Iree Osogbo Bank Robbery: Ara olóògbé Dauda Jelili Kayode ti wọ káà ilẹ̀ lọ ní Iree

Lẹyin ti ileewosan ti fidiẹ mulẹ pe sajẹnti ọlọpaa ti awọn adigunjale pa sileeṣẹ ọlọpaa ni ilu Iree lọjọ ru naa ni wọn sin in.Àwọn olùgbé ìpínlẹ̀ Osun bínú yabo iléeṣẹ́ ọlọ́pàá lẹ́yìn ìdigunjalẹ̀ tó gba ẹ̀mí eèyàn ní Iree
Ana, ọjọ kẹfa, oṣu kẹjọ, ọdun 2021 ni wọn gbe oloogbe Dauda Jelili Kayode wọ kaa ilẹ lọ.
Ilu Iree nibi to ti n ṣiṣẹ ti o ti ku iru iku yii naa ni wọn sin Dauda Jelili Kayode si.
- Obìnrin kan gbé McDonald's lọ ilé-ẹjọ́ torí ìpolówó Buger já a láàwẹ̀
- Mo gbádùn bí wọ́n ṣe ń pè mí ní ''audio governor''- Seyi Makinde
- Èèmọ̀ rèé o! Àrá sán pa èèyàn 17 níbi ayẹyẹ ìgbéyàwó, ọkọ ìyàwó farapa
- Ìdí tí wọ́n fi ń pè mi ní Maradona rèé- Ibrahim Babangida
- Tú ajá rẹ sílẹ̀, kí o fi ẹ̀wọ̀n oṣù mẹ́fà jura ní ìpínlẹ̀ Oyo
- ESABOD gbé ìjà Mide Martins rù sórí ara rẹ̀ ó ń fi èpè ránṣẹ́ sí Adunni Olorisa àtàwọn míì
Tẹbi tara ati iyekan lo peju sibẹ pẹlu omije kikoro loju wọn.
Awọn alaba ṣiṣẹ rẹ naa royin iwa akọni to ni pe o ṣeni laanu pe nibi ti yoo ba lọ ni ẹnu iṣẹọba to n ṣe.

Awọn olugbẹ ilu Ire ni ipinlẹ̀ Osun ti yabo ileeṣẹ ọlọpaa to wa ni ilu na pẹlu ibinu.
Wọn ṣe iwọde de ileeṣẹ ọlọpaa to wa ni Iree lẹyin ti awọn adigunjale yabo banki UBA ati Access Bank nibẹ ti wọn si ṣọṣẹ.

Ninu idigunjale naa ni ẹmi agbofinro kan ti ba iṣẹlẹ naa lọ ni irọle ana, ọjọbọ, ọjọ karun un, oṣu kẹjọ, ọdun 2021.

Oríṣun àwòrán, @NPF
Àwọn olùgbé ìpínlẹ̀ Osun bínú yabo iléeṣẹ́ ọlọ́pàá lẹ́yìn ìdigunjalẹ̀ tó gba ẹ̀mí eèyàn ní Iree
Awọn adigunjale naa lo fi ibọn pa ọkunrin naa ni agọ ọlọpaa to wa nitosi ibẹ lati fi le awọn agbofinro kuro ni agbegbe naa ki wọn to ṣoṣẹ.
Awọn olugbe Iree binu nitori lati nkan bii aago mẹrin ni wọn ni awọn oniṣẹ ibi naa ti bẹrẹ iṣẹ nibẹ.
- Níbo ló kù tí Messi yóò lọ báyìí?
- Òjò àrọ̀rọ̀dá gbẹ̀mí èèyàn mẹ́ta ní Oshogbo,ọ̀pọ̀ dúkìá ṣòfò
- A ti mú afurasí darandaran méjì tó ń da màálù tó kan ọmọ oṣù mẹ́ta pa- Ọlọ́pàá
- Wo àwòrán ìgbéyàwó ọkùnrin tó gbé obìnrin mẹ́rin níyàwó lọ́jọ́ kan ṣoṣo
- Ẹran Akíka(Pangolin) àti ìwo Erin d'ẹ́rù b'olẹ̀, ìjọba f'òfin gba bílíọ́nù 22 ẹran ara wọn
Agbẹnusọ fun ileeṣẹ ọlọpaa nibẹ, Yemisi Opalola fidi iṣẹlẹ naa mulẹ lẹyin to ni awọn akọṣẹmọṣẹ agbopfinro ti bẹrẹ iṣẹ nibẹ bayii.
O ni awọn ọlọpaa n fọwọsowọpọ pẹlu awọn ẹgbẹ Olọdẹ ibilẹ ati awọn ẹgbẹ alaabo mii nibẹ bayii.
Awọn ti iṣẹlẹ ibinu awọn ara ilu ṣoju wọn sọ pe awọn ara ilu kan n ṣe iwọde alaafia ni.
Ati pe wọn ko ba nkan ini ilu kankan jẹ.
Bẹẹ naa ni wọn ko ṣe ọlọpaa kankan ni ijamba.
Wọn ni wọn ti gbe oku Sajẹnti ọlọpaa ti awọn adigunjale pa naa lọ si aagọ ọlọpaa miran ni Ikirun.
- Àwọn ọmọ Nàìjíríà ń wa ẹnu lé ìyàwó ọmọ Ààrẹ Buhari torí àwọn aṣọ ìgbéyàwó rẹ̀ tó ṣí ara sílẹ̀
- Bí ènìyàn Ọ̀ọ́dúnrún ṣe fò ṣán'lẹ̀ kú rèé torí ààrùn onígbà méjì ní Kano ati Jigawa
- Ààrẹ NFF tẹ́lẹ̀ri Oneya jáde láyé lẹ́ni ọdún 73
- Ẹran Akíka(Pangolin) àti ìwo Erin d'ẹ́rù b'olẹ̀, ìjọba f'òfin gba bílíọ́nù 22 ẹran ara wọn
- Ọ̀rẹ́bìnrin kó sí gbaga ọlọ́pàá lórí ẹ̀sùn pé ó gún "Sugar daddy" rẹ̀ pa
Kọstabu ọlọ́pàá ni awọn adigunjale pa ní ìlú Ire ti wọ́n ti fọ BankiAkọroyin BBC ti fidi ọrọ mulẹ fun BBC pe kọstabu ọlọpaa ni awọn adigunjale to ṣọṣẹ ni Banki meji kan ni ilu Ire.
Bakan naa lo fi kun pe ibọn ba asọna banki ti Access naa sugbọn o ti n gba itoju nile iwosan.Nibayii eniyan kan lo ku nibi iṣẹ̀lẹ̀ naa ti eniyan kan si wa ni ile iwosan.

