Niger School Fire: Àlàyé rèé lórí bí iná ṣe jó ogún akẹ́ẹ̀kọ́ alákọ́bẹ̀rẹ̀ pa níléèwé

Awọn ẹbi ati ara awọn akẹkọọ ogun ti bẹrẹ si ni ṣọfọ lẹyin ti ijamba ina gbẹmi awọn ọmọ wọn ni ileewe.
Iṣẹlẹ naa waye ni ileewe alakọbẹrẹ ni agbegbe Pays Bas, ni ilu Niamey to jẹ olu ilu orilẹede Niger.
Akọrọyin BBC, Tchima Illa Issoufou ni ilu Niamey ni, ina naa bẹrẹ ni ẹnu ọna ileewe naa to ni akẹkọọ to le ni ẹgbẹrin.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ẹ̀ẹ̀mẹrin ni ọ̀dá owó já mi kulẹ̀ lásìkò tí mo fẹ́ wọ Fáṣítì - Biola Adebayo
- Ìjínigbé akẹ́kọ̀ọ́ Chibok pé ọdún méje, ọjọ́ wo ni wọn yóò padà sílé?
- "Ajínigbé ní tí a kò bá tètè sanwó, àwọn yóò gbé ọmọ mi sálọ, tí yóò sì kọ́ ìbọn yínyìn"
- Gani Adams yarí pé èdè Yorùbá gbọdọ̀ di ọ̀rànyàn nílé ẹ̀kọ́ alákọ́bẹ̀rẹ̀
- Báwo ní Nàíjíríà ṣe ná $30m fún ààbò akẹ́kọ̀ọ́ lẹ́yin ìjínigbé akẹ́kọ̀ọ́ Chibok?
- Òjòóró ló wáyé lásìkò ìbò PDP l‘Osogbo - Fayose
- ''Ẹ gbà mí o, ọkọ mí ti lé mi nílé torí mo ya ‘tatoo’ Tinubu sára''
Titi di asiko yii, koi tii si ẹni to mọ ohun to fa iṣẹlẹ ina naa.

Amọ, ileeṣẹ panapana to wa si ibi iṣẹlẹ naa ni, bi wọn ṣe kọ awọn yara ikẹkọọ naa bii ahere papọ, lo mu ki ina naa gba gbogbo ileewe naa.
Olori ileesẹ panapana Sidi Mohamed ni, awọn oṣiṣẹ oun tete de ileewe naa lati pa ina to n jo ran-in ran-in ọhun, ki awọn to ri pa.

''Yara ikawe mejilelogun lo jona raurau pẹlu awọn akẹkọọ ogun to ha si inu yara ikawe naa, ti wọn si ku.''
''Ko tun si ọna pajawiri kankan fun awọn akẹkọọ lati gba jade, ti awọn miran tilẹ gun ogiri, lati raye sa asala fun ẹmi wọn.''
''O si ṣeni laanu wi pe awọn akẹkọọ ọmọde ti wọn nilo iranwọ to ha si inu ina ọhun lo ku, ninu ijamba ina naa.''

Bakan naa ni Sidi Mohamed ni awọn ileewe yii ti wọn kọ si opopona, ti atẹkun lile si n fẹ pẹlu ohun to ṣe ijamba fun awọn ọmọde, ni ile alakọbẹrẹ naa.
- ''Ẹ gbà mí o, ọkọ mí ti lé mi nílé torí mo ya ‘tatoo’ Tinubu sára''
- Ajínigbe gbé sọ́jà, obìnrin méjì ní Ibadan, wọn tún yìnbon pá ọlọ́pàá l'Abuja
- Okorocha bọ́ sí gbaga EFCC lẹ́yin ọjọ́ díẹ̀ tó gba àmì ẹ̀yẹ n‘Ibadan
- Toyosi Adesanya yarí lórí ọ̀rọ̀ Foluke Daramola
- Nǹkan márùn ún tó yẹ kí aláàwẹ̀ ṣe àti èyí tó yẹ kó yàgò fún


















