Border Closure reoppening: Àarẹ Buhari ní àti dẹ́kun fàyàwọ́ ogun ati ìbọn ló fa títi ẹnubodè pa, ṣùgbọ́n yóò di ṣíṣí padà láìpẹ́

Oríṣun àwòrán, Others
Wo ìgbà tí Ààrẹ Buhari yóò ṣí 'bọ́dà' padà
Aarẹ Muhammadu Buhari ni ijọba apapọ ti n ronu ṣiṣi awọn ẹnubode orilẹede Naijiria ti wọn ti pa tẹlẹtẹlẹ.
Aarẹ Buhari kede pe ijọba orilẹede Naijiria ko ṣa dede ti awọn ẹnubode naa bikoṣe lati dẹkun awọn fayawọ ohun ija oloro ati ogun nigba naa lẹyin ipade pẹl'awọn gomina ipinlẹ mẹrindinlogoji to wa lorilẹede Naijiria.
Ninu atẹjade kan to fi soju opo twitter rẹ ni aarẹ ti ṣalaye lori igbesẹ yii.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
Aarẹ ni oun ti ṣalaye idi ti wọn fi gbe awọn ẹnubode naa ti pa, "bẹẹni nisisiyi to dabi ẹni pe awọn orilẹede to mule ti wa ti mọ pataki ohun ti a fẹ bayiisaid, a ti n wo igbesẹ ati ṣii pada.
Awọn ohun ti o nilo lati mọ nipa ẹnubode ti ijọba aarẹ Buhari tipa niyi:
Ni oṣu kẹjọ ọdun 2019 ni ijọba ti awọn ẹnubode lati dẹkun fayawọ ogun, ohun ija oloro, ounjẹ atiohun elo ọgbin wọ orilẹede Naijiria.
* Orilẹede Naijiria kun ara awọn orilẹede to buwọlu adehun ajọṣepọ okoowo ọfẹ laarin awọn orilẹede Afirika, agreed African Continental Free Trade Area (AfCFTA),
Nibi ti ijiroro ti waye lori ṣiṣi awọn ẹnubode naa lati bẹrẹ owo pẹlu awọn orilẹede Afirika yoku.
*Minisita iṣuna ati ato ọrọ aje, Zainab Ahmed ṣalaye loṣu to koja pe igbimọ ti aarẹ gbe kalẹ ti pari iṣẹ rẹ o si ti buwọlu ki wọn ṣi awọn ẹnubode naa pada.
O fi kun un pe laipẹ ni wọn yoo gbe abajade iwadii wọn tọ aarẹ lọ.
- Èsì ìdìbò tí yóò gbé aàrẹ tuntun wọlẹ́ ní Ghana rèé...
- Ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa ìgbésẹ̀ tí Amẹ́ríkà fẹ́ gbé lórí Nàìjíríà nítorí ọ̀rọ̀ ẹ̀sìn
- Àwọn èèyàn tí bẹ̀rẹ̀ sì ní gba abẹ́rẹ́ àjẹsára fún ìdènà àrùn Coronavirus ni ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì
- Mi ò kí n ṣe afẹfẹ-yẹ̀yẹ̀ lórí ayélujára nítorí pé mí ò ní dúkìá tí mó le fihàn- Ronke Oshodi-Oke
- Lóòtọ́ ni ọkọ mi lù mí bí àṣọ òfì, àmọ́ gómìnà ti bá wa parí ẹ̀, ẹ máa gbàdúrà fún ìdílé mi- Dokita Ifeyinwa


















