OPC: Àwọn àgbà ilẹ̀ Yoruba ní OPC àti Boko Haram kò jọra, kí wọn má fi ewúrẹ́ wé ẹkùn

Oríṣun àwòrán, OPC
Awọn agbagba ilẹ Yoruba kan ti sọ pe, bi ẹni fi ewurẹ we ẹkun ni ki eeyan maa fi ẹgbẹ OPC we ẹgbẹ agbesumọmi Boko Haram jẹ, nitori wọn ko jọ ara wọn.
Ṣaaju ni olórí àwọn ọmọ ogun Naijiria tẹlẹ, Abdulrahman Dambazau ti kọkọ sọ pe ọkan naa ni ẹgbẹ IPOB, OPC ati Boko Haram nitori afojusun awọn ẹgbẹ naa ni lati da ogun abẹle silẹ ni Naijiria.
Nigba to n ba BBC Yoruba sọrọ, Ọmọwe Taye Ayorinde to jẹ alaga ẹgbẹ Yoruba World Assembly sọ pe, agbesumọmi gan ni Dambazau funra rẹ fun afiwe to ṣe ninu ọrọ to sọ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Á fojú Sunday Igboho balé ẹjọ́, á sì gba ₦500m owó ìtanràn fún Seriki - Ẹgbẹ́ Fulani
- Ọmọ yẹrí ẹ, èpè ń bọ̀! Kí ló dé tí Foluke Daramola bu èpè jólẹ̀ lórí ayélujára?
- Àlàyé rèé lórí ikú tó pa ọmọ Ronke Oshodi Oke
- Wo ọ̀pọ̀ àǹfààní tó wà nínú eré ìdárayá Squash fún àgbéga ìlera àti ọrọ̀ ajé rẹ
- Òjò owó ń rọ̀ fún abilékọ ẹlẹ́sẹ̀ kan tó n ta pure water lójú pópó
- Ẹ wo ìdí tí omije fi bọ́ lójú Pasuma níbi ìgbéyàwó ọmọ rẹ̀ obìnrin
- Ikọ̀ aláàbò Ebube Agu bẹ̀rẹ̀ nílẹ̀ Igbo, tó túmọ̀ sí Amotekun
Ayorinde ni ko yẹ ki ẹni to jẹ ologun maa fi OPC we Boko Haram nitori awọn eeyan to n bọwọ fun ofin ni awọn ọmọ ẹgbẹ OPC jẹ.
O ni "Nigba miran eeyan a maa ba ọrọ agọ nibi ti yoo ti ro pe oun yoo ba ọrọ ọgbọn, bawo ni eeyan ṣe maa fi ewurẹ we ẹkun?"

Oríṣun àwòrán, Taye Ayorinde
"Awọn ọmọ wa lo wa ninu ẹgbẹ OPC, ṣugbọn ni ti Boko Haram, awọn Dambazau yii lo mọ awọn to wa nibẹ nitori awọn naa lo lo wọn lasiko eto idibo."
Ayorinde ṣalaye pe ko mu ọgbọn dani ki eeyan maa fi OPC to n ṣiṣẹ abo we awọn Boko Haram to n wu iwa ipaniyan ati ijinigbe.
Ẹwẹ, Alagba Sehinde Arogbofa naa da si ọrọ ọhun nigba to sọ fun BBC pe, iyatọ gedegbe lo wa laarin ẹgbẹ OPC ati Boko Haram.
O ni ilu Kano ni ẹni to da ikọ agbesumọmi Boko Haram ti bẹrẹ, ki wọn to le lọ ilu Maiduguri nibi to ti gbilẹ.

