FIBAN: Ìpàdé àláàfíà wáyé láàrin KWAM 1 àti FIBAN, ìjà pari

Gbonmi si omi o to to waye laarin ẹgbẹ awọn sọrọsọrọ Naijiria ta mọ si FIBAN ati akọrin Fuji KWAM 1 ti pari.
Ọrọ naa yanju lẹyin ipade alaafia kan to waye tawọn mejeeji si ni awọn ti pana ohunkohun to n da wahala silẹ.
Ni aafin Olu ti ilu Itori ni ipade yi ti waye ti Wasiu Ayinde si sọ pe oun ko paṣẹ ki awọn ọmọ gbẹ oun kankan lu Mc Murphy.
Nitori naa aarẹ ẹgbẹ FIBAN Desmond Nwachukwu ti wa pasẹ ki awọn ọmọ ẹgbẹ naa jeburẹ ki wọn si bẹrẹ si ni lo orin KWAM 1 lori eto wọn.

Oríṣun àwòrán, Instagran/kingwasiuayindemarshal
'Nítori ààbò ẹmí MC Murphy ló fi gbá #100,000 lọ́wọ́ K1 lọ́jọ́ ìṣẹ̀lẹ̀'

Àwọn ọmọ ẹgbẹ́ FIBAN ti fi ààké kọrí lórí ìṣẹ̀lẹ̀ to wáyé láàrin MC Murphy tó jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ wọ́n ní ìpińlẹ̀ Ogun àti gbájúgbaja olórín fújì, King Wasiu Ayinde Mashall.
Nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀ lásìkò tó bá BBC Yoruba sọ̀rọ̀, ní ààrẹ ẹgbẹ́ FIBAN Desmond Nwachukwu sàlàyé pé, àwọn ṣì ń dúró de Ọjọ́rú ọjọ keje, ọdún yìí kí àwọn tó gbé ìgbẹ́sẹ̀ tó kan lórí ọ̀rọ̀ náà.
Nwachukwu ní, lẹ́yin ọjọ́ náà, ti Wasiu Ayinde ko ba bẹ̀bẹ̀ gẹ́gẹ́ bi àwọn ṣe kọ̀wé ránṣẹ́ sí í lórí ǹkan ti àwọn ń fẹ́ kó ṣe, lawọn yoo ṣe iwọde lọ sọdọ Kabiyesi iku baba yeye lati rọ ọ loye gẹgẹ bi Mayegun ilẹ Yoruba.
- Tani Akeredolu tó ń díje dupò gómìnà fún ìgbàkejì nípìnlẹ̀ Ondo?
- Ẹgbẹ́ òṣèlú PDP, ẹ̀ka ìpínlẹ̀ Eko fún Fayose lọ́jọ́ méje láti bẹ àwọn adarí ẹgbẹ́
- Ikọ̀ Boko Haram àti gbogbò àwọn tó ń sàtìlẹyìn fún wọn kò ní rí ọdún 2021 - Pásítọ̀ Adeboye
- Yoruba wo ló fẹ́ gbé Oduduwa Republic tẹ́ n pariwo? - Lizzy Anjorin
- Ẹgbẹ́ òṣèlú PDP, ẹ̀ka ìpínlẹ̀ Eko fún Fayose lọ́jọ́ méje láti bẹ àwọn adarí ẹgbẹ́
- Làásìgbò òṣèlú wáyé nílùú Ondo, ọ̀pọ̀ èèyàn fara pa
- A ti ń bimọ ju ǹkan tí apá orílẹ̀èdè lè ká lọ, ẹ má bí ju méjì, mẹ́ta lọ mọ́ o! - Aregbesola
Ó ní ìdí tí àwọn fi fẹ́ kí wọ́n gba oyè lọ́wọ́ Máyégún gbogbo ilẹ̀ Yorùbá ní pé ìwà tó hù kò bá ìlànà oyè tó jẹ́ lọ nítorí náà, Aláàfin Ọyọ Ọba Lamidi Adeyemi gbọ̀dọ gbà á lọ́wọ́ rẹ.
Lórí ẹgbẹ̀rún lọ́nà ọgọ́rún Náírà ti Murphy gbà lọ́wọ́ K1, o ní láti le dáàbò bo ẹ̀mi rẹ nítori túlàsì ni wọ́n fi fún un ni owó náà. Tí ọ̀rọ̀ bá sì ti rí bẹ́ẹ̀, ó ti pọndandan ki ènìyàn dáàbò bo ẹmi ara rẹ náà.
