Erelu Elemure: Ìyá mi rò pé mi ò lè tibi kíkọrin bíi bàbá mi là

Àkọlé fídíò, Tí mo ba ti múra bí ọkùnrin fi kọrin, kò sí ọ̀dọ̀ ààrẹ́ tí mi ò lè wọ̀- Erelu, ọmọ Elemure Ekiti

Yoruba ni bi baba ba ku, baba nii kù. Adia fun ọmọ bibi inu gbajugbaja olorin ilu Ekiti, Elemure Ogunyemi ti gbogbo eeyan mọ si Elemure iyẹn Funmilayo Elemure to fiwa jọ baba ninu gbogbo nkan.

Erelu Elemure ni orukọ itage rẹEde Ekiti kan naa ti baba rẹ, Peter Ogunyemi elemure to ti di oloogbe bayii ma fi n kọ orin loun naa nlo, koda bii ọkunrin lo yan lati maa mura ninu ẹwu bii Agbada, Sokoto ati sọọrọ.

Gẹgẹ bo ṣe ṣalaye fun BBC Yoruba, ara ọtọ to n gba mura lo n fun un ni ọgbọn atinuda fun iṣẹ rẹẹ bẹẹ si ni o ni oun n ri iyi ati ọwọ gba latara eyi.

O sọ bi iya rẹ ṣe kọkọ sọ ireti nu ninu oun to yan laayo yii to si sọ fun un pe ko le ṣe oriire nibẹ amọ ṣe ni ohun ati ilu ijo mama gan yipada nigba tinkan ti ọmọ rẹ, Erelu elemure n ṣe bayii ti di iwuri nla fun un.