Ọwọ́ tẹ àwọn ọmọ ogun méje tó ń ṣe agbódegbà fún àwọn agbésùmọ̀mí ní Zamfara

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Ijọba ipinlẹ Zamfara ti sọ pe ọwọ ti tẹ awọn ọmọ ogun meje to n ṣe agbodegba fun awọn agbesumọmi ni ipinlẹ naa.
Ikede naa lo waye nibi ipade awọn akọroyin kan ti wọn ṣe nileeṣẹ to n ri si ọrọ to n lọ ati ọrọ abo.
Wọn ni awọn afurasi naa jẹwọ pe lootọ ni wọn ṣe ohun ti wọn fi ẹsun rẹ kan awọn, bẹ si ni awọn n fun awọn agbesumọmi ni awọn iroyin idankọnkọ nipa ileeṣẹ ologun.
Atẹjade naa ni ọkan ninu awọn eeyan ọhun jẹwọ pe oun maa n ko aṣọ ati irinṣẹ ologun fun awọn agbesumọmi naa.
O fikun pe N100,000 ni wọn fun oun lati ṣe iranwọ fun ẹgbẹ agbesumọmi.
Lasiko ti wọn mu, wọn ba aṣọ awọleke ti ọta ibọn kii wọ mẹsan an lọwọ rẹ, aṣọ ọmọ ogun mẹrin ati kaadi idanimọ ọmọ ogun kan.
Baka naa ni ọwọ tun tẹ dokita kan ti wọn ba ohun ija awọn ọmọ ogun lọwọ rẹ.
Atẹjade naa fi kun pe awọn ti ọwọ tẹ yii n ṣapẹrẹ ọrọ ti goimina ipinlẹ naa sọ ṣaaju pe, ẹnu yoo ya awọn arralu lẹyin ti aṣiri awọn to wa nidii iṣẹrubalu ba tu tan.
Lẹyin naa ni ijọba Zamfara rọ Aarẹ Muhammadu Bauhari lati fi alekun ọmọ ogun ṣọwọ si ipinlẹ ọhun gẹgẹ bii ileri to ṣe fun wọn ṣaaju.
- Ẹ má dán abẹ́rẹ́ Covid-19 wò lára mi, mi ò gbà! Mi kìí ṣe ẹmọ́ òyìnbó- David Oyedepo
- Aṣọ tí mo wọ̀ lọ sí 'Headies Award' ló sún mi débi oríire ipò aṣojú LAWMA- Eniola Badmus
- Sanwo-Olu àti Osinbajo ẹ gbà mí o, mo ti jẹ gbèsè - Iyabo Ojo figbe ta
- "Seyi Makinde ló ṣàtìlẹyìn ètò ààbò fún ìwọ́de Oduduwa Nation"
Lọjọ kẹtalelogun, oṣu Kẹta, ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Kano fi ṣikun ofin mu ọkunrin kan to n ta alupupu fun fun awọn janduku.
Agbenusọ ileeṣẹ naa, DSP Abdullahi Haruna Kiyawa ni ọkunrin naa jẹwọ pe oun ti ta alupupu bii ọgọrun fun awọn agbesumọmi ọhun ni obitibiti owo.
- Akẹ́kọ̀ọ́ girama tó jẹ́ afurasí ẹlẹ́gbẹ́ òkùnkùn mẹ́rin bọ́ sọ́wọ́ ọ̀lọ́pàá l‘Eko
- Ìgbeyàwó mú kí àpọ́nlé tó pọ̀ wà fún mi ju ti tẹ́lẹ̀ lọ - Tayo Sobola
- Ọlọ́pàá, fijilanté àti ọdẹ ìbílẹ̀ dóòlà obìnrin mẹ́ta lọ́wọ́ ajínjigbé l‘Oyo
- Èmi kọ́ ni mò n pín ìrẹsì lókè Ọya lásìkò àwẹ̀ yìí - Bola Tinubu
- Àwọn olùpolongo Oduduwa Nation àti ọlọ́pàá kojú ara wọn ní Sagamu