Lẹ́yìn tí Wasiu Ayinde bá wá ti gbé ìgbésẹ̀ tí ẹgbẹ̀ náà bèrè fún ni àwọn yoo tó mọ̀ boya àwọn yóò dá owó náà padà bi bẹ́ẹ̀ kọ́, owó ọhun kò tí tó ǹkan ti àwọn fi ṣe ìtọ́jú MC Murphy.
Ó rọ gbogbo olórin láti so ewe agbéjẹ́ mọ́wọ́ lórí bi wọ́n ṣe máa n huwa sí àwọn akọròyìn, ìwà ìyànjẹ to fi mọ ìwà àitọ sí àwọn akọròyìn ní Naìjíríà.
Bákan náà ló fi kún un pé, ìdáhùn ọkan lára amúgbálẹ́gbẹ̀ẹ́ K1 to bá BBC Yoruba sọ̀rọ̀ tó sí ló àwọn ọ̀rọ̀ kan, ẹgbẹ náà ni láti mọ̀ bóya òun gan ló fún un láṣẹ lati sọ̀rọ̀.
Bákan náà ni wọ́n gbọdọ̀ tọ̀rọ̀ àforijì lórí ọ̀rọ̀ náà.
Àwọn ọmọ FIBAN kò gbọdọ̀ lo orin Wasiu Ayinde mọ́ lẹ́yìn ìfìyàjẹní Murphy- FIBAN
Ẹgbẹ awọn oniroyin aladani, FIBAN ti kede pe ọmọ ẹgbẹ wọn kankan ko gbọdọ lo orin Wasiu Ayinde kankan mọ lori eto wọn.
Aarẹ ẹgbẹ FIBAN, Desmond Nwachukwu lo fi lede ninu atẹjade kan lati fesi si iṣẹlẹ to ṣẹlẹ laarin Wasiu Ayinde ati oniroyin Wole Sorunke ti wọn n pe ni MC Murphy.
Nwachukwu ni iṣẹlẹ naa ko dun mọ awọn ninu nitori pe ki i ṣe igba akọkọ ni yii ti Kwam 1 yoo ma hu iru iwa bayii ni igba de igba.
O ni ọrọ abuku ni asoju Kwam 1, Kunle Rasheed sọ nipa iṣẹlẹ naa fun BBC News Yoruba nibi to ti sọ fun ẹgbẹ FIBAN lati sa ipa wọn lori iṣẹlẹ naa, koda wọn le e gbe awọn lọ si ileẹjọ.
''Ma a bẹ awọn ọmọ ẹgbẹ lati da ọrọ Rasheed nu, nitori ko si otitọ kankan to sọ pẹlu ọrọ kubakugbe to sọ si ẹgbẹ FIBAN.''
''Rasheed tabuku lu wa nitori pe o pe wa ni ẹgbẹ ti ko ni oye nipa iṣẹ to n ṣẹ''
''Nitori naa ni bayii, ko si ọmọ ẹgbẹ wa kankan ti yoo lo orin Kwam 1 lori eto wa kaakiri iwo oorun orilẹede Naijiria.''
''Bakan naa ni a ti ranṣẹ si awọn adari ileeṣẹ radio ati amọhunmaworan lati tẹlẹ aṣẹ wa lati maṣe lo orin Kwam 1 mọ.''
- ₦750m ni Akeredolu ń gbà lóṣù fún ‘Security Vote’ àti ₦150m owó oṣù - Agboola Ajayi fèsì
- Àwọn olùpolongo ìdìbò Aketi àti Jegede ń forígbárí l'Ondo, bí wọ́n ṣe n yìnbọn ni wọn n sun táyà
- INEC kéde agbègbè ẹsẹ̀ odò 270 ti èrú ìbò ti le wáyé ní ìpínlẹ̀ Ondo
- Ọ̀pọ̀ aráàlú Owo wà nílé ìwòsàn, síbẹ̀ APC àti PDP kò gba ẹ̀bi
- Ẹ gbọ́ òhun tí àwọn olùdíjé sípò gómìnà nípínlẹ̀ Ondo sọ nípa Bàbá ìsàlẹ̀...
- Wike, má gbé jàgídíjàgan wá sí Ondo, APC kò ní ṣ'èèrú nínú ìdìbò gómìnà tó ń bọ̀- Kalejaye
Ẹgbẹ FIBAN fi kun un wi pe awọn yoo ṣewode lọ si aafin ti Alaafin Oyo lati fi aidunnu wọn han si iwa ifiyajẹni ti Kwam 1 n wu lawujọ.
