Sunday Igboho Ogun trip vs Fulani: Mó wá sí ìpínlẹ̀ Ogun láti lé àwọn Fulani ajínigbé dànù lórí ilẹ̀ Yorùbá
Adari egbe Miyetti Allah ni ile Yoruba, Muhammed Kabir Labar ni nkan tÍ Sunday Igboho Ṣe ní Ibarapa tún ti ṣelẹ̀ ní ìpínlẹ̀ Ogun
Kabir Labar lo so bee fun BBC Yoruba.
Labar fẹsun kan Sunday Igboho pe bi o ṣe ṣẹlẹ lẹyin ti o kuro ni Igangan naa tun ti ṣẹlẹ ní Ogun.
Wọn dana sun ile Seriki ni agbegbe Ijọba ibilẹ Igbowa, ni ipinlẹ Ogun.
- Mọ̀ síi nípa Aung Suu Kyi tí wọ́n sọ sẹ́wọ̀n ní Myanmar àti bí ìgbàjọba ṣe wáyé níbẹ̀
- Ọ̀rọ̀ ìfẹ́ mú àgùnbánirọ̀ di èrò iléẹjọ́ ní ìpínlẹ̀ Kogi
- Ìjọba Nàìjíríà ti sún ọjọ́ ìforúkọsílẹ káàdi ìbánisọ̀rọ̀ síwájú síi
- Ọmọ ọdúnmẹ́tàdínlógún káwọ́ sẹ́yìn rojọ́ lórí ẹ̀sùn ìdúnkookò láti gbẹ̀mí ìyá rẹ̀''
- Seyi Makinde fi ọkọ̀ ńlá mẹ́rin dá ikọ̀ Amotẹkun lọ́lá nípìnlẹ̀ Oyo

Oríṣun àwòrán, Facebook/Africa Eyes
Ìjọba ìpínlẹ̀ Ogun kọ́ ló pé Sunday Igboho, ó kàn wá fúnra rẹ ni- Kọ̀míṣọ̀nná Ogun
Kọsmiṣọnna fun ifitonileti ni ipinlẹ Ogun, Abdulwaheed Odusile ti ni ki awọn eeyan mẹnu kuro lori koko pe Gomina Dapo Abiodun lo ranse pe Suinday Igboho.
Odusile fi atẹjade naa sita ni Abeokuta to jẹ olu ilu ipinle Ogun lẹyin ti Sunday Adeyemi wa si ipinlẹ Ogun wa kilọ iwa buruku fawon Fulani ajinigbe.
Kọmiṣọnna salaye ohun to ṣẹlẹ pe, Remi Hazzan to jẹ olubadamọran fun gomina Dapo Abiodun lori ibaraenisoro ni awọn kan dori ọrọ rẹ kodo.
O ni wọn yi ọrọ Hazzan ninu ifọrọwanilẹnuwo kan to ṣe ṣaaju ki Sunday Adeyemo ti ọpọ n pe ni Sunday Igboho to wa si Yewa nirọlẹ ana.
Odusilẹ ni nitootọ ni Hazzan ni ijọba Dapọ Abiodun yoo fọwọsopọ pẹlu awọn ti ọrọ kan ninu ile ati ni ia lati rii pe eto aabo wa fun awọn eniyan ipinlẹ Ogun ṣugbọn ko darukọ pe Sunday Igboho ni wọn n ranṣẹ pe.
O ni rioyin pe ijọba ranṣẹ pe Oloye sunday Igboho lati wa daabo bo awọn eeyan ipinlẹ Ogun jẹ irọ.
Odusilẹ ni ijọba gomina Dapo Abiodun n ko gbogbo eeyan mọra, ko dẹyẹ si ẹnikẹni ati pe ko si ẹni ti ko le fọwọsowọpọ pẹlu fun idagbasoke ati eto aabo ipinlẹ Ogun.
- Òfin kónílé-ó-gbélé gbòde nílùú Igangan lórí ẹ̀rù pé Fulani le k'ógun wá lẹ́yìn àbẹ̀wò Igboho
- ''Ìjọba gbọ́dọ̀ fí òfin dé ìrìnàjò àwọn Fulani darandaran láti àríwá sí gúúsù Nàíjíríà''
- Gomina Seyi Makinde ṣe ìpàdé lóru mọ́jú pẹ̀lú àwọn eèyàn Ibarapa ní Oke Ogun
- Ó lódì sí òfin kí ilé ìtura fí 'camera' sí inú yàrá tí àwọn ènìyàn wà- Irukera FCCPC
- Gbajúgbajà akọrin jùjú, Shina Peters jẹ oyè Bíṣọ́ọ̀bù Ìjọ Cherubim àti Seraphim

