Sunday Igboho: YWG ní káwọn àgbà Yorùbá báwọn ajìjàgbara sọ̀rọ̀ láti dẹkun ìpè fún ìyapa

Igboho ati ami idam YWG

Ẹgbẹ Yoruba Welfare Group (YWG), ti kesi awọn ọba alaye atawọn asaaju oloselu nilẹ Yoruba lati dide doola aawọ to n waye laarin Sunday Igboho ati eyi to fi n da si ijọba apapọ.

Ẹgbẹ YWG lọgun bẹẹ ninu atẹjade kan to fisita eyi ti aarẹ ẹgbẹ, Comrade Abdulhakeem Adegoke Alawuje fọwọsi to da lori bi DSS se kọlu ile ajijagbara naa ati bi ijọba apapọ se kede pe oun n wa Sunday Igboho.

Ẹgbẹ naa wa rọ ijọba apapọ lati jẹ ki awọn agbaagba nilẹ Yoruba ba Sunday Igboho atawọn ọmọlẹyin rẹ sọrọ lọna ati jẹ ki alaafia jọ̀ba.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

O ni eyi yoo tun fun wọn lanfaani lati dẹkun idunkooko lati da ilu ru nipa bi wọn se n pe fun ominira ilẹ Yoruba kuro lara Naijiria.

"A n rọ awọn eekanlu nilẹ Yoruba lati gbe ọrọ ẹsin tabi oselu ti sẹgbẹ kan, ki wọn si fori jin Sunday Igboho lori awọn ẹsẹ to le sẹ wọn.

Àkọlé fídíò, 'Oko ni mo wà lọ́nà "Express" Ilesha tí àwọn agbébọn yìnbọn bá ẹnu mi tí mò fi dà báyìí'

Amọ ki wọn dide lati gba oun atawọn alatilẹyin rẹ lọwọ awọn ẹsun ti ijọba apapọ fi kan wọn nitori alaafia ilẹ Yoruba se koko.

Gẹgẹ bii ajogunba wa, Ololufẹ alaafia ni awa ọmọ Yoruba, a ko si le kuna ninu ojuse yii, paapaa lori ọrọ to nii se pẹ́lu ilẹ baba nla wa."

YWG ni oun le fi ọwọ sọya pe ẹya Yoruba ko fara mọ iyapa Naijiria, to si n fẹ orilẹede to wa ni isọkan ati alaafia nibi ti idajọ ododo, ibaradọgba, aisegbe sibikan ati isejọba rere yoo ti wa.

Ẹgbẹ naa wa n fi ọwọ sọya pe oun yoo maa kan si awọn asaaju nilẹ Yoruba lati da si ọrọ to wa nilẹ yii, ki wọn si jẹ ki alaafia jọba nilẹ Yoruba.