Prophet Israel Oladele: Wo díẹ̀ lára àwọn ìwàásù mánigbàgbé tí wòlíì ìjọ CCC Genesis Global ti ṣe

Oríṣun àwòrán, Facebook/Genesis Global
Ọpọ awọn eeyan kaakiri Naijiria lo ti n sọrọ lori iru iranṣẹ Ọlọrun ti wolii Israel Oladele Ogundipe jẹ Lẹyin ti ile ẹjọ kan ni ipinlẹ Eko ran lọ si ẹwọn ọdun meji lori ẹsun gbajuẹ.
Bi awọn kan ṣe n sọ nipa awọn ore to ti ṣe fun tile-toko, lawọn miran n sọ nipa awọn iwaasu manigbagbe to ti ṣe ati awọn to da lọla lori aga iwaasu.
Lara awọn iwaasu wolii Israel Oladele Ogundipe ree:
- Wo àwọn èèkàn, ìlúmọ̀ọ́ka olórin tó ṣàbẹ̀wò sí ijọ Celestial Church ti Genesis Global
- Wòlíì míì, tún wọ gàù lẹ́yìn tó tàpá sí ìlànà béèlì tí wọ́n fún un nílé ẹjọ́
- Ṣé Sanwo-Olu, gómìnà Eko yóò farahàn níwájí ìgbìmọ̀ olùwádìí ìṣẹ̀lẹ̀ Lekki Tollgate?
- CCC Genesis Global: Ǹkan mẹ́wàá tí ẹ ò gbọ́ rí nípa Israel Oladele, Woli ìjọ Genesis Global
Ko yẹ ki ibalopọ ju iṣẹju marun un pere lọ
Oṣu kọkanla ọdun 2019 ni fidio iwaasu wolii Oladele kan fa oju ayelujara ye, nibi to ti sọ pe ko yẹ ki ibalopọ laarin lọkọlaya ju iṣeju marun un pere lọ.
Ninu iwaasu naa ni wolii ọhun ti sọ pe "ibalopọ to ba ti ju iṣeju marun lọ kii ṣe ibalopọ mọ, nitori ibalopọ aladun ko gbọdọ ju iṣeju marun un lọ."

Oríṣun àwòrán, Facebook/Genesis Global
O tẹsiwaju pe "alalubarika ọkunrin to mọ pe ọna oun jin ko ni maa dunu pe oun lo ọgbọn iṣeju lori obinrin."
- Ẹ̀tanú pé Olùṣọ́ Genesis kò fẹ́ Laide Williams-Oni ló ṣe rán an lọ́ sí ẹ̀wọ̀n ọdún kan - CCC Genesis Global
- A kò tíì lè sọ pé ọmọ Ọba tuntun ni yóò jẹ Ooni lọ́jọ́ iwájú - Elebuibọn
- Ọkùnrin tó pe ìyàwó rẹ̀ lájẹ̀ẹ́ tì í mọ́lé fọ́dún mẹ́rin, fún un lóyún nígbà mẹ́ta!
- Bàbá mi, ẹ yé fi mí gba ìràwọ̀, ọmọbìnrin Charly Boy, Dewy Oputa fárígá fún bàbá rẹ̀
Oladele sọ pe aṣiwere ni ọkunrin to ba n dunnu pe oun lo nnkan bi ọgbọn iṣẹju lati fi ba oninrin ni ibalopọ.
Wolii naa ni ọgbọn iṣeju ti awọn kan fi wa lori obninrin ni awọn miran fi n ka owo gọbọi.
Maṣẹ gbe ọrọ ọlọrọ lori

Oríṣun àwòrán, Genesis Global
Lara awọn iwaasu manigbagbe ti wolii Oladele ti ṣe ni bo ṣe maa n kọ awọn ọmọ ijọ rẹ lati foju si iṣẹ wọn, ki wọn si ma sọrọ ẹnikeji lẹyin.
- Ṣé lóòtọ́ ni ìgbìmọ̀ olùwádìí dábàá kí Ààrẹ Buhari yọ alága EFCC, Ibrahim Magu nípò?
- A dúro bí iké lẹ́yìn ìròyìn táa gbé jáde nípa Lekki Tollgate; CNN tako Lai Mohammed
- DSS ṣèlérí iwadìí tí kò rújú lórí bí òṣìṣẹ́ rẹ̀ kan ṣe yìnbọn pa fẹ́ńdọ̀ lẹ̀yìn Gbajabiamila
- Saka ń wá ọ̀rẹ́ rẹ̀ kan nítorí aṣọ kóòtù ọdún 34 sẹ́yìn
Ninu iwaasu rẹ kan to ṣe ninu oṣu Kẹjọ, ọdun 2020, Oladele ni "okoowo to lamilaaka julọ nile aye ni ki eeyan gbaju mọ iṣẹ rẹ."
Nibẹ lo ti sọ fun awọn ọmọ ijọ rẹ pe, ki wọn ma ṣe maa da si ọrọ ti ko kan wọn, ki wọn si ma ṣeyọnu nipa ẹni ti ko ba fẹran wọn.
Oladele da obinrin kan lọla ninu iwaasu
Ọdun 2018 ni Oladele da obinrin lọla ti ko ro tẹlẹ ninu ijọ rẹ.
Ohun to ṣẹlẹ lọjọ naa ni pe bi wolii ọhun ṣe n waasu lọwọ ni awọn ọmọ ijọ bẹrẹ si n fi owo si ẹsẹ rẹ gẹgẹ bi iṣe wọn.
Ṣugbọn kaka to yẹ ki owo naa jẹ wolii ọhun, ni ṣe lo pe obinrin kan sita, to si ni ki obinrin naa ma ko gbogbo owo ọhun lọ.
O ni Ọlọrun sọ fun oun pe ki oun ko gbogbo naa fun oninrin ọhun.
Gẹgẹ bo ṣe sọ, o ni obinrin naa ko bere owo lọwọ ohun, ṣugbọn oun gbe igbesẹ naa nitori oun ti ṣe alaini ri, ati pe Oluwa lo ni ki oun ṣe bẹẹ.
Fifariga àwọn ẹ́ka ijọ Celestial mii pe o gbe olorin aye wa sinu ijọ mimọ
Wasiu Ayinde K1 De Ultimate

Oríṣun àwòrán, Genesis Global
Alhaji Wasiu Ayinde K1 De Ultimate naa lara awọn ilumọọka to ti ṣabẹwo si ijọ Celestial CCC (GENESIS) labẹ akoso pasitọ Ogundipe.
K1 De Ultimate ṣere ninu ijọ naa pẹlu awọn ọmọlẹyin rẹ.
Alhaji Ayinde kọ ninu orin nibẹ pe ayọ ni fun gbogbo awọn ijọ Genesis ati fun oun naa to fi mọ idile oun.
Wasiu tun kọ ninu orin pe awọn to n binu Pasitọ Ogundipe le maa binu lasan nitori ẹni ti Ọlọrun gba fun un ni.
K1 De Ultimate tun ki gbogbo awọn alatilẹyin Pasitọ Oladele ninu orin rẹ bakan naa.
Pasitọ Ogundipe naa dupẹ lọwọ K1 De Ultimate pẹlu idọbalẹ, bakan naa lo tun gbadura fun olorin naa.


















