Prophet Shepherd Bushiri: Iléẹjọ́ gbẹ́sẹ̀ lé ilé wòlíì tí iye rẹ̀ tó $350,000

Oríṣun àwòrán, @TanzaniaUpdates
Adajọ ti pasẹ ki wọn gbẹsẹ le ile wolii Shepherd Bushiri lẹyin to tapa si ilana beeli rẹ ti wọn fun un.
Awọn oniroyin ni iye owo ile naa to wa ni Pretoria to $350,000.
Adajọ yi ti saaju ni ki wọn ko iwe ile yi kalẹ fun ile ẹjọ lori ẹsun gbajuẹ ti wọn fi kan wolii ọhun ati iyawo rẹ nilẹ South Africa.
Bayi ti wọn kọ lati tẹle ilana beeli ti wọn gba lọwọ ile ẹjọ, adajọ ti ni ki wọn gbẹsẹ le ile wọn yii.
Ọrọ yi waye lẹyin ti Bushir na papa bora pada lọ si orileede rẹ Malawi .
Ẹwẹ, ile ẹjọ kan ni Malawi ti wọn salọ ti tu awọn mejeji silẹ lẹyin ti wọn saaju gbe wọn wa siwaju rẹ lonii.

Oríṣun àwòrán, @namibiansun
- Ọkùnrin tó pe ìyàwó rẹ̀ lájẹ̀ẹ́ tì í mọ́lé fọ́dún mẹ́rin, fún un lóyún nígbà mẹ́ta!
- Èyí ni bí wọ́n ṣe pín fásitì LAUTECH láàrín ìpínlẹ̀ Oyo àti Osun
- CCC Genesis Global: Ǹkan mẹ́wàá tí ẹ ò gbọ́ rí nípa Israel Oladele, Woli ìjọ Genesis Global
- DSS ṣèlérí iwadìí tí kò rújú lórí bí òṣìṣẹ́ rẹ̀ kan ṣe yìnbọn pa fẹ́ńdọ̀ lẹ̀yìn Gbajabiamila
Amọ sa, awọn alasẹ ni South Africa si n tẹnu mọ pe Bushiri ati iyawo rẹ gbọdọ wa wi tẹnu wọn lori ẹsun gbajuẹ ti wọn fi kan awọn mejeeji nibẹ.
Wolii Bushiri ati iyawo rẹ ko sinmi lati sọ pe awọn ko jẹbi ẹsun ti wọn fi kan awọn, ati pe nitori ewu ti ẹmi awọn wa lo jẹ kawọn na papa bora lọ si Malawi.
Nibayi, South Africa ti fi iwe asẹ sita pe ki awọn alasẹ Malawi da wọn pada lati wa foju wina ofin.
Wolii Bushiri jẹ ilumọọka oniwaasu ọmọ Malawi to n dari awọn ile ijọsin ni Ghana ati South Africa.
Bushiri ni oludasilẹ Evangelical Church Gathering ni South Africa to si pẹka de awọn ilẹ Africa mii.
Wolii yi ti figba kan sọ pe oun da ara awọn eeyan ya lọwọ arun AIDS, oun le sọ afọju dẹni to n ri iran kedere, oun le sọ talaka di olowo, koda o ni oun le fẹsẹ rin lori ofurufu.

Oríṣun àwòrán, @CapitalFMMw
Bushiri ti sọ fun oloselu Zimbabwe kan, Kembo Mohadi pe wọn yoo de lade saaju ki o to pada wa di igbakeji aarẹ ilẹ naa gẹgẹ bi iwe iroyin New Zimbabwe se
Fọfọ ni papa isere maa n kun nigbakigba to ba se akojọ iwaasu nibẹ.
Ọpọ si ti ni o wa lara awọn pasitọ to lowo julọ nilẹ Africa.
- Saka ń wá ọ̀rẹ́ rẹ̀ kan nítorí aṣọ kóòtù ọdún 34 sẹ́yìn
- Bàbá mi, ẹ yé fi mí gba ìràwọ̀, ọmọbìnrin Charly Boy, Dewy Oputa fárígá fún bàbá rẹ̀
- Ṣé lóòtọ́ ni ìgbìmọ̀ olùwádìí dábàá kí Ààrẹ Buhari yọ alága EFCC, Ibrahim Magu nípò?
- A dúro bí iké lẹ́yìn ìròyìn táa gbé jáde nípa Lekki Tollgate; CNN tako Lai Mohammed
Ọrọ Bushiri ati iyawo rẹ di ohun tawọn eeyann ran lẹnu lẹyin ti oun ati iyawo rẹ sa mọ ile ẹjọ lọwọ lọ si Malawi lẹyin ti wọn gba beeli wọn.

Oríṣun àwòrán, @DumaFMRadio
Esun magomago ati iwa jibiti ni wọn fi kan wọn.
Awọn ọlọtẹlẹmuyẹ sọ pe, ẹjọ naa nii se pẹlu jibiti owo to to miliọnu mejilelọgọrun owo South Africa.
Saaju lo ti kọkọ yọju nile ẹjọ Majistireeti Pretoria lori ẹsun yi lọjọ kọkanlelogun osu Kẹwaa, ti adajọ si gba beeli rẹ lọjọ Kẹrin, osu Kọkanla.sọ.


















