Niger Republic killings: Buhari ṣèlérí ìrànwọ́ láti dojú ìjà kọ agbésùnmọ̀mí láwọn ilẹ̀ tó yí Nàijíríà ká

Oríṣun àwòrán, Facebook/Bashir Ahmad
Aarẹ Muhammadu Buhari ti bu ẹnu ẹtẹ lu iṣẹlẹ ipaniyan to ṣẹlẹ ni orilẹede Niger Republic.
Aarẹ Buhari sọrọ yii lọjọ Ẹti lori bi iṣẹlẹ igbesunmọmi ṣe n gbilẹ si to si n tan kalẹ kaakiri.
Eeyan bii mọkandinlaadọrin lawọn agbesunmọmi pa ni ifanna faṣu laarin ibode Niger ati Burkina Faso.
- "Ó dùn mí pé èmi ló bí Abubakar Shekau tó dá ayé lóró"
- Ìkúnlẹ̀ Abiyamọ oo! Ìyá ju ọmọ rẹ̀ méjì sí Kànga
- Ọ̀pọ̀ ẹ̀mí àti dúkìá sọnù sínú ìjàmbá iná Kẹrosínìì l‘Abuja
- Ọ́dọ́kùnrin 18 láti òkè ọya pẹ̀lú ohun ìjà olóró dojú ìjà kọ Àmọ̀tẹ́kùn l'Ondo
- Gómínà díbọn lọ ilé ìwòsàn, òṣìṣẹ ìlera tó gba rìbá N10,000 wọ gàù
- Ìdìbò gómìnà Anambra gbérasọ, ìíú dá wáí-wáí, aráàlú ń sá kíjo kíjo
- Wo ohun tó ṣẹlẹ̀ nílé ẹjọ́ lónìí lórí ìgbẹ́jọ́ Baba Ijesha
- Kí ló so Yemi Osinbajo pọ̀ mọ́ ilé alájà púpọ̀ tó dà wó ní Eko?
- Kókó méjìlá nípa ìgbé ayé Femi Osibona
- "Amẹ́ríkà ni Wale Bob-Oseni ń lọ, ìpè fóònù tó gbà, ló gbe lọ síbi ilé tó dà wó"
Ninu atẹjade ti oludamọran Aarẹ Buhari, Garba Shehu fi sita, aarẹ ṣeleri iranwọ fun orilẹede Niger atawọn orilẹede to yi Naijiria ka lati doju ija kọ awọn agbesunmọmi nibẹ.
Buhari ṣe apejuwe iṣẹlẹ ipaniyan naa gẹgẹ bi eyi to ba ni lọkan jẹ pupọ.
''Ibanujẹ ni o jẹ bi awọn agbesunmọmi ṣe da awọn eeyan loro kaakiri apa iwọ oorun ilẹ Afirika.
A gbọdọ sa gbogbo agbara wa lati ri pe a ṣegun awọn agbesunmọmi lapa iwo oorun Afirika.
Ọrọ igbesunmọmi kii ṣe ohun ti a le maa fi oju iṣẹlẹ abẹle wo mọ.
Igbesunmọmi dabi ina inu ọyẹ to n ran kaakiri bayii lapa iwo oorun ilẹ Afirika.
Asiko ti wa to bayii lati wa egbo dẹkun fawọn agbesunmọmi to n ṣakoba fun ọrọ aje awọn orilẹede lapa iwọ oorun Afirika,'' Buhari lo ṣalaye bẹẹ ninu atẹjade ti ileeṣẹ aarẹ fi sita.

















