Ondo Election 2020:Tani Akeredolu tó ń díje dupò gómìnà fún ìgbà kejì nípìnlẹ̀ Ondo

Oríṣun àwòrán, Akeredolu/instagram
A bi Oluwarotimi Odunayo Akeredolu ( SAN) ni ọjọ kọkanlelogun, Oṣu keje, ọdun 1956.
Idile Ẹni ọwọ Ola Akeredolu ati idile "Lady Evangelist" Grace Akeredolu ni ilu Igbotu, ijọba ibilẹ Ese Odo nipinlẹ Ondo.
O lọ si ile iwe alakọbẹrẹ ni ilu Owo lẹyin naa lo lọ si ile-iwe girama St Aquinas College ni ilu Akure, Loyola College ni Ibadan ati Comprehensive High ni Ayetoro nibi to ti gba iwe ẹri aṣe kagba girama.
- Ọ̀rọ̀ SARS kọ èmi àti ààrẹ Buhari lóminú - Yemi Osinbajo
- Bí èsì ìdìbò gómìnà ìpínlẹ̀ Ondo se ń jáde rèé..
- Akeredolu ti mókè nínú ìbò gómìnà níjọba ìbílẹ̀ méjìlá l‘Ondo, PDP gba mẹ́ta
- Ààrẹ Buhari kí Akeredolu kú orííré bí ó ṣe jáwé olúborí nínú ìdìbò sípò gómínà
- Gomina Kano tí ní kí olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ lọ rọ́kún nílé nítori o bu Ààrẹ Buhari lórí #EndSars
Lẹyin naa lo lọ si fasiti ile Ife to ti di Obafemi Awolowo bayii, lati gboye amofin to si kẹkọọ jade ni ọdun 1977, bakan naa ni wọn gbaa si ile ẹkọ awọn amofin lọdun 1978.
Akeredolu di kọmisọnna eto idajọ ati agbẹjọro ijọba ìpinlẹ Ondo lọdun 1997 si 1999,
O si di amofin agba (SAN) lẹyin naa lo di alaga awọn oluranlọwọ awọn to nilo agbẹjọro laarin ọdun 2005 si 2006.

Oríṣun àwòrán, Akeredolu/Instagram
Wọn fẹsun iwa jẹgudujẹra kan ninu oṣu kọkanla, ọdun 2009 nigba ti igbakeji ààrẹ ẹgbẹ awọn agbẹjọro (NBA), akọwe eto itọju ọmọ ẹgbẹ àti igbakeji akọwe owo n pin iwe ẹsun kaakiri pe Akeredolu kowojẹ ati pe o tẹ gbogbo ofin ẹgbẹ loju mọlẹ.
Ko pẹ ti ọrọ naa ṣẹlẹ ni awọn alaṣẹ ẹgbẹ NBA se atungbeyẹwo ẹsun naa wọn si da ẹjọ naa sigbo.

Oríṣun àwòrán, AFP
Ninu oṣu kejila, lọdun 2009 lasiko ti Akeredolu n ṣe idanilẹkọ ni Akeredolu sọ fun awọn ero pe ko si nkan ti ijọba le se lati ṣe atunto ẹka idajọ ti idibo Naijiria fi le lọ lai ni magomago ninu, bi awọn ara ilu gan ba kọ lati gbe igbesẹ to yẹ lati jẹ ki ibo wọn ni itumọ.
Ni ọdun 2012 ẹgbẹ NBA fi ile ẹgbẹ wọn tuntun ti wọn kọ s'Abuja sọ ori Rotimi Akerdolu nitori gbogbo iṣẹ takuntakun to ti ṣe fun ẹgbẹ ati bi o ṣe sọ ẹgbẹ naa di ilumọọka.
- Ikọ̀ Boko Haram àti gbogbò àwọn tó ń sàtìlẹyìn fún wọn kò ní rí ọdún 2021 - Pásítọ̀ Adeboye
- Àwọn ọmọ FIBAN kò gbọdọ̀ lo orin Wasiu Ayinde mọ́ lẹ́yìn ìfìyàjẹní Murphy- FIBAN
- Àwọn olùpolongo ìdìbò Aketi àti Jegede ń forígbárí l'Ondo, bí wọ́n ṣe n yìnbọn ni wọn n sun táyà
- Àwọn ọ̀dọ́ yabo ààfin, Ṣọun Ògbómọ̀ṣọ́ àti mínísítà sá àsálà fẹ́mi wọn
Ni ọdun 2011 Akeredolu wa lara ọpọ ero to fẹ di gomina labẹ asia ẹgbẹ Action Congress of Nigeria (ACN) lati di gomina ipinlẹ Ondo ninu idibo ọdun 2013.
Akeredolu dide labẹ asia ẹgbẹ oṣelu ACN to si fori gbari pẹlu Olusola Oke ati Mimiko.

Oríṣun àwòrán, Akeredolu/instagram
Ni ọdun 2016 Akeredolu dide labẹ oṣelu APC ti ajọ INEC si kede rẹ bi olujawe olubori ni ọjọkẹtadinlọgbọn osu kọkanla ọdun 2016.
Ni ọjọ kẹtadinlọgbọn oṣu kọkanla ọdun 2016, wọn kede Akerdolu bi ẹni to jawe olubori pẹ idibo 244, 842 nigba ti ọgbẹni Jegede ni ibo 150, 380 ti ọgbẹni Oke si ni 126, 889 gẹgẹ ọjọgbọn Ganiyu Ambali to jẹ alaboju to ibo to soju ajọ INEC.
- Mọ̀ sí i nípa díẹ̀ lára àwọn èèyàn tí ikú wọn 'láti ọwọ́ ọlọ́pàá' milẹ̀ tìtì ní Nàìjíríà
- Ẹni méjì kú, ọ̀pọ̀ dèrò ilé ìwòsàn níbi ìjàmbá ọkọ̀ tó ṣẹlẹ̀ ní Okokomaiko nípínlẹ̀ Eko
- Ó sàn fún mi kí n má tíì lọ́kọ báyìí ju kí n lọ́kọ ṣùgbọ́n...- Nkechi Blessing
- Ọ̀rẹ́ wa ni Lawrence jẹ́, àmọ́ ó gbẹ̀yìn dẹ́nu ìfẹ́ kọ abúrò wa - Joshua àti Damilola Bamiloye
- Ìdí márùn ún tí agbára Covid 19 ní ilẹ̀ Adúláwọ̀ kò fi tó tí àwọn ilẹ̀ àgbáyé míràn
Ni Bayii, ẹgbẹ oṣelu APC tun fun Akeredolu ni aaye lati tun dije dupo gomina fun idibo ọdun 2020 lẹyin to fi ẹyi Olusola Oke, DI Kkemeke, Segun Abraham àti àwọn miran janlẹ ninu idibo komẹsẹoyọ to waye.
Ni ọjọkọkandinlọgbọn oṣu keje ọdun 2020, Rotimi Akeredolu yan Lucky Aiyedatiwa gẹ́gẹ́ bi olujumọ dije dupo fun idibo ọdun 2020 lẹyin oun ati igbakeji rẹ Agboola Ajayi fija pẹẹta.
Rotimi Akeredolu fẹ Betty Akeredolu ni Iyawo, Ọlọrun si fi ọmọ tawọn lọrẹ

Oríṣun àwòrán, Akeredolu/Instagram

















