Mide-Funmi Martins: Kí ló dé táwọn èèyàn ń ṣ'épè fún Mide Martins torí àbúrò rẹ̀ àmọ́ tí kò fèsì? - ESABOD

Esabod ati Mide Martins

Oríṣun àwòrán, Mide Martins, Esabod

Gbajugbaja sọ̀rọ̀ sọ̀rọ̀ orí ayélujára, Esther Aboderìn tí ọ̀pọ̀ mọ si Esabod ti fi epe kabiti kabiti ránṣẹ́ sì àwọn tó ń wá egun ọ̀rọ̀ lè gbajugbaja Òṣeré Mide Martins.

Mide Martins lo jẹ ọmọ olóògbé Funmi Martins lórí ọrọ pé kò tọju àbúrò rẹ̀, Damilare to wá ní ìkòkò nígbà tí ìyà rẹ faye silẹ.

Kii kúkú ṣe ìgbà àkọ́kọ́ tí ọrọ yìí yóò jáde rèé torí ni igba to sẹlẹ keyin, àwọn èèyàn dá sii.

Tó bẹ́ẹ̀ tí bàbá ọmọ náà gangan ti òun náà jẹ ìlumọọka olorin Afro-Juju, Sir Shina Peters jáde síta láti sọ pé òun lòun bí ọmọ náà kì gbogbo ayé dárí jì òun.

Àkọlé fídíò, Sunday Igboho Update: Igboho ti sọ ohun tó fẹ́ kí a ṣe tí ọ̀rs bá bẹ́yìn yọ- Saheed Yusuf

Kí wá lọ tún kan Mide-Funmi Martins mọ nínú ọ̀rọ̀ yìí?

Ní àkọ́kọ́, ọ̀pọ̀lọpọ̀ rii pe Mide kii fèsì rárá àti rárá lórí ayélujára bí àwọn èèyàn bá ti ń sọ̀rọ̀ nípa ọmọkùnrin àbúrò rẹ̀ yìí.

Àmọ́ṣá, lọpọ ìgbà ni àwọn akọroyin ti fi fídíò iforowanilenuwo wọn pẹlu ọmọ náà àti ẹ̀gbọ́n ìyá rẹ tó ń gbé lọdọ rẹ sita àmọ́ kò fi bẹẹ si fídíò kankan tí Mide fúnra rẹ ti fèsì.

Esabod bẹ̀rẹ̀ si ni wù orúkọ àwọn èèyàn tó ṣepé fún Mide síta ó sì ń dá epe náà padà sórí wọn torí ni tìrẹ kò sohun tó burú tí Mide ṣe.

"Ṣe dandan ni ki Mide tọju ọmọ yìí ni, àbúrò rẹ̀ taa ń sọ yìí tí lè ní ọmọ ọdún méjìdínlógún ".

Ó ní osere bìnrin Adunni Olorisa kan ń ṣe ìlara lásán ni.

O ní àrùn ọpọlọ lo n dá a láàmú to jẹ pe kii se ìgbà àkọ́kọ́ to bá àwọn osere ja niyii. Ó bú ẹnu atẹ lu bí Adunni ṣe ń ṣepe fún Mide.

Iroyin sọ pé Adunni gbé fídíò kan jáde níbi tó ti ń pe fún kí àwọn eleyinju àánú máa dá owó láti ran ọmọ náà lọwọ to tún wà ń dá orúkọ Mide Martins pelu ohun tó ṣe.

"Kódà kii se dandan kí òbí rẹ tọju rẹ, mi ò ní kii ṣe ojúṣe wọn ò àmọ́ ẹni tí irú rẹ bá sẹlẹ si ko tesiwaju ninu igbe ayé rẹ ".

Àkọlé fídíò, Olawale Dada: Igbá bárà kọ́ ló kàn, àwa náà n ṣoríire láyé pẹ̀lú ìpèníjà 'Cerebral Palsy'

Esabod ni ọmọ tí wọn ń sọ yìí tí tójú bọ pé ó leè lọ wà isẹ ṣe.

Àti pé níwọ̀n ìgbà tí Sir Shima Peters tí gba pe oun ni bàbá rẹ̀ tó ṣí ṣèlérí fún gbogbo ayé pé òun yóò tọju rẹ, o ni ki lo ṣe tí wọn tún wà ń fún ogún mọ Mide Martins.

Esabod ni wọn tún ń kó ọkọ Mide Martins pọ gan tí wọn ró èrò kí òun àti Afeez Owó àti Mide ìyàwó rẹ tuka nítorí ọrọ Damilare.

Àkọlé fídíò, Oba Gbolahan Timson shomolu: Obasanjo ti jẹ́wọ́ pé 'Mistake' ni Buhari ṣùgbọ́n...

Esabod: "Àìmọye àwọn ọmọ tó wà nilu oyinbo tí kò tójú ìyá àti bàbà wọn, irú wọn náà mọ pe oun ó lè jẹun ọmọ, àmọ́ ẹyin ẹ fi idajọ tó wà láàrin Mide àti ìdílé rẹ silẹ".

Ó figbe tá pé kí wọn fi Mide lọrun silẹ lórí ọrọ yìí.

"Ẹ rántí pé Mide náà ti ní ìdílé tirẹ kí wọn fii silẹ".

Ẹwẹ, àti ori àti àbọ̀ ohun tó tún wú ọ̀rọ̀ yìí síta kò tíì loju gẹgẹ bí kò ṣe sí ẹni tó gbọ́ bóyá owó kankan jáde lára ohun tí wọ́n ń gbèrò láti kó jọ fún iranlọwọ ọmọ náà.