọ̀n he ní àyájọ́ olólùfẹ́ ní Ilọrin
- Wo ọkùnrin kan tó fi N1.2m gbẹ́ ibojì rẹ̀ sílẹ̀ nígbà tó sì wà láàyè
Ṣugbọn ti sọ pe oun ko jẹbi gbogbo ẹsun ti wọn fi kan oun.
Amọ, adajọ Binta Nyako ileẹjọ giga ijọba apapọ niluu Abuja ti sun igbẹjọ naa di ọjọ kẹjọ oṣu kẹrin ọdun yii.
Kanu ti n pe fun iyapa ẹya Ibo kuro lara Naijiria tipẹ, o ni ki awọn Ibo da orilẹede Biafra silẹ.
Kanu to ni iwe igbeluu ilẹ Gẹẹsi ati orilẹede Naijiria lọwọ da ẹgbẹ IPOB silẹ ni nkan bi ọdun mẹwaa sẹyin.
Nnamdi Kanu yóò tún fojú balé ẹjọ́ lónìí, oun tó lè ṣẹlẹ̀ rèé
Igbẹjọ adari awọn ajijagbara Biafra, IPOB, Nnamdi Kanu yoo tẹsiwaju lonii, ọjọ kẹrindinlogun, oṣu Keji, ọdun 2022, nile ẹjọ giga to wa niluu Abuja.
Kanu n koju ẹsun marun un ọtọtọ to da lori igbesumọmi, iṣọtẹ, iyapa ati jijẹ ọkan lara awọn ọmọ ẹgbẹ ti ijọba apapọ ti fofin de.
Wọn tun fẹsun kan Kanu pẹ o n kede awọn ọrọ kobakungbe nipa Aarẹ Muhammadu Buhari, amọ o ti sọ pe oun ko jẹbi ọkankan ninu gbogbo ẹsun naa.
- Ìjọba Canada ṣetán láti gbẹ́sẹ̀ lé àkáùntì àwọn tó ń ṣẹ ìwọ́de táko abẹ́rẹ́ covid-19
- EFCC gbẹ́sẹ̀lé dúkìá ọ̀gá olọgun tí iye rẹ̀ tó ₦10.9b
- Olaleye Paul rí ẹ̀wọ̀n he ní àyájọ́ olólùfẹ́ ní Ilọrin
- Wo ọkùnrin kan tó fi N1.2m gbẹ́ ibojì rẹ̀ sílẹ̀ nígbà tó sì wà láàyè
- Awakọ̀ dáná sun ara rẹ̀ lórí bí àwọn 'task force' ṣe mu l'Eko
Lẹyin ti Kanu ti kọkọ sọ pe oun ko jẹbi afikun ẹsun marundinlogun ti ijọba apapọ fi kan, agbẹjọro ijọba apapọ, Shuiabu Labaran, rọ adajọ to n gbọ ejọ ọhun, Binta Nyako, lati tete bẹrẹ ẹjọ naa.
Labaran sọ pe awọn ti ni awọn eeyan nilẹ ti yo jẹri tako Kanu.
Ẹwẹ, agbẹjọro Kanu, Mike Ozekhome, to jẹ agbẹjọro agba ni Najiiria, ni oun ko ni gba ki ẹjọ naa bẹrẹ nitori awọn ti pe ẹjọ meji tako ẹjọ ti ijọ apapọ pe tako Kanu.
O ni ohun ti awọn n fẹ ni ki ile ẹjọ naa da ẹjọ ti wọn pe tako Kanu nu, ki wọn si tu silẹ ahamọ lọna ati le maa lọ sile rẹ layọ ati alaafia.
Lẹyin naa ni adajọ to n gbọ ẹjọ naa sun si oni, ọjọ Kẹrindinlogun, oṣu Keji, ti a wa yii.
Ohun to le ṣẹlẹ̀ nibi igbẹjọ naa lonii
Ile ẹjọ naa ti sọ pe aago kan ọsan ni igbẹjọ naa yoo bẹrẹ.
Ile ẹjọ ọhun tun paṣẹ pe ki awọn agbofinro maṣe di awọn ọna to yi ile ẹjọ naa ka ki awọn eeyan miran to ni ẹjo le ri aye wọ ile ẹjọ.
Ẹwẹ, iroyin ni o ṣeeṣe ki agbẹjọro Kanu pe ẹjọ tako ibi ti igbẹjọ naa ti n waye nitori bi ijọba Naijiria ṣe ji olubara rẹ gbe lati orilẹ-ede miran wa si Naijiria.

















