Ibrahim Babangida, IBB: Mo gbìyànjú ipá mi kí June 12 má yọrí sí ogun ní 1993 ni- Badamosi Babangida

Oríṣun àwòrán, @Babangida
Aarẹ ologun Naijiria nigba kan ri, Ibrahim Babangida ti sọ pe oun gbogun ti iwa jẹgudujẹra lasiko ijọba oun ju ti asiko ijọba Aarẹ Muhammadu Buhari to wa lode lọ.
Babangida lo fi ọrọ naa lede lasiko ifọrọwerọ kan pẹlu ileeṣẹ iroyin Arise TV.
O ni eeyan mimọ ni awọn to ba oun ṣiṣẹ lasiko ijọba oun yatọ si irufẹ awọn eeyan ti Aarẹ to wa lori alefa bayii ko sọdi.
- Wàhálà àti ìkùnsínú láàrin ọmọ ẹgbẹ́ PDP, kí ni ọ̀nà àbáyọ?
- Ilé ẹjọ́ ju ọmọ ààrẹ Naijiria tẹ́lẹ̀, Umar Musa Yar'Adua sí ẹ̀wọ̀n nítorí ẹ̀sùn ìpànìyàn
- Olùwọ́de EndSars mìí tí oyún bàjẹ́ mọ́ lára ni ẹ̀wọ̀n Akure, Bukunmi Ayodele gba òmìnira
- "Ẹ yé fún àwọn ọkọ yín lọ́yàn mu mọ́, àwọn ọmọ ló lọyàn"
- Yéèpà, òfin ìtakété síra ẹni forí ṣánpọ́n lásìkò ọdún Osun Osogbo
Babangida sọ pe oun gbogun gbaṣẹ lọwọ gomina kan lọdun naa lọhun lẹyin to ko ₦313,000 owo ilu sapo.
Sugbọn laye ode oni, ijọba ko ṣe ohunkohun nipa awọn eeyan to ti ko ẹgbẹlẹgbẹ biliọnu naira jẹ.
Nigba ti wọn beere erongba Babangida lori akitiyan ijọba to wa lode lati gbogun ti iwa ajẹbanu; o sọrọ ilẹ kun.
Wo ohun tí Babangida sọ nípa àwọn ajìjàgbara Yoruba Nation
Àwọn èèyàn kówó ìjọba jẹ nínú ìjọba Buhari ju àsìkò tí mo wà lórí àléfà lọ
O ni: "Pẹlu awọn akọsilẹ atawọn iroyin ti a n fi oju ri, o ṣoro lati ṣafiwe bi awọn eeyan ṣe n lu owo ilu ni ponpo laye ọjọhun si asiko ijọba alagbada ti a wa yii."
"Mo da gomina to ko ₦313,000 jẹ duro lẹnu iṣẹ, ṣugbọn bayii, awọn to ko owo to le ni biliọnu naira jẹ n yan fanda laarin ilu."
"Nitori naa, ta lo n gbogun ti iwa ajẹbanu ninu ijọba ti a sẹ ati ijọba to wa lode lonii?"
Babangida ni ibaṣepọ to dan mọran lo wa laarin oun ati Aarẹ Muhammadu Buhari, amọ awọn akọroyin lo n da aarin awọn mejeji ru.
Ni ti oun to waye lasiko June 12, ajagunfẹyinti naa ni o ṣeeṣe ki iditẹgbajọba waye to ba jẹ pe awọn kede esi idibo igba naa.
O ni "To ba jẹ pe a kede esi idibo June 12, 1993 ni, o ṣeeṣẹ ki iditẹgbajọba waye, eyii ti yoo ta ẹjẹ ọpọ eeyan silẹ."

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Ni ti ọrọ Sunday Igboho ati Nnanmdi Kanu, Babangida sọ pe kii ṣe tuntun ki awọn araalu maa bere fun iyapa, ṣugbọn o da le ohun ti wọn n bere fun ni pato.
O pari ọrọ rẹ pe "O ti le ni aadọta ọdun ti a ti gba lati maa gbe papọ gẹgẹ bii ọmọ iya kan ni Naijiria, a si ti ṣe oniruru ijiroro bii 500 lori ibaṣepọ wa, ohun to yẹ ki a maa lepa bayii ni ibaṣepọ ọhun ko ṣe ni bajẹ."
















