Osun Crisis Oyetola and Aregbesola: Wọ́n fẹ́ ṣe ìkọlù sí ọkọ̀ Aregbesola la ṣe da ìbọn bolẹ̀ - NSCDC

Oríṣun àwòrán, Others
Àwọn tọ́ọ̀gì Aregbesola ló da wàhálà sílẹ̀ l'Osun - Ọlọ́pàá
Àjọ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Osun ti di ẹ̀bi làásìgbò tó wáyé lọ́jọ́ Ajé, ní agbègbè Old Garage, Osogbo, olú ìlú ìpínlẹ̀ náà ru Mínísítà fọ́rọ̀ Abẹ́lẹ́, Rauf Aregbesola.Aregbẹsọla kìí ṣe Olọ́run, iṣẹ́ Oyetola ló máa fọhùn lọ́jọ́ ìdìbò- Ismail Omipidan
Àtẹ̀jáde kan látọwọ́ agbẹnusọ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Osun, Yemisi Opalola lọ́jọ́ Ìṣẹ́gun ní ṣàdédé ní àwọn ẹ̀ṣọ́ aláàbò ààbò ara ẹni làbò ìlú, NSCDC àti ti Immigration tí wọ́n kọ́wọ̀ọ́ rìn pẹ̀lú Aregbesola dédé da ìbọn bolẹ̀ ní Old Garage àti MDS nígbà tí wọ́n ń kọjá níbẹ̀.
- Nnamdi Kanu yóò tún fojú balé ẹjọ́ lónìí, oun tó lè ṣẹlẹ̀ rèé
- EFCC gbẹ́sẹ̀lé dúkìá ọ̀gá olọgun tí iye rẹ̀ tó ₦10.9b
- Ìjọba Canada ṣetán láti gbẹ́sẹ̀ lé àkáùntì àwọn tó ń ṣẹ ìwọ́de táko abẹ́rẹ́ covid-19
- Olaleye Paul rí ẹ̀wọ̀n he ní àyájọ́ olólùfẹ́ ní Ilọrin
- Wo ọkùnrin kan tó fi N1.2m gbẹ́ ibojì rẹ̀ sílẹ̀ nígbà tó sì wà láàyè
- Afurasí tọkọtaya ta ẹ̀yà ara ní ẹgbẹ̀rún lọ́nà àádọ́rin náírà- Ọlọ́pàá
- Awakọ̀ dáná sun ara rẹ̀ lórí bí àwọn 'task force' ṣe mu l'Eko
Opalola ní ìbọn yínyìn yìí dá ìfòyà sọ́kàn àwọn ara àdúgbò náà, tí wọ́n sì ń sá àsálà fún ẹ̀mí wọn àti pé ọta ibọn mẹ́tàlá ni àwọn ṣà nílẹ̀ lẹ́yìn tí ọkọ̀ Mínísítà náà lọ tán.
Ó ní ìwà yìí kò dára tó bó ṣe jẹ́ dída àláfíà àwọn ara ìlú láàmú ṣùgbọ́n tó ní ẹnìkankan kò farapa níbẹ̀.
Kí ni ajọ aṣọ alaabo NSCDC wí?
Ẹ̀wẹ̀, agbẹnusọ àjọ ẹ̀ṣọ́ ààbò ara ẹni làbò ìlú, NSCDC, tẹ̀ka ìpínlẹ̀ Osun, Olabisi Atanda ní àwọn ọmo ìta kan ló fẹ́ ṣe ìkọlù sí ọkọ̀ gómìnà àná ní ìpínlẹ̀ náà lásìkò tó ń kọjá ní Old Garage ni àwọn ṣe da ìbọn bolẹ̀.
Nínú àtẹ̀jáde kan tó fi síta, Atanda ní nǹkan bí aago méje ku ogún ìṣẹ́gún ní àwọn ọmọ gàǹfé náà gbìyànjú láti ṣe ìkọlù sí ọkọ̀ Aregbesola ṣùgbọ́n tí àwọn tètè rí ìkápá lórí rẹ̀ bá àwọn ẹ̀ṣọ́ aláàbò tó tẹ̀lé Mínísítà náà ṣe jí gìrì sí ojúṣe wọn.
Bákan náà ló ní, ọ̀gá àgbà àjọ NSCDC ìpínlẹ̀ Osun, Emmanuel Ocheja ti sọ àrídájú rẹ̀ pé àjọ náà kò ní kùnà láti pèsè ètò ààbò tó péye fún àwọn ara ìlú nígbà gbogbo.
Kí ló ti ṣẹlẹ̀ sẹ́yìn?
Ní ọjọ́ Ìṣẹ́gun ni àwọn olùfẹ̀hónúhàn yabo ọ́fììsì àjọ NSCDC tó wà ní ìlú Osogbo lórí bí wọ́n ṣe dàbọn bolẹ̀ nígbà tí ọkọ̀ Mínísítà Rauf Aregbesola kọjá ní agbègbè Old Garage ní Osogbo.
Àwọn olùfẹ̀hónúhàn náà lábẹ́ àpapọ̀ ẹgbẹ́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ìpínlẹ̀ Osun (NAOSS) gbé onírúurú àkọ́lé lọ́wọ́ bíi "NSCDC ń dúnkokò mọ́ àwọn ènìyàn wa l'Osun", "NSCDC ṣe ààbò wà fún wa", "NSCDC, nítorí ààbò la ṣe gbà yín kìí ṣe láti pa àwọn ènìyàn wa", àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ.
Ààrẹ NAOSS, Moshood Yusuf nígbà tó ń bá àwọn akọ̀ròyìn sọ̀rọ̀ lẹ́yìn tó ṣàgbékalẹ̀ ìwé ìpẹ̀jọ̀ tí wọ́n kọ sí ọ̀gá NSCDC ní àwọn òṣìṣẹ́ tó lọ́wọ́ níbi ìbọn tí wọ́n yìn náà gbọ́dọ̀ fojú winá òfin.
Ṣaájú, àjọ NSCDC kò fẹ́ kí àwọn olùfẹ̀hónúhàn náà rí ààyè wọ inú ọgbà wọn tí wọ́n sì ṣe àwọn akọ̀ròyìn tó wà níbẹ̀ léṣe.
IPAC dá sí aáwọ̀ Aregbesola àti Oyetola
Ìgbìmọ̀ tó ń rí sí ìpẹ̀tùsááwọ̀ àárín àwọn ẹgbẹ́ òṣèlú, (IPAC) ti rọ àwọn Aregbesola àti Gómìnà Gboyega Oyetola láti gba àláfíà láàyè kí ìpínlẹ̀ Osun le tẹ̀ síwájú.
Alága IPAC, Wale Adebayo, ní ìfaǹfà tó ń wáyé láàárín àwọn àgbà olóṣèlú méjéèjì yìí le dogun dọ̀tẹ̀ ní ìpínlẹ̀ náà tí wọn kò bá kíyè sára.
Ó fi kun pé yóò tún ṣàfihàn ìpínlẹ̀ Osun lọ́nà tí kò dára sí aráyé.





















