Femi Gbajabiamila: DSS ti fi ẹ̀sọ́ àbò Gbajabiamila tó pa fẹ́ndọ̀ l'Abuja sátìmọ́lé

Oríṣun àwòrán, Femi Gbajabiamila
Abẹnugan ilé ìgbìmọ̀ aṣojú-ṣòfin l'Abuja, Femi Gbajabiamila ti ṣèlérí pé òun ṣetan láti tọ́ àwọn ọmọ fẹ́ndọ Ifeanyi Okereke ti ẹ̀ṣọ́ rẹ̀ yìnbọ̀n pa titi ti wan yóò fi dàgbà.
Gbajabiamila sọ èyí lásìkò tó lọ ṣe ẹkú ọrọ èèyàn si àwọn ẹbi olóògbé lágbègbè Kwata ní Madalla-Suleja.
Abẹnugan ni òun yóò tọ́ àwọn ọmọ rẹ̀ méjèèjì ní ilé ìwé titi wọ́n yóò fi tójúú bọ́, bákan náà ni òun yóò fún ìyàwó rẹ̀ ni owó ti yóò maa fi ṣòwò.
- Iye ìgbà tí ọrọ̀ ajé Nàìjíríà ti dẹnukọlẹ̀ lábẹ́ ìjọba ààrẹ Buhari
- Òtítọ́ làwọn sọ́jà gbé ìbọn tó lọ́ta gidi nínú lọ sí Lekki Toll Gate lásìkò ìwọ́de EndSARS- Ọ̀gágun Taiwo
- Wòlíì míì, tún wọ gàù lẹ́yìn tó tàpá sí ìlànà béèlì tí wọ́n fún un nílé ẹjọ́
- Ṣé Sanwo-Olu, gómìnà Eko yóò farahàn níwájí ìgbìmọ̀ olùwádìí ìṣẹ̀lẹ̀ Lekki Tollgate?
" Àwọn ọmọ yìí ti di tèmi, mo si ti pé agbẹjọ́rò mi láti ṣi àpò owó fún wọ́n títí ti wọ́n yóò fi tójuubọ́" ọ̀rọ̀ Femi Gbajabiamila rèé
Ẹ̀sọ́ abẹnugan ilé, to jẹ́ ọkan lára àwọn òṣìṣẹ́ ọ̀tẹlẹ̀múyẹ (DSS) Nàìjíríà, Abdullahi M. Hassan ló yìbọ̀n pa Ifeanyi nítori wan ń sá tẹ̀lé mọ́to Femi Gbajabiamila ti wọn si n kíi.
Ó ti le ni ọdún méje ti Ifeanyi ti n ta ìwé ìròyìn lágbègbè Federal Secretariat tó sì jẹ́ pé ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin ló mọ̀ọ́.
Bí abẹnugan ilé ṣe ń kọja ló fún Ifeanyi ni ẹgbẹrun mẹ́sán náírà pé kí ó pin pẹ̀lú àwọn tó kù rẹ̀, kí a tí wí ká tó fọ̀, ní Abdullahi yìn ni ìbọ̀n lórí ni ìgbà mẹ̀rin.
Ọ̀pọ̀ àwọn ọ̀rẹ́ Ifeanyi ló sàlàyé pé kìí ṣe ìgbà àkọ́kọ́ rèé ti Abdullahi ti maa n yìnbọn ni gbogbo ìgbà ti abẹnugan ba ti n kọjá.
Wọ́n ni ǹkan ti ó dun àwọn jùlọ ni pé, Ifeanyi ti rí iṣẹ́ sí ilé iṣẹ́ Labour & Productivity to si ti n múra láti lọ bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ kí ó tó kú

Oríṣun àwòrán, Gbajabiamila
Níbo ni SSS tó pa Ifeanyi wà?
Àjọ DSS ti fi Abdullahi si àtìmọ́le títí di àsìkò tí wọn yóò parí ìwádìí wọ̀n.
Agbẹnusọ àjọ náà Peter Afunaya tó fìdí ọ̀rọ̀ náà múlẹ̀ sàlàyé pé Abdullahi lo yìnbọ, ọmọ àjọ àwọn sì ni, àti pé àwọn ti ṣetan láti dá sẹríà tó tọ́ fún.
Ó fi kun pé, àjọ ọ̀hún ti yọọ́ kúrò lára àwọn tó ń tèlé mótò abẹnugan, àjọ náà fi kun pé kedere ni àwọn yóò ṣe gbogbo ìwádìí àti ìdája ọ̀rọ̀ náà.
Ìdája òdodo ni Ifeanyi yóò rí gbà
Ẹ̀wẹ̀, Gbajabiamila ti fi ọkàn gbogbo àwọn fẹ́ndọ̀ tó kù balẹ̀ lónìí ọjọ́ àìkú pé òun yóò rí dájú pé Ifeanyi kò kú lásán.
Abénugan to sàbẹ̀wò sí ilé iṣé wọ́n, ó sàlàyé fún wan pé, bí ìjọkó ilé yóò ṣe bẹ̀rl lọ́ja ìṣẹ́gun, àwọn yóò yẹ́ Ifeanyi sí nínú ìjókó àwọn
Bákan náà ló sọ pé òun ti wọ́gilé gbogbo ètò tí òun ní nílẹ̀ tẹ́lẹ̀ láti ríi dájú pé, òun se ìdárò Ifeanyi dáadáa.