Bakan naa ni awọn yoo bẹrẹ lọwọ Alaafin lati rọ ọ loye Mayegun ti Ilẹ Yoruba nitori ihuwasi rẹ ti ko ba ọna asa ati iṣe Yoruba mu.
Kwam 1: Ọmọṣẹ́ Wasiu ni MC Murphy, tó bá fẹ́ lọ sílé ẹjọ́ kó nìsó níbẹ̀- Alákòso orín K1
Ni owurọ ọjọ Abamẹta ni ariwo gba ilẹ kan pe, ilumọọka akọrin Fuji ati Mayegun ilẹ Yoruba, Wasiu Ayinde Mashall, ti ọpọ eeyan mọ si Kwam 1, gba gbajumọ agbohunsafẹfẹ kan leti loju agbo.
Alákòso orín Wasiu Ayinde Mashall, Adebayo Olasoju to ba BBC Yoruba sọrọ lórí fóònù ṣàlàyé pé, ọ̀rọ̀ tó ṣẹlẹ kìí ṣe èyí tó yẹ ki ó jáde rárá nítóri, ọmọ iṣẹ́ K1 ni MC Murphy.
Kété ti ọrọ náà bẹrẹ si ni ran ka ni BBC kan si àwọn to jẹ́ ti K1, nítori owe àgbà ló sọ pé agbẹ́jọ́ ẹnikan dájọ àgbà òṣìkà ni.
"Tí ọ̀rọ̀ bá ṣẹlẹ̀ láàrín K1 àti MC Murphy ti Murphy kò si le pé Wasiu Ayinde to wá gbé ẹjọ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn oníròyìn , òun ló mọ"
"Tí àwọn FIBAN bá sì fẹ́ lọ sí ilé ẹjọ́, kí wọ́n nìsó níbẹ̀" Ọ̀rọ̀ ti a ń múgbọ́ jú ti Murphy lọ, a ò ni ẹjọ́ kankan ti a fẹ́ bá a rò"
Alakoso orin Kwam 1, Adebayo Olaasoju sọ fun BBC Yoruba pe, ọrọ naa ko ri bẹẹ rara nitori Kwam 1 ko lee gba ẹnikẹni leti rara.
- Yoruba wo ló fẹ́ gbé Oduduwa Republic tẹ́ n pariwo - Lizzy Anjorin
- Ohun tójú àwọn èèyàn tún rí tí wọ́n figbé ENDSARS bọnu
- Àwọn olùpolongo ìdìbò Aketi àti Jegede ń forígbárí l'Ondo, bí wọ́n ṣe n yìnbọn ni wọn n sun táyà
- Pásítọ̀ CAC àti afurasí 'Yahoo boy' Olawale tó lu Hayatou ní jìbìtì N12.7m kó sí páńpẹ́ EFCC
- Adìyẹ́ jẹ̀fun ara wọn! Ẹ̀ṣọ́ NSCDC ṣèèṣì yìnbọ̀n pa ọlọ́pàá ọ̀tẹlẹ̀múyẹ́ DSS l'Osun
"Awọn wo lo na a, se Kwam 1 ni. Ọmọ Wasiu ni MC Murphy now, ko si yẹ ko gbe ọrọ naa lọ sọdọ awọn akọroyin, oun n gan mọ pe oun ko sọ ootọ bi ọrọ naa se ri.'
Bakan náà BBC bá ilumọọka agbohunsafẹfẹ naa ti wọn pe ni Wole Sorunke, ti ọpọ eeyan mọ si MC Murphy, ẹni tii se oludari eto gbogbo nileesẹ radio Fresh FM to wa nilu Abeokuta náà sọ̀rọ̀.
