Oduduwa Nation: Àwọn obìnrin náà ní alálẹ̀ ló rán àwọn wa sílé lórí bí Yorùbá yóò ṣe dá dúró

Ooni Adeyeye Ogunwusi gbalejo awọn obinrin bii ẹgbẹrun kan

Oríṣun àwòrán, Ooni Adeyeye Enitan Ogunwusi, Ojaja ll Facebook

Agbarijọpọ àwọn obinrin to jẹ ọmọ Yoruba to wa nilẹ okeere ti ṣabẹwo si aafin Ooni ti Ife, Ọba Adeyeye Ogunwusi, lati beere fun ipinnu to fẹṣẹ mulẹ.

Awọn obinrin ọhun ti iroyin sọ pe wọn to ẹgbẹrun kan niye, lo wa lati orilẹ-ede mẹtadinlogoji.

Alànà fun ìlànà Ọmọ Oodua, Ọjọgbọn Banji Akintoye si lo lewaju wọn lọ si aafin Ooni.

Akọwe ikede fun Ọjọgbọn Akintoye, Maxwell Adeleye sọ ninu atẹjade kan pe, lọjọ Aiku ni awọn obinrin naa wa lati orilẹ-ede Amẹrika, Canada, Argentina, UK, Spain, ati awọn orilẹ-ede míì, lati bẹ Ooni wo.

Oludari awọn obinrin naa l'agbaye, Ọmọọbabinrin Simisade Kuku-Onayemi ati Akọwe rẹ, Dokita Owowunmi Babalola-Okocha lo lewaju wọn.

Ooni Adeyeye Ogunwusi gbalejo awọn obinrin bii ẹgbẹrun kan

Oríṣun àwòrán, Ooni Adeyeye Enitan Ogunwusi, Ojaja ll Facebook

Awọn obinrin naa ni àwọn Alaalẹ ilẹ Yoruba lo sọ pe dandan ni ki awọn rin irinajo ẹ̀mí, ti yoo mu ki idasilẹ orilẹ-ede Oduduwa tete waye, lai si itajẹsilẹ.

Wọn ni nkan to mu awọn wa si ilẹ baba awọn niyii.

Kuku-Onayemi sọ pe, "gbogbo àwọn to wa fun àbẹ̀wò naa lo ri taje ṣe, sugbọn bi nkan ṣe ri nilẹ baba wa ko dun mọ wa ninu.

Nitori naa la ṣe wá, láti wa ọna abayọ ni ilana abalaye."

Amin iyasọtọ kan

Ọ̀pọ̀ Yorùbá kò fẹ́ àtúntò mọ́, wọ́n fẹ́ ká dá dúró ni, èrò tèmi nìkan kọ́ - Gani Adams

Aarẹ Gani Adams

Oríṣun àwòrán, Facebook/Seyi Makinde

Aarẹ Ọna Kakanfo ilẹ Yoruba sọ pe pupọ ọmọ ilẹ Yoruba lo ti ṣetan, to si faramọ dida ijọba orilẹede ara wọn ṣe.

Gani Adams fidi ọrọ yii mulẹ nibi ifilọlẹ iwe kan to waye nilu Eko l‘Ọjọru

Agba ilẹ Yoruba naa ni oun faramọ ero ọkan awọn eeyan to sọ pe, ipinu Yoruba ti sun kuro nibi ki atunto iṣejọba waye nikan, si eyi to gbagbọ pe ki wọn maa da ijọba ilẹ wọn ṣe.

''Nkan tawọn olori Yoruba n beere ree, ti atunto ko ba waye ni Naijiria laarin ọdun mẹta si akoko yii, ọjọ iwaju ko le sunwọn.

Orisirisi atunto lo wa, o si yẹ ki wọn mọ iru eleyi taa n fẹ''

Iba tun sọ pe ti Naijiria yoo ba ṣe atunto, o yẹ ki wọn kẹkọ lara nkan to waye laarin ọdun 1960 si 1963, eyi to faaye gba ki ẹkun kọọkan maa mojuto idagbasoke ara rẹ.

O ni koda nigba aye ijọba ologun ọgagun Sani Abacha, igbalaaye wa labẹ ofin pe ki ẹkun mẹfẹẹfa lorileede Naijira maa ṣeto ara wọn niwọn bi aaye ba ṣe gba wọn.

''Ohun temi n fẹ ni iṣejọba awarawa. A o si gbaradi fun idunadura eyikeyi to ba waye''

Aarẹ Gani Adams

Oríṣun àwòrán, Facebook/Seyi Makinde

Lẹnu ọjọ mẹta yii, awọn olori ati aṣaaju ilẹ Yoruba ti n tẹnu mọ atunto iṣejọba eleyi ti yoo gba agbara kuro lọdọ ijọba apapọ, ti yoo si faaye silẹ fun ẹkun kọọkan lati ṣeto ara wọn.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Nibi ayẹyẹ taa n wi yi, aṣoju Ooni Ifẹ, iyẹn alara ti ilu Oodaye Ifẹ, Oba Segun Layade sọ pe, pupọ awọn alumọni ẹkun iwọ oorun guusu, lawọn eeyan ariwa n jẹ anfaani rẹ.

Oun naa wa pe fun idapada kikọ ẹkọ nipa itan lawọn ileẹkọ Naijiria .

Àkọlé fídíò, Egbejila Fish Village: Àwọn ọlọ́sìn ẹja ní àwọn fi iṣẹ́ báńkì sílẹ̀ wá ṣe ọ̀sìn ẹja ni

Bode George to jẹ eekan ninu ẹgbẹ oṣelu PDP, ti ọjọgbọn Charles Akitoye ṣoju fun naa sọ pe, eto iṣejọba Naijiria bo ti ṣe wa, ti yiwọ pupọ ati wi pe, eto ọrọ aje Naijiria fi sapa kan.