Ebenezer Obey: Ìdí iṣẹ́ agbẹjọ́rò tàbí dókítà ni mo rò pé mo ti máa ṣe oríire

Oríṣun àwòrán, @THEWILLNG
Agbabọje akọrin juju, Ebenezer Obey Fabiyi ti tẹnu bọọrọ lori idi ti iya rẹ ko fi fẹ ko ya sidi orin kikọ.
O ni iya to bi oun lọmọ ko fi tọkantọkan ro wi pe oun yoo se isẹ orin nisẹ asela.
Ninu alaye ti ilumọọka akọrin yi se fun ileeṣẹ iroyin abẹle Punch, o sọ pe dipo isẹ olorin isẹ dokita tabi agbẹjọro ni iya oun nifẹ si ki oun se.
- A ti ṣetán láti fi ẹ̀mí wa lélẹ̀ fún òmìnira ilẹ̀ Yoruba, a ò níbi kankan ti a fẹ́ sálọ - Ọba Adetokunbo Tejuosoho
- Ọkọ̀ agbépò gbiná ní Benue, ẹni mẹ́sàn án kú, ṣọ́ọ̀bù 72 ọlọ́já iyebíye jóná
- Màálù 250 tasẹ̀ agẹ̀rẹ̀ wọ oko ní Ilaramọkin, ní ikọ̀ Amotekun bá sọ Màálù àti olówó rẹ sí gbaga
- Ṣé o fẹ́ lọ sí ọ̀run rere? Wo bí Naira Marley ṣe le ràn ọ́ lọ́wọ́ láti wọlé
Ko kuku si ẹni to mọ irinajo ẹda, nitori naa lo fi da bi ẹni pe iya Chief Commander fi maa n sọ fun tọsan-toru pe ko sinmi lati maa lu ilu kaakiri, ko si gbajumọ ẹkọ la ti le di dokita tabi agbẹjọro.
"Nise ni mama mi maa n sọ pe, ṣe iwọ ko fẹ soriire laye ni?"

Oríṣun àwòrán, @Go247B
"Bi o ba kọju mọ ẹkọ rẹ, ti o si di agbẹjọro se o mọ pe awọn eeyan yoo maa pe mi ni iya lawyer ni?"
Obey tun sọ pe mama oun yoo tun beere pe "ṣe iwọ ko nifẹ si ko ma wa ọkọ ayọkẹlẹ ni?''
O tẹsiwaju pe mama ko mọ ni ati pe oun ko da wọn lẹbi rara.
''Ṣugbọn nigba ti wọn ri pe isẹ orin yi lọna mi ati pe nnkan ti mo fẹ se niyẹn, wọn fi mi silẹ laaye ara mi.''
Ohun to n fa ifoya fun iya Ebenezer Obey gẹgẹ bi ohun to sọ ko sẹyin igbagbọ tawọn eeyan ni pe awọn olorin a maa mu siga, wọn a si maa mu ọti.
Lati le jẹ ki ọkan mama rẹ balẹ, Ebenezer Obey sọ pe oun ṣe ileri lati yago fun gbogbo nkan ti mama oun ko nifẹ si.
"Amọran ti wọn gba mi yi jẹ ojulowo amọran nitori nigba ti mo de oju agbami orin kikọ, gbogbo awọn nkan wọn yi ni mo ba pade."
''Pẹlu ogo lọdọ Ọlọrun mo ṣe ileri lati yago fawọn iwakiwa yi, mo si dupe pe mo se ileri yi notori ohun lo jẹ ki n yan kin yanju lonii niyẹn.''
- Ẹ má dán abẹ́rẹ́ Covid-19 wò lára mi, mi ò gbà! Mi kìí ṣe ẹmọ́ òyìnbó- David Oyedepo
- Wo bí ọkọ Ọbabìnrin ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sí, Prince Philip ṣe sètò ìsìnkú ara rẹ̀ kó tó dágbere fáyé
- "Seyi Makinde ló ṣàtìlẹyìn ètò ààbò fún ìwọ́de Oduduwa Nation"
- Wo ohun táwọn aṣọ́gbó ń kojú pẹ̀lú Ìnàkí tí wọ́n ń ṣọ́
- Akẹ́kọ̀ọ́ girama tó jẹ́ afurasí ẹlẹ́gbẹ́ òkùnkùn mẹ́rin bọ́ sọ́wọ́ ọ̀lọ́pàá l‘Eko