Oríṣun àwòrán, Gbajabiamila
Àjọ agbófinró DSS ń àwọn ti bẹ̀rẹ̀ ìwadìí ẹ̀ṣọ́ olórí ilé aṣòfin-ṣojú, Femi Gbajabiamila tó yìnbọn pa Fẹndọ l'Abuja
Ileeṣẹ agbofinro ọtẹlẹmuyẹ DSS lorilẹede Naijiria ni awọn ti bẹrẹ iwadii lori iṣẹlẹ ibọn yinyin to ṣekupa fẹndọ kan ti orukọ rẹ n jẹ Ifeanyi Okeke latọwọ ọkan lara awọn oṣiṣẹ ileeṣẹ agbofinro naa.
Alukoro ileeṣẹ agbofin ọtẹlẹmuyẹ DSS, Ọmọwe Peter Afunaya ṣalaye ninu atẹjade kan pe lootọ oṣiṣẹ ileeṣẹ agbofinro DSS ni arakunrin ti wọn funrasi pe o yin ibọn naa, ati pe ara awọn ẹṣọ alaabo ti wọn yan ti olori ileegbimọ aṣoju-ṣofin orilẹede Naijiria, Họnọrebu Fẹmi Gbajabiamila ni.

Oríṣun àwòrán, Twitter/gbajabiamila
O ni wọn ti yọ ọgbẹni naa kuro lara awọn ẹṣọ olori ile aṣojuṣofin naa ati wi pe, ni ibamu pẹlu ilana ibawi lẹnu iṣẹ, wọn ti fi si ahamọ, ileeṣẹ agbofinro DSS si ti bẹrẹ iwadii pẹlu ileri pe ko ni si kọnu n kọhọ ninu iwadii lori bi afunrasi naa ṣe lo ibọn rẹ.
- Wòlíì Genesis kan yẹra díẹ̀ ni, ó máa tó wọlé padà bí olè lóru- Adelé pásítọ̀ Oladele
- Òtítọ́ làwọn sọ́jà gbé ìbọn tó lọ́ta gidi nínú lọ sí Lekki Toll Gate lásìkò ìwọ́de EndSARS- Ọ̀gágun Taiwo
- Ìjọba àpapọ̀ pàṣẹ pé kí gbogbo ọkọ̀ agbépo kúrò ní márosẹ̀ Lagos-Ibadan
- Seyi Makinde fún olórin Fuji Taye Currency lẹ́bùn ọkọ̀ bọ̀kìnnì Toyota Prado 2020
Wo orúkọ ẹ̀ṣọ́ Gbajabiamila tó yìnbọn pa fẹ́ńdọ̀ nílùú Abuja, pẹ̀lú ibi tó ti ń ṣiṣẹ́
Olori ileegbimọ aṣoju-ṣofin lorilẹede Naijiria, Họnọrebu Fẹmi Gbajabiamila ti ṣiṣọ loju ẹṣọ alaabo rẹ to yinbọn pa fẹndọ kan ni ilu Abuja l'Ọjọbọ
Họnọrebu Gbajabiamila darukọ ẹṣọ alaabo naa gẹgẹ bii Abdulahi Hassan.
O ni oṣiṣẹ ileeṣẹ alaabo ọtẹlẹmuyẹ DSS ni atipe wọn ti faa le awọn ileeṣẹ to yẹ lọwọ fun iwadii ati igbesẹ ibaniwi to rọ mọ iṣẹ rẹ ati ẹṣẹ ti o ṣẹ.
- CCC Genesis Global: Ǹkan mẹ́wàá tí ẹ ò gbọ́ rí nípa Israel Oladele, Woli ìjọ Genesis Global
- Ṣé lóòtọ́ ni ìgbìmọ̀ olùwádìí dábàá kí Ààrẹ Buhari yọ alága EFCC, Ibrahim Magu nípò?
- A dúro bí iké lẹ́yìn ìròyìn táa gbé jáde nípa Lekki Tollgate; CNN tako Lai Mohammed
- Ẹ̀tanú pé Olùṣọ́ Genesis kò fẹ́ Laide Williams-Oni ló ṣe rán an lọ́ sí ẹ̀wọ̀n ọdún kan - CCC Genesis Global
- Ìtàn ayé Abiola Peller, ọlọ́wọ́ idán tó fi ọ̀bẹ gé ìyàwó rẹ̀ sí méjì
- Ọkùnrin tó pe ìyàwó rẹ̀ lájẹ̀ẹ́ tì í mọ́lé fọ́dún mẹ́rin, fún un lóyún nígbà mẹ́ta!
Ni Ọjọbọ ni awọn ẹṣọ alaabo to wa pẹlu Họnọrebu Gbajabiamila 'yinbọn soke'lati tu awọn eeyan kan ti wọn ni wọn dabu ọkọ olori ile aṣojuṣofin naa ka.
Amọṣa lẹyin o rẹyin ni iroyin jade pe ibọn ba Ifeanyi Okereke, ọkan lara awọn fẹndọ to n ta iwe iroyin ni sẹkitariati ijọba apapọ ni lu Abuja ti o si jade laye.
Ẹ̀ṣọ Gbajabiamila yìnbọn pa fẹ́ńdọ̀ kan l'Abuja, àwọn akẹgbẹ́ rẹ̀ fẹ ṣe iwọde