Àwọn adigunjalè ṣọṣẹ ni Banki méjì nípìnlẹ̀ Osun.
Àwọn adigunjale kan ti lọ kọlu ile ifowopamọ meji ni ilu Iree ni ipinlẹ Osun.
Gẹgẹ bi akọroyin BBC to debi iṣẹlẹ naa ṣe sọ ibọn ba okunrin kan ti wọn si ri oku rẹ nilẹ, bi o tilẹ jẹ pe ko si ẹni ti o ti le sọ iye eniyan ti o ti ba iṣẹlẹ naa rin.
Awọn ti isẹlẹ naa ṣẹ loju wọn salaye pe akẹkọọ ni ọmọkunrin ti ibọn ba naa sugbọn ko si ẹni to tii mọ eni to jẹ.
- Ọ̀rẹ́bìnrin kó sí gbaga ọlọ́pàá lórí ẹ̀sùn pé ó gún "Sugar daddy" rẹ̀ pa
- Ẹ wo ọ̀nà àbáyọ tí adigunjalè bá kọ lẹ́tà sí yín pé àwọn fẹ́ ẹ́ wá jà yín lólè
- Àdigunjalè báńkì ní Iyin-Ekiti fẹsẹ̀ fẹ, bí wọ́n ṣe rí wa - Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá
- Ẹran Akíka(Pangolin) àti ìwo Erin d'ẹ́rù b'olẹ̀, ìjọba f'òfin gba bílíọ́nù 22 ẹran ara wọn
Wọn fi kun pe awọn adigunjale naa dede yabo ile ifowopamọ UBA ati banki miiran ni agbegbe ijoba ibile Boripe.
Bakan naa ni wọn fi kun pe ilu Ada ni wọn gba salọ.
Ninu awọn ti ọrọ soju wọn ohun, bi awọn kan se n fidi rẹ mulẹ fun akọroyin wa pe awọn ri pe ọkọ meji ni wọn gbe wa ni awọn miiran sọ pe ọkọ mẹta ni wọn gbe wa titi di asiko yii ko si ẹni to mọ iye wọn.
Agbesnusọ ọlọpaa ipinlẹ Osun SP Yemisi Opalola fidi ọrọ naa, o si fi kun pe awọn ikọ ọlọpaa ti le awọn adigunjale naa lati se awari wọn.
- Ìjọba Eko jáwọ́ nínú ẹ̀sùn tó fi kan Ọba Ogboni pé ó pààyàn ní ìwọ́de Yoruba Nation ní Ojota
- Wo àwòrán ìgbéyàwó ọkùnrin tó gbé obìnrin mẹ́rin níyàwó lọ́jọ́ kan ṣoṣo
- Ìjọba Eko jáwọ́ nínú ẹ̀sùn tó fi kan Ọba Ogboni pé ó pààyàn ní ìwọ́de Yoruba Nation ní Ojota
- Afẹnifẹre kan sárá sí ẹ̀ka ètò ìdájọ́ Nàìjíríà lórí ìdájọ àwọn ti wọ́n kó nílé Sunday Igboho
- Ọmọ ìjọ RCCG f'ara gba ìbọn lóríi pẹpẹ níbi ìsìn ìkómọ, ó gba ibẹ̀ kú!

