Oríṣun àwòrán, Sehinde Arogbofa
Arogbofa ṣalaye pe, Boko Haram lodi si iwe kika ati iwa ọlaju, ṣugbọn OPC ko ṣe bẹẹ, niṣe ni wọn n ja fun igbala awọn ti wọn n fi iya jẹ lawujọ.
O tẹsiwaju pe iwa jagidijagan pẹlu ibọn ni awọn Boko Haram fi n ṣọṣẹ, ko si ṣe ṣafiwe awọn OPC to jẹ pe awọn ọmọwe lo da ẹgbẹ ti wọn silẹ.
Alagba naa fi kun pe "Boko Haram atawọn ti ko fẹ itẹsiwaju Naijiria lo jọ n ṣiṣẹ papọ, ṣugbọn niṣe ni OPC n wa ilọsiwaju Naijiria."
Arogbofa pari ọrọ rẹ pe "awọn ẹlẹsin Musulumi lo kun ẹgbẹ Boko Haram nigba ti OPC ko ni nnkan ṣe pẹlu ẹsin, idi ree ti awọn Musuli, Kristeni atawọn ẹlẹsin abalaye ṣe wa nibẹ."
O ni "eyii ti ẹ ni Dambazau sọ yẹn kii ṣe ara ẹ o, ko sọ daa o, ẹ o le fi aja we ẹkun o."
Ẹwẹ, onimọ nipa eto abo kan, Arákùnrin Akin Adeyi sọ pe Dambazau ko ni imọ lo jẹ ko maa fi OPC we Boko Haram nitori wọn jina si ara wọn.
Gẹgẹ bo ṣe sọ, ara iṣoro ti Naijiria ni niyẹn nitori wọn ko sọ oju abẹ niko.
Adeyi sọ pe idojuti nla ni ọrọ naa jẹ fun Dambazu gẹgẹ bii ologun ati ipo to di mu ni Naijiria nitori ibi ti OPC ati Boko Haram ti n bọ ati iwa wọn kii ṣe ọkan naa.

Ìjà parí! Ẹgbẹ́ dókítà dáwọ́ ìyanṣẹ́lódì ọlọ́jọ́ mẹ́wàá dúró

Oríṣun àwòrán, United States Africa Command
Ẹgbẹ awọn dokita lorileede Naijira ti so iyanṣẹlodi ti wọn gunle rọ lẹyin ọjọ mẹwaa.
Dokita Uyilawa Okhuaihesuyi, tii se aarẹ ẹgbẹ awọn Dokita lo fidi ọrọ yi mulẹ fawọn akọroyin.
O ni ''ni nkan bi wakati kan sẹyin (lọjọ Abamẹta) la so iyanṣẹlodi naa rọ ni idahun si ẹbẹ awọn ọmọ Naijiria.''
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ìlẹ̀kẹ̀ otútú ọgbọ̀n, Ìrọ́kẹ́, àwa ẹlẹ́sìn ìbílẹ̀ náà fẹ́ káwọn ọmọ wa máa wọ lọ sílé ìwé - Elebuibon
- Àwọn ajínigbé bèèrè fún óúnjẹ àti suya kí wọ́n tó tú ọkọ, ìyàwó àtàwọn ọmọ sílẹ̀ l'Ondo
- Bí Oladeinde Fernandez ṣe rìn ín tó ń lúwẹ̀ẹ́ nínú ibú owó lókè òkun
- Èèmọ̀! Saka dáná sun 'ààlè' rẹ̀ tọmọ-tọmọ n'Ibadan, òun nàá tún jóná kú
- Àrà kengé! Ṣọ́ọ̀ṣì Church of England fẹ́ dá ère idẹ Benin méjì padà sí Nàìjíríà
O tẹsiwaju pe ''ijọba ti dahun sawọn ibeere kọọkan ninu ohun taa beere lọdọ wọn''
Ṣaaju ni ijọba Naijriia ti buwọlu iwe adehun kan pẹlu awọn ẹgbẹ dokita Naijira-igba keji ree ti wọn yoo buwlu iwe adehun laarin ọsẹ meji.

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Ninu ifọrọwanilẹnuwo kan, Minisita feto igbaniṣiṣẹ ni Naijiria, Dokita Chris Ngige sọ pe ''ipade taa ṣe lọjọ Abameta waye ki a baa le ṣe atunse si adehun taa kọkọ buwọlu pẹlu awọn Dokita''
O ni nitori eleyi awọn ti gbe igbimọ ẹlẹni marun un kan kalẹ, ti yoo mojuto awọn oṣiṣẹ ti ọrọ yii kan, taa si fun wọn ni ọjọ mẹta lati gbe orukọ wọn jade.
Lọjọ kinni oṣu Kẹrin lawọn ẹgbẹ dokita wọn yi gunle iyanṣẹlodi.
Ohun ti ẹgbẹ naa n beere lọwọ ijọba pọ, to fi mọ pe ki ijọba san owo oṣu ti wọn jẹ awọn dokita lai da ẹnikankan si.
Wọn tun beere fun afikun ida aadọta lori iye owo ajẹmọnu gbogbo oṣiṣẹ ilera, to fi mọ sisan gbese owo moriya iṣẹ Covid-19 fawọn to n ṣiṣẹ ni ile iwosan ipinlẹ to fi mọ awọn nkan miran.




