Oríṣun àwòrán, Twitter
Olori ile asojusofin Naijiria Femi Gbajabiamila ti ni ki ọlọpaa kan lara awọn ẹsọ rẹ lọ rọọkun nile nitori pe o yinbọn pa arakunrin kan to n ta iwe iroyin Ifeanyichukwu Elechi nilu Abuja.
Gbajabiamila ni yoo bẹrẹ lilọ rọọkun nile naa titi ti ileesẹ ọlọpaa yoo fi pari iwadii.
Agbegbe Secretariat niluu Abuja ni nkan bi ago mẹta ni ọlọpaa naa yinbọn lu Ifeanyi.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
- CCC Genesis Global: Ǹkan mẹ́wàá tí ẹ ò gbọ́ rí nípa Israel Oladele, Woli ìjọ Genesis Global
- Báyìí ni olùwọ́de EndSARS, Eremosele Adene ṣe gba òmìnira lọ́wọ́ ọlọ́pàá Nàìjíríà
- Ìpànìyàn orí ayélujára lásán lẹ̀ ń pariwo, ìbọn òfifo làwọn sọ́jà yìn sínú afẹ́fẹ́ - Lai Muhammed
- Ẹ̀tanú pé Olùṣọ́ Genesis kò fẹ́ Laide Williams-Oni ló ṣe rán an lọ́ sí ẹ̀wọ̀n ọdún kan - CCC Genesis Global
Isẹlẹ yii waye nigba ti olori ileasojusofin kuro ni ọfisi rẹ.
Wọn sare gbe e lọ si ile iwosan agba nilu Abuja sugbọn ẹpa ko boro mọ.
Bi Isẹlẹ naa se waye
Gbajabiamila to sapejuwe iku fẹndọ naa gẹgẹ bi ohun to fọwọ kan ni lẹmi sọ pe awọn kuro ni ọfisi bi ise awọn ni tawọn si duro lati ki awọn to n ta iwe iroyin .
Gẹgẹ bi ohun to sọ, o ni oun ati awọn to n ta iwe iroyin wọnyi ti mọra tipẹ nitori ọdọ wọn loun ti n ra iwe iroyin lati igba ti oun ti de si Abuja.
O ni nitori eyi, oun a si tun maa fun wọn lowo nigbakigba toun ba kọja.
Nitori eyi, o ni Ifeanyi ati awọn akẹgbẹ rẹ rọ yika ọkọ oun nitori wọn mọ pe a maa fun awọn lowo.
Sadede lo ni awọn gbọ iro ibọn.
Olori ile sọ pe awọn arakunrin kan tawọn ko mọ ri darapọ mọ wọn lati yi ọkọ oun ka eyi lo si mu ki awọn ẹsọ yin ibọn soke.
O ni awọn agbofinro yi sọ pe ọgbọn lawọn agbofinro yi lo lati fi yin ibọn yi sugbọn nigba ti yoo fi ya lawọn gbọ pe asiyin ibọn ba arakunrin kan iyẹn Ifeanyi.
Gbajabiamila sọ pe oun ba awọn mọlẹbi Ifeanyi kẹdun lori isẹlẹ naa.
Awọn fẹndọ fẹ se iwọde ifẹhonu han
Ẹwẹ awọn fẹ́ndọ to n ta iwe iroyin lAbuja sọ pe awọn yoo bọ si igboro lati se iwọde lori iku ọkan lara wọn yi.
Wọn ni iwọde yi se pataki lati fi pe akiyesi ọga agba ọlọpaa si isẹlẹ yi.
Wọn tun sọ pe awọn ko ni ta iwe iroyin kankan titi di ago mẹwaa aarọ ati pe bi ẹnikẹni ba tapa si aṣẹ yi awọn yoo foju rẹ jofin.
Iwọde naa yóò gberasọ lati Area 1.


















