Ọọni Adeyeye gbé orúkọ àrẹ̀mọ rẹ̀ jáde, ẹ kọ́ ẹ̀kọ́ nípa àwọn ǹkan tí wọ́n fi gbàdúrà f'ọ́mọ ọba

Oríṣun àwòrán, Ooniadimula
Ilẹ Yoruba ni asa isọmọlorukọ ara ọtọ
Bẹẹ idalu kuku ni iṣelu ni awon agba n sọ.
Awọn ohun eelo ati ohun ti ẹnu n jẹ ni awọn agba maa n ko sita fi ṣadura fun ikoko tuntun ti a ba bi nilẹ oodua.
Ni ọjọ mẹjọ si ni ikomọjade ọmọ tuntun nilẹ Yoruba.
Isomọlorukọ ọmọ tuntun ti o jẹ arole Oọni Ifẹ: Kílódé tí Ọọni Ife, Oba Ogunwusi kò fi gbọdọ̀ rí ọmọ rẹ̀ tuntun ti Olorì Naomi bí títí di bíi ẹ̀yìn oṣù mẹ́fà?
Ni ibi isọmọlorukọ Arẹmọ Oba Adeyey Ogunwusi, Ojaja I to jẹ Oọni Ile Ife ni awọn ohun eelo ikomọjade tun ti jade.
Oyin. Orogbo, Obi, Iyọ suga, Ireke, Aadun, Igbin, Ẹja, ỌtiṢinaapu ati awọn nkan miran ni awọn agbaagba lo lati fi sọ ọmọ tuntun ti a bi na ni orukọ.
Awọn ohun eelo yii mu awọn adura ati asọtẹlẹ da ni fun ẹjẹ ọrun tuntun naa ni eyi to n mu aṣẹ dani ninu igbagbọ iran Yoruba.
- Àpò òfìfo ni a bá nígbà tí a gbàjọba lọ́dún 2015, ṣùgbọ́n a ti ṣiṣẹ́ ribiribi - Ìjọba àpapọ̀
- Ọwọ́ Interpol àti ọlọ́pàá Nàìjíríà ti tẹ ọmọ Nàìjíríà mẹ́ta tó lu èèyàn 50,000 ní gbájúẹ̀
- Àwọn Olúkọ ìpínlẹ̀ Oyo fakọyọ lórí ètò Akọ́mọlédè àti Àṣà púpọ̀
- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá palẹ̀ òkú ọmọ ọjọ́ kan mọ́ lẹ́yìn t́i wọ́n jùú sórí ààtàn
- Omotara kan ìdin nínú iyọ̀, àwọn ọmọ ilẹ̀ Faranse náà bínú síi nítorí alágbe tó fi ṣe yẹ̀yẹ́.
Taa ni Ọọni àná tí Ọba Ogunwusi forúkọ ọmọ rẹ̀ sọ?
Ooni ile Ifẹ, Oba Adeyeye Enitan Ogunwusi ti muleri ṣẹ lori adehun to ṣe pe oun yoo sọ ọmọ rẹ tuntun lorukọ Ooni to ṣaaju rẹ .
Fun idi eyi o ti ni ọmọ tuntun naa yoo ma jẹ orukọ pẹlu Ooni Tadenikawo Adesoji Aderemi to jẹ Ooni ṣaaju.
Ikede yi waye loju opo Twitter Ooni lẹyin ọjọ kẹjọ tọmọ naa d'aye ti wọn si ti yoo si ṣe etutu ọlọsẹmẹta tori ki o baa le ri bi o ti ṣe yẹ ko ri.
Alaafin ni awọn kan si Ifa nipasẹ Araba Agbaye olori awọn onifa lagbaye ki awọn to sọ orukọ yi di mimọ faraye.
Ooni salaye siwaju pe Araba Agbaye fi orukọ ọmọ naa le Oloye Lowa ilu Ife Adekola Adeyeye lọwọ ki wọn to wa kede rẹ setigbọ ero to pe sita.
Ẹkunrẹrẹ orukọ ọmọ naa ni Tadenikawo, Adesoji, Aderemi, Eri-Ifeoluwasimi, Adeiwa, Inioluwa, Ademide, Adegbite, Diekoloreoluwa, ọmọ Ogunwusi.
- Àwọn àwòrán ìrántí tó ń sàmì ogójì ọdún tí Ọba Adesoji Aderemi jáde láyé
- Adesoji Aderemi, Ọọ̀ni Ifẹ̀ àti gómìnà Adúláwọ̀ àkọ́kọ́ láyé eèbó amúnisìn
- Kí ìjọ mi ní Sagamu le gbòòrò ni mo fi ń ṣiṣẹ́ ajínigbé pawó - Pásítọ̀
- Orúkọ Aisha Yesufu náà wọ inú BBC 100 Women tí a fi ń sọri àwọn obìnrin tó pegedé ní 2020
Saaju ni Ooni ti ṣadehun pe oun yoo sọ ọmọ tuntun ti a bi lọjọ Kejidinlogun oṣu Kọkanla ọdun 2020 lorukọ ọkan lara awọn Ooni to jẹ saaju rẹ.
Ooni Tadenikawo Adesoji Aderemi ni o jẹ Ooni ikọkandinlaadọta ni Ile Ife.
Lasiko igbe aye rẹ, o jẹ oye Gomina adulawọ akọkọ laye eebo amunisin.

