Seyi Makinde: Ọ̀sẹ̀ àkọ́kọ́ ní December ni màá sìnkú ìyá mí

Oríṣun àwòrán, @seyiamakinse
Gomina ipinlẹ Oyo, Seyi Makinde ti ṣapejuwe iya rẹ gẹgẹ bi obinrin to ni akinkanju, to ṣe gbẹkẹle, to ṣiṣẹ karakara nigba aye rẹ.
Seyi Makinde lo sọ eyi lasiko to gbalejo Deji ti ilu Akure, to ṣe abẹwo si lati ba kẹdun lori iku iya rẹ to papoda ni ẹni ọdun mọkanlelọgọrin.
Makinde ninu ọrọ rẹ sọ wi pe, iya oun to jẹ ọmọ ilu Akure fihan gbangba pe, awọn ara ilu Akure jẹ eniyan ọtọ to ṣe e fi ọkan tan.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ìwọ́de EndSARS ló ń sọ pé inú ń bí àwọn ọ̀dọ́, ìjọba, ẹ náání wọn - Obasanjo
- Ẹ̀yin ọ̀dọ́ ti rí èrè ìwọ̀de yín lórí EndSARS àmọ́ ẹ ṣọ́ra, kẹ má baà sọ èrè náá nù - Tinubu
- Owó ìrànwọ́ Covid-19 dé, ìjọba fẹ́ san ₦75bn fún 54,000 olókoòwò
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Eko ti iléèwé pa nítorí ìwọ́de #EndSARS
- Ìrẹ̀wẹ̀sì ń bá wa torí ìdánwò NECO tẹ ń ṣún síwájú lọ́pọ̀ ìgbà - Akẹ́kọ̀ọ́, ọ̀gá iléèwé
- Agbára ìgbìmọ̀ ìdájọ tí mo gbé kàlẹ̀ yóò dé ọ̀dọ̀ àwón ólọ́pàá tó ti kúrò lẹ́nu iṣẹ́ tẹ́lẹ̀- Sanwo Olu
- Wo àwọn orílẹ̀èdè míràn tó ń fojú winá ìwọ́de bíi ti ENDSARS
- Mo fura pé ẹ fẹ́ da Nàíjíríà rú, ń kò ṣe ìwọ́de mọ́ - Segalink, agbátẹrù ìwọ́de yọwọ́
''Ti o ba ri ọmọ ilu Akure, ohun ti wa ri ni awọn eniyan to jẹ akinkanju, ti ọrọ wọn si ṣee gbẹkẹle.

Oríṣun àwòrán, @seyiamakinse
Bakan naa ni gomina Makinde kede pe, o di ọsẹ kini, Oṣu Kejila, ọdun 2020 ki oun to ṣe oku iya oun to papoda.
Gomina wa dupẹ lọwọ Deji ti Akure fun abẹwo rẹ, to si fi da wọn loju pe, awọn ara ilu Akure yoo ko ipa ribiribi ninu eto isinku iya oun.
Bẹẹ si ni gomina ipinlẹ Oyo lo asiko naa, lati fi ki awọn eniyan ipinlẹ Ondo, fun atilẹyin ti wọn ṣe fun ẹgbẹ oṣelu PDP, lasiko idibo sipo gomina to waye ni Osu Kẹwaa, ọdun 2020.
''Paapaa ilu Akure, wọn fihan pe awọn ṣetan lati jẹ ki ọmọ wọn di gomina ipinlẹ naa pẹlu bii wọn ṣe dibo wọn fun ẹgbẹ oṣelu PDP''
''Amọ, a o tẹsiwaju lati ma a rọ awọn ẹkun to ku nipinlẹ Ondo, lati fi ọwọ sọwọpọ fun gomina to wa lati ilu Akure, nipinlẹ Ondo.''
Ninu ọrọ tirẹ, Deji ti ilu Akure ni iya Gomina naa, Abigail Omojolagbe Makinde to wa lati idile Omoregie, jẹ idile ti awọn eniyan mọ fun iwa ọtọ ati awọn eniyan to ṣe e gbẹkẹle.
Deji naa si gbadura ki Olorun fi ọrun kẹ mama to doloogbe.
Ìyá gómìnà Seyi Makinde dágbére fáyé lẹ́ni ọdún 81

Oríṣun àwòrán, @Makinde
Iya to ṣe ọlọkọ to wa gomina ipinlẹ Oyo wa saye, Arabinrin Abigail Omojolagbe Makinde ti faye silẹ.
Bo tilẹ jẹ pe gomina Makinde funrarẹ ko tii fi ọrọ sita, iroyin taa gbọ ni pe Mama Abigail dakẹ lowurọ ọjọbọ ọjọ kẹẹdogun oṣu kẹwa ọdun 2020.

Oríṣun àwòrán, @Makinde
Ni ibẹrẹ ọdun yii ni wọn ṣe ayẹyẹ ọgọrin ọdun ti mama naa pe lorilẹ aye.
- Gbọ́ ìtàn bí ikọ̀ SARS ṣe dà bó ṣe dà láti ẹnu Ọ̀gá ọlọ́pàá tó dá SARS sílẹ̀
- Ìjọba kéde ọjọ́ ìwọlé àwọn àgùnbánirọ̀ sí ìpàgọ́ lẹ́yìn Covid 19- Sunday Dare
- #EndSARS: Àwọn olùwọ́de kọ etí ikún sí àṣẹ ijọba, wọ́n tẹ̀sìwájú ìwọ́de l'Abuja
- Kanye West, Ozil, Boyega, àti àwọn gbajúmọ̀ ilẹ̀ okèèrè tó ṣàtìlẹyìn fún ìpolongo #ENDSARS
- Ọba Lamidi Adeyẹmi, òṣìṣẹ́ adójútòfò àti Abẹ̀ṣẹ́kùbíòjò kó tó jọba

Oríṣun àwòrán, @Makinde
Lẹyin aisan ranpẹ toripe ọjọ ogbo ni mama wa lọ sinmi.
Ṣaaju asiko yii gomina Makinde ti ṣapejuwe iya rẹ ri gẹgẹ bii ẹni ti wi bẹ ki wọn ba a bẹẹ to si ni oun fi iru eyi jọ iya to bi oun lọmọ.
Ọpọlọpọ ọrọ ni gomina Seyi Makinde sọ nibi ayẹyẹ ọjọ ibi ti iya rẹ ṣe gbẹyin eyi to fihan pe o mọ riri iya yii ko si ko iyan rẹ kere.
A o mu ẹkunrẹrẹ iroyin wa fun yin bo ba ṣe n lọ.


















