Seyi Makinde: Gómìnà ìpínlẹ̀ Oyo ní òun jẹ dòdò báwọn nkan ṣe ń pè òun ní ''audio governor''

Oríṣun àwòrán, @seyiamakinde
Gomina ipinlẹ Oyo, Seyi Makinde sọ pe ipakọ o gbọ suti, ori ẹlẹgan an lo daru lọrọ awọn to n pe oun ni ''audio governor.''
Makinde sọrọ yii nigba to n ṣe ifilọlẹ awọn kọmiṣọnna meje to yan sipo pada lọjọ Ẹti niluu Ibadan.
Gomina ipinlẹ Oyo ṣalaye ninu atẹjade kan ti akọwe iroyin rẹ, Taiwo Adisa fi sita pe awọn alako ijọba oun ko ni ṣai ri ariwisi kan tabi omiran nipa iṣejọba oun.
- Èèmọ̀ rèé o! Àrá sán pa èèyàn 17 níbi ayẹyẹ ìgbéyàwó, ọkọ ìyàwó farapa
- Sunday Igboho ti ní kí Ìjà òmìnira Yorùbá Nation tẹ̀síwájú láìnáání ìdojúkọ àwọn ìjọba- Alhaji Ajikobi!
- Ìgbà díẹ̀ ló kù kí Secondus parí sáà rẹ̀, ẹ jẹ́ kí a fi ara dà á títí yóò fi lọ PDP
- Àrá kọ ṣàràà! Ó sán pa èèyan 16 tó ń ya "Selfie" lórí ilé gogoro
- Ẹran Akíka(Pangolin) àti ìwo Erin d'ẹ́rù b'olẹ̀, ìjọba f'òfin gba bílíọ́nù 22 ẹran ara wọn
- Àṣìṣe ńlá ni Tinubu ṣe tó ti Buhari lẹ́yìn tó fi dé ipò- Oba Shomolu-Bariga
- Dánáfojúrà nìyí, abàmì eégún tí ń gbé inú iná ṣọlá
Amọ, Makinde sọ pe ijọba oun ko ni kaarẹ nipa pipese ohun amaye dẹrun fawọn eeyan ipinlẹ Oyo.
''Mo ranti ni bii ọdun kan sẹyin pe awọn kan maa n sọ pe ''audio'' ni gbogbo iṣẹ ti a sọ pe a n ṣe nipinlẹ Oyo.
Ṣugbọn to jẹ pe ''audio'' lawọn iṣẹ iṣẹ ti a nṣe ni tootọọ, o tumọ si pe awọn eeyan n ri ẹri ohun ti a n ṣe.
Nigba ti a ba ṣetan ni wọn yoo mọ pe ọpọn ti tun siwaju ninu eto iṣejọba nipinlẹ Oyo.
Laipẹ yii ti mo n ba gomina kan sọrọ lo sọ fun mi pe, ''audio governor'' ni wọn n kọkọ pe mi.
Ṣugbọn ni bayii wọn ti n ri ohun ti a n ṣe, wọn n wa beere bo ya a maa le tẹsiwaju lati maa ṣe ohun ti n ṣe bayii.
A o ti jẹ owo oṣu awọn oṣiṣẹ ati owo ifẹhinti fun ọdun meji, awawi naa ni wọn yoo maa wa titi ti wọn ko fi ni ri nkan kan sọ mọ,'' Makinde lo ṣalaye bẹẹ.
Makinde rọ awọn kọmiṣọnna to ṣẹṣẹ yan sipo lati tubọ ṣiṣẹ takun takun ki awọn eeyan ipinlẹ Oyo le ri ere ijọba oun jẹ.
Gomina ni asiko ti ko si adari gidi ni ipinlẹ Oyo ti lọ.
O ni gbogbo kọmiṣọnna lo ni ipa pataki lati ko ninu titu ọkọ ipinlẹ Oyo lọna tawọn araalu yoo fi gbadun ijọba.
- Wo àwòrán ìgbéyàwó ọkùnrin tó gbé obìnrin mẹ́rin níyàwó lọ́jọ́ kan ṣoṣo
- Òjò àrọ̀rọ̀dá gbẹ̀mí èèyàn mẹ́ta ní Oshogbo,ọ̀pọ̀ dúkìá ṣòfò
- Kò sí olóṣèlú kankan tó ń pàṣẹ fún wa pé kí á máa ti aráálú mọ́lé- DSS
- Àwọn ìlúmọ̀ọ́ká Mẹ́wàá to kú nínú oṣù keje odun 2021
- Ilé ẹjọ́ ju ọmọ ààrẹ Naijiria tẹ́lẹ̀, Umar Musa Yar'Adua sí ẹ̀wọ̀n nítorí ẹ̀sùn ìpànìyàn
