Oríṣun àwòrán, @oluwole_dada
A kò tíì lè sọ pé ọmọ Ọba tuntun ni yóò jẹ Ooni lọ́jọ́ iwájú - Elebuibọn
Ọjọ kejidinlogun, oṣu kọkanla, ọdun 2020 ni Ooni Ile Ife, Adeyeye Enitan Ogunwusi, kede lori ayelujara pe Olori oun, Naomi Ogunwusi, ti bi ọmọ ọmọkunrin tuntun.
Bi ọpọ awọn eeyan ṣe n ki Onirisa ayọ abara tintin, lawọn miran n sọ pe Ọba lọla lo de yẹn.
Ṣugbọn ṣe ootọ ni pe ọmọ tuntun ti Ooni ṣẹṣẹ bi ni yoo jẹ Ooni lọjọ iwaju?
Idi ree ti ileeṣẹ iroyin BBC Yoruba ṣe kan si Araba awo ilu Oṣogbo, Ifayemi Elebuibọn lati tanj imọlẹ si ọrọ naa.

Oríṣun àwòrán, Oniadimula
Elebuibọn ni, pe Ooni bi ọmọ ọkunrin ko tumọ si pe ọmọ naa ni yoo gori itẹ lọjọ iwaju.
O ni, bi wọn ṣe n yan ọba nilẹ Yoruba tẹlẹ ko to di pe ijọba ati ọlaju de, ti ijọba si n lọwọ ninu ọba yiyan.
Elebuibọn ni ki wọn to yan Ooni, tabi Ọba nilẹ Yoruba, idile ti oye ba kan lo maa fa ẹni ti wọn ba n fẹ ko dori itẹ silẹ, ti awọn afọbajẹ yoo si di ifa lati mọ boya asiko irufẹ Ọba bẹẹ yoo san awọn ara ilu.
O ni "wọ maa pe idilẹ ti oye bá kan, lẹyin naa ni wọn yoo to bi ifa lere."
- Wo àwọn èèkàn, ìlúmọ̀ọ́ka olórin tó ṣàbẹ̀wò sí ijọ Celestial Church ti Genesis Global
- CCC Genesis Global: Ǹkan mẹ́wàá tí ẹ ò gbọ́ rí nípa Israel Oladele, Woli ìjọ Genesis Global
- Ẹ̀tanú pé Olùṣọ́ Genesis kò fẹ́ Laide Williams-Oni ló ṣe rán an lọ́ sí ẹ̀wọ̀n ọdún kan - CCC Genesis Global
- Saka ń wá ọ̀rẹ́ rẹ̀ kan nítorí aṣọ kóòtù ọdún 34 sẹ́yìn
- Ọkùnrin tó pe ìyàwó rẹ̀ lájẹ̀ẹ́ tì í mọ́lé fọ́dún mẹ́rin, fún un lóyún nígbà mẹ́ta!
"Awọn idile ti oye kan yoo da'fa, bẹẹ ni awọn afọbajẹ naa yoo da'fa."
O ni kii ṣe akoko niyii lati maa sọ pe ọmọ tuntun ti Ooni bi ni yoo di Ọba lọla "nitori wọn ko mọ iru ori to yan, Ọba le bi ọmọ mẹwaa, kii si ṣe dandan ni pe akọbi ni yoo gori itẹ lẹyin baba rẹ, o le jẹ abigbẹyin."
Fun gbogbo awọn to n sọ pe Ooni ti bi Ọba lọla, Elebuibon sọ pe ti wọn ni wọn n sọ yẹn nitori gbogbo igi kọ lo maa n so olu.
Araba awo ilu Oṣogbo pari ọrọ rẹ pe, ifa lo ma n yan Ọba laye atijọ, ṣugbọn bayii oju ni wọn fi n yan ẹni to lọla tabi to lorukọ lawujọ lati di ọba.
O ni "eeyan le lowo lọwọ ṣugbọn ko ma lori oye."
- Ìtàn ayé Abiola Peller, ọlọ́wọ́ idán tó fi ọ̀bẹ gé ìyàwó rẹ̀ sí méjì
- Oba Folagbade Olateru-Olagbegi wàjà lẹ́ni ọdún 77
- Eji Gbadero, ọmọ Ibadan àti jayé-jayé ọmọ ónílẹ̀ ti wọn yẹgi fun l'Eko
- Áṣẹyin kìlọ̀ fáwọn adarí olóṣèlú Nàìjíríà láti ṣe ohun tó yẹ nítorí ará ọ̀run ń wò wọ́n!
- Oluwo Ìwo ṣ'àlàye lori oye Emir



