Oríṣun àwòrán, Facebook/Africa Eyes
Ki lo ti kọkọ ṣẹlẹ sẹyin?
Mó wá sí ìpínlẹ̀ Ogun láti lé àwọn Fulani ajínigbé dànù lórí ilẹ̀ Yorùbá- Sunday Igboho
Iroyin to tẹ wa lọwọ lati ipinlẹ Ogun sọ pe gbajugbaja ajijagbara ilẹ Yoruba, Sunday Adeyemo ti ọpọ mọ si Sunday Igboho ti gunlẹ si ipinlẹ Ogun lati kọju ija sawọn janduku Fulani to n huwa ọdaran nibẹ.
Ohun iroyin to tẹ wa lọwọ sọ pe aarọ ọjọ Aje, ọjọ kinini, oṣu keji ni Igboho fi ilu Ibadan silẹ lọ si ipinlẹ Ogun.
''A o ba awọn agbaagba ni Yewa ṣe ipade pọ, a si ti wa ni ilẹ Yewa bayii,'' Ọgbẹni Akinpelu ṣalaye.
Fidio kan lori ayelujara ṣe afihan Igboho fun ra rẹ nibi to ti n ba awọn ọmọ ipinlẹ sọrọ ni Ilu Ọja Ọdan.
- Ṣé lóòtọ́ọ́ láwọn Fulani tún ṣá aráàlú Igangan méjì ládàá nígbà tí wọ́n ń sùn?
- Seyi Makinde, Akeredolu, òfo ni kùrù-kẹrẹ yín lọ́dọ̀ Buhari lórí ìpèsè ààbò - Falana
- Wo àwọn ọmọ Yorùbá tó ń ti Sunday Igboho lẹ́yìn bí i iké
- Ẹ múra mi sílẹ̀ ẹ̀yin apààyàn Fulani ní Ogun, mò ń bọ̀ kánkán - Sunday Igboho
- Àwọn olóṣèlú ti ń fowó bẹ̀ mí kí n má bá Fulani jà torí ìbò 2023, àmọ́ o ti bọ́ - Sunday Igboho
- Gomina Seyi Makinde ṣe ìpàdé lóru mọ́jú pẹ̀lú àwọn eèyàn Ibarapa ní Oke Ogun
''Ipinlẹ Ogun ni mo wa bayii, mo wa gba awọn ọmọ Yoruba silẹ lọwọ awọn Fulani ajinigbe, awọn Fulani to fi ipa bawọn obinrin lopọ,'' Igboho sọrọ soke.
Igboho tun ni ''a ko fẹ Fulani ajinigbe mọ lori ilẹ baba wa, o to gẹẹ bayii.''
''O ya ẹ jẹ ki a wọ inu igbo Idua lọ bayii lati lọ pade awọn Fulani to n ji awọn Yoruba gbe.
Ọkan lara awọn ọmọlẹyin Igboho, Ọgbẹni Sina Akinpẹlu to ba BBC Yoruba sọrọ ṣalaye pe Igboho atawọn ọmọlẹyin rẹ gbera lọ si ipinlẹ lati kilọ fawọn Fulani lati so ewe agbejẹ mọwọ bi bẹẹ kọ, wọn o jẹ iyan wọn niṣu.
Ọgbẹni Akinpelu ṣalaye pe ko si ẹni to ranṣẹ pe Igboho atawọn ọmọlẹyin ni pato,
O ni Igboho atawọn to kọwọ rin pẹlu rẹ fi ọrọ naa to awọn lọbalọba leti pe awọn n bọ wa si ipinlẹ Ogun.
''A o ba awọn agbaagba ni Yewa ṣe ipade pọ, a si ti wa ni ilẹ Yewa bayii,'' Ọgbẹni Akinpelu ṣalaye.
Akinpelu sọ pe awọn yoo ranṣẹ si awọn Fulani to wa ni Yewa pe lati kilọ fun wọn pe wọn o gbọdọ na ọba alade kankan tabi fiya jẹ ọmọ Yoruba mọ, lai jẹ bẹ, wọn gbọdọ ko ẹru wọn ki wọn si ipinlẹ Ogun silẹ.

Oríṣun àwòrán, Facebook/Africa Eyes
''A o mọ iye ọjọ ti a maa lo ni Yewa lori ọrọ awọn Fulani yii, gbogbo awọn ọmọ Yoruba to nifẹ si ohun ti a n ṣe lo wa lẹyin wa,'' Ọgbẹni Akinpẹlu lo sọ bẹẹ.
Content is not available
View content on FacebookBBC kò mọ̀ nípa àwọn ohun tí ó wà ní àwọn ojú òpó tí ó wà ní ìta.End of Facebook post
Akinpelu fikun ọrọ rẹ pe awọn ranṣẹ si Gomina Abiodun wi pe awọn n bọ ṣugbọn gomina ko tii fesi.
''Amọ, a ko le duro ki gomina fesi kawọn ti wọn yoo fi pa awọn eeyan wa tan,'' Akinpelu ṣalaye.

Oríṣun àwòrán, Facebook/Africa Eyes
Ṣaaju akoko yii ni oludamọran pataki fun Gomina Abiodun ipinlẹ Ogun, Remmy Hazzan sọ pe ẹnikẹni to ba le ṣe iranwọ lori eto abo to mẹhẹ l'Ogun, ijọba yoo gbaruku tii.
Hazzan ni kii ṣe Igboho nikan, ẹnikẹni to ba le wa ojutu si ipenija ti ipinlẹ Ogun ni lori eto abo ni ijọba yoo ṣe atilẹyin fun un.

Oríṣun àwòrán, Facebook/Africa Eyes
Laipẹ yii ni iroyin kan gbori ayelujara pa pe awọn olugbe agbegbe ijọba ibilẹ ariwa Yewa ke gbajare pe awọn sọja to tẹle awọn Fulani darandaran kan to ko ẹran jẹ oko ni Yewa fiya jẹ awọn.
- Ṣé lóòtọ́ọ́ láwọn Fulani tún ṣá aráàlú Igangan méjì ládàá nígbà tí wọ́n ń sùn?
- ''Ìjọba gbọ́dọ̀ fí òfin dé ìrìnàjò àwọn Fulani darandaran láti àríwá sí gúúsù Nàíjíríà''
- Gomina Seyi Makinde ṣe ìpàdé lóru mọ́jú pẹ̀lú àwọn eèyàn Ibarapa ní Oke Ogun
- Ó lódì sí òfin kí ilé ìtura fí 'camera' sí inú yàrá tí àwọn ènìyàn wà- Irukera FCCPC
- Gbajúgbajà akọrin jùjú, Shina Peters jẹ oyè Bíṣọ́ọ̀bù Ìjọ Cherubim àti Seraphim
