Gẹgẹ bi iroyin naa se wi, nibi ayẹyẹ ọjọ ibi ọgọta ọdun Olu tilu Itori, Ọba Abdulfatai Akorede Akamọ ni isẹlẹ naa ti waye, lasiko ti wọn pe Kwam 1, ko wa kọrin nibẹ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Sunday Igboho kàn ń gbé ‘Camera’ lẹ́yìn kiri, kí wọ̀n lè rò pé ó ń jà fún Yorùbá - Gani Adams
- Donald Trump dèrò ilé ìwòsàn torí àrùn Coronavirus tó mu
- Ìlànà ‘Referendum’ nìkan la fi le gba orílẹ̀èdè Oduduwa, kìí ṣe ìwọ́de
- Aṣọ́bodè ṣèèsì pa ‘Panel Beater, aya mẹ́rin àti ọmọ 18 ń bẹ̀bẹ̀ fún ìrànwọ́
- ₦750m ni Akeredolu ń gbà lóṣù fún ‘Security Vote’ àti ₦150m owó oṣù - Agboola Ajayi fèsì
- INEC kéde agbègbè ẹsẹ̀ odò 270 ti èrú ìbò ti le wáyé ní ìpínlẹ̀ Ondo
- Ẹgbẹ́ tó ń fẹ́ Oduduwa Republic kọ̀wé ẹ̀hónú sí UN, EU, AU àti ìjọba Gẹ̀ẹ́sì
- Àjọ EFCC ti mú ọ̀dọ́kùnrin mẹ́wàá lórí ẹ̀sùn jìbìtì lílù lórí ayélujára ní Oyo
- Irọ́ ni o! Ìyàwó Ọ̀ọ̀ni Ogunwusi kò bímọ tuntun
A gbọ pe Mayegun se agbohunsafẹfẹ yii, bii ọsẹ tii se oju, to si fi se ẹlẹya lori ọrọ ti ko to nnkan.
Ọna lati fi idi otitọ mulẹ nipa iroyin yii, lo mu ki BBC Yoruba kan si MC Murphy, ka le mọ bi isẹlẹ naa se waye.
Nigba to n ba BBC Yoruba sọrọ, Murphy ni lootọ ni ọmọ isẹ gbajumọ olorin Fuji , Wasiu Ayinde, to pe orukọ rẹ ni KC gba oun leti, ti Wasiu Ayinde funra rẹ gan si fi bata tẹ oun ni ori ati ẹnu mọlẹ.
O fikun pe, lẹyin to tẹ oun lori ati ẹnu tan, ni Wasiu to wa sẹsẹ tun n gbe oun lori dide, eyi ti ko bojumu rara.
"Mo kọkọ n wo pe se ẹgbọn n ba aburo rẹ wi ni abi ibo ni mo ti se asise? Abi nnkan kan sẹlẹ ti Alhaji ko ri ni, abi nnkan ti ko yẹ ki wọn sọ fun wọn ni wọn gbọ ni, ko tiẹ ye mi."

Oríṣun àwòrán, Instagran/kingwasiuayindemarshal
Murphy ni oun lọ siwaju Kwam 1 lati nawo fun ni, ki o le ki ẹnikan ti oun n ba se onigbọwọ, ki oun si fi ọrọ ẹni naa to leti pe onitọun fẹ wa na lowo fun loju agbo.
Amọ o ni, Wasiu Ayinde ko dahun, ti oun si sọkalẹ loju agbo naa.
"Sugbọn bi mo se sọkalẹ ni mo gbọ gba leti mi, ti wọn si da mi dọbalẹ, ti wọn n fi bata tẹ mi lori mọlẹ. Gbogbo awọn ero to wa loju agbo lo binu, ti wọn si kuro nibẹ.
Murphy ni Olu ti ilu Itori tawọn lọ ba se ayẹyẹ ti bẹ oun, nitori oloye ni oun nilu Itori, oun si ni Aarẹ Amuludun fun gbogbo ilu Itori.
"Mo maa n promote awọn olorin, mo si mọ pe Wasiu gbọ ọrọ ti ko yẹ ni nitori ko ye mi nipa oun ti wọn gba mi leti si, kii si se eeyan bẹẹ."
Nigba ta bi pe ki lo fẹ se nipa isẹlẹ yii, MC Murphy ni isẹlẹ naa ti kọja agbara oun, ti olu ile ẹgbẹ awọn agbohunsafẹfẹ ni Naijiria, FIBAN, si ti tẹsẹ bọ ọrọ naa.
"Wasiu Ayinde funra rẹ gan ti n bẹ mi, to si ti pe mi pe, ki n ranti pe oun ni ẹgbọn oun. Ti Wasiu ba na mi ni kọrọ, o to eeyan to le na mi, amọ eyi to se ni gbangba lo ku diẹ kaa to.
Ọlọrun kan fẹ ki iru nnkan bayii sẹlẹ ni, ki Alhaji Wasiu ma baa se iru nnkan bayii mọ."
O wa rọ awọn akọroyin atawọn adari eto, ta mọ si MC pe, ki wọn maa bọwọ fun ara wọn, ki wọn ma si toju bọ ayẹyẹ ti wọn ko ba pe wọn si, tori awọn abuku bii eleyi.


















