Oduduwa Nation: Àwọn tó ń polongo Oduduwa Nation fẹ́ ba àláàfíà, ìfẹ́ àti ìṣọ̀kan ilẹ̀ Yorùbá jẹ́ ni- YWG

Oríṣun àwòrán, YWG
Ọjọ Satide, ọjọ kẹtadinlogun, oṣu Kẹrin, ọdun 2021 ni oriṣiriṣi ẹgbẹ ko ara wọn jọ ni gbọngan Mapo, ni agbegbe Ọja-Ọba nilu Ibadan, lati tubọ polongo idasilẹ Oduduwa Nation.
Ṣugbọn ṣa, ẹgbẹ to wa fun igbaye-gbadun ẹya Yoruba, Yoruba Welfare Group, YWG, ti sọ pe awọn eeyan to n polongo igbesẹ yii ko le paṣẹ nkan ti Yoruba o sẹ.
Aarẹ ẹgbẹ YWG, Abdulhakeem Alawuje, ninu atẹjade to fi sita ni ọjọ Satide, fi ẹsun kan awọn to n polongo idasilẹ orilẹ-ede Oduduwa, pe wọn fẹ ẹ ba alaafia, ifẹ ati iṣọkan to wa nilẹ Yoruba jẹ ni.
- Àwọn tí àkóso ìjọba bọ́ lọ́wọ́ wọn ló ń ti Igboho lẹ́yìn lórí ìdásílẹ̀ Oodua Nation - YWG
- Lóòtọ́ọ́ ni Hausa àti Yorùbá wọnú ara wọn, àmọ́ ìyẹn kò ní kí Yorùbá má lọ - Oba Yoruba Bauchi
- Àwọn olùpolongo Oduduwa Nation àti ọlọ́pàá kojú ara wọn ní Sagamu
- "Seyi Makinde ló ṣàtìlẹyìn ètò ààbò fún ìwọ́de Oduduwa Nation"
O ni nkan ti ko ni i bojumu, ni ki awọn ọdọ ati araalu yọnda ara wọn lati jẹ ohun elo idaluru, lọwọ awọn iranṣẹ Satami.
"Igba ikẹhin re e ti a o fi ikilọ sita fun awọn to wa nidi ijijagbara oṣelu, pe ki wọn o dẹkun radarada ti wọn n ṣe nilẹ wa.
"Ilẹ Yoruba ko le jẹ ibi ti wọn o ti ma a pilẹ iwa ọdaran."
Bakan naa ni Alawujẹ ke si gbogbo awọn ọba nilẹ Yoruba pe ki wọn o fi ewe ọmọ mọ awọn eniyan naa l'eti, nitori pe "ko ni i bojumu ki a maa gbe igbesẹ tako ara wa ni ẹkùn kan naa".
O fi ẹsun kan pew awọn to n lewaju awọn eeyan naa, paapaa Ọjọgbọn Banji Akintoye, n ṣe bẹ ẹ nitori imọtara ẹni nikan.
- Ẹ má dán abẹ́rẹ́ Covid-19 wò lára mi, mi ò gbà! Mi kìí ṣe ẹmọ́ òyìnbó- David Oyedepo
- Aṣọ tí mo wọ̀ lọ sí 'Headies Award' ló sún mi débi oríire ipò aṣojú LAWMA- Eniola Badmus
- Ìyá Leah Sharibu ké gbàjarè sí ìjọba Buhari
- INEC: Kò sí ìká tí o kò lè fí dìbò, ṣáà tí tẹ̀ ẹ́ sójú ẹ dáadáa
- Sanwo-Olu àti Osinbajo ẹ gbà mí o, mo ti jẹ gbèsè - Iyabo Ojo figbe ta















