Secret Cult: Ọjọ́ orí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ náà wà láàrin ọdún 14 sí 18

Oríṣun àwòrán, @GreaterLagosNG
Ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Eko ti fi ṣikun ofin mu awọn ọdọ mẹrin kan, ti wọn fẹsun kan pe wọn jẹ ọmọ ẹgbẹ okunkun.
Wọn ni awọn afurasi naa tẹkọ leti lọ si ipinlẹ Eko lati Ogun lati ṣakọlu si awọn ọmọ ẹgbẹ okunkun miran, to wa lawọn ile iwe girama kan lagbegbe Akinyele ati Alakukọ.
Gẹgẹ bii atẹjade ti alukoro ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Eko, Muyiwa Adejobi fi lede, o ni awọn afurasi ọhun jẹ ọdọ ti ọjọ ori wọn ko ju ọdun mẹrinla si mejidinlogun lọ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
Adejobi sọ pe meji lara awọn ọdọkunrin naa jẹ akẹkọọ ile ẹkọ girama Odewale Community High School to wa ni Ijoko, nipinlẹ Ogun.
Nigba ti awọn meji to ku jẹ akẹkọọ ile ẹkọ Tunik Internation School, to wa ni Dalemo Alakuko.
Atẹjade naa tẹsiwaju pe ni kete ti awọn agbofinro gbọ pe awọn ọmọ ẹgbẹ okunkun naa n mura lati kọlu awọn orogun wọn nile iwe miran ni wọn tọpaṣe wọn lọ.
Lara awọn ohun ija ti wọn ri lọwọ awọn afurasi naa ni ada, egboogi oloro, ati oriṣiriṣi oogun abẹnu gọngọ.
Ẹwẹ, kọmiṣona ọlọpaa ipinlẹ Eko, Hakeem Odumosu ti pasẹ pe ki wọn ko awọn afurasi naa lọ si agọ wọn to wa ni Ikeja.
- Ọlọ́pàá, fijilanté àti ọdẹ ìbílẹ̀ dóòlà obìnrin mẹ́ta lọ́wọ́ ajínjigbé l‘Oyo
- Èmi kọ́ ni mò n pín ìrẹsì lókè Ọya lásìkò àwẹ̀ yìí - Bola Tinubu
- Kọmíṣọ́nnà Ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọyọ gbọ́dọ̀ fí ipò sílẹ̀ nítórí ó kùnà láti dẹ́kun ìpàníyàn ní Ibarapa - Gani Adams
- Bolanle Ninalowo sọ̀rọ̀ sókè lórí ìdí tó fi kúrò nínú Islam di Krístẹ́nì
- Èèmọ̀ wọ̀lú, Ajínigbé fo ògiri wọnú ààfin, wọ́n jí oríadé gbé l'Ekiti
Lẹyin naa lo ni ki wọn bẹrẹ iwadii ni kikun ati ọna lati fi ṣikun ofin mu awọn ọmọ ẹgbẹ okunkun to jẹ orogun wọn, ti wọn n gbiyanju lati ṣakọlu si.


















