NYSC Camp, After coronavirus: Ìjọba kéde ọjọ́ ìwọlé àwọn àgùnbánirọ̀ sí ìpàgọ́ lẹ́yìn Covid 19- Minista ọ̀rọ̀ ọ̀dọ́ Nàìjíríà

Agunbaniro

Oríṣun àwòrán, @NyscHqtrs

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 1

NYSC: Adupẹ! Ètò àgùnbánirọ̀ yóò bẹ̀rẹ̀ padà jakejado Nàìjíríà

Ijọba apapọ Naijiria ti kéde pe ki wọn ṣí gbogbo Ibudo akojọ eto agunbanirọ pada keto gbogbo si maa waye nibẹ.

Iroyin ayọ yi ni Minisita idagbasoke ọrọ ọdọ Naijiria Sunday Dare fi sita loju opo Twitter rẹ lỌjọbọ to si ni eto agunbanirọ yoo gberasọ lọjọ Kewaa, oṣu Kọkanla.

Skip X post
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post

Ọgbẹni Dare fi kun ọrọ rẹ pe ijọba yoo ri wi pe gbogbo ilana idaabobo Covid-19 ni wọn tẹle lawọn ibudo yi.

Báyìí lo ṣe salaye ọrọ naa loju opo Twitter rẹ pe ijọba yoo pese ohun gbogbo ti wọn nilo lati tẹlẹ aṣẹ igbogunti itankalẹ ajakalẹ arun Covid 19.

Àkọlé fídíò, Sotitobire: Ọkọ mi kò mọ̀ Jegede PDP rí, kódà kò fa ẹnikẹ́ni kalẹ̀ dípò Akeredolu- Bisola

O ni: "Wọn ti buwọlu aṣẹ pe ki wọn ṣí gbogbo ibudo akojọ agunbanirọ to jẹ ibi ipagọ fawọn ti yoo kopa ninu eto naa lasiko yii.

Eto naa yoo si bẹrẹ ni ọjọ kẹwaa, oṣu Kokanla. ọdun 2020.

A o si tẹle gbogbo ilana Covid-19"

Saaju ni ijọba apapọ ti sọ agadagodo si gbogbo aaye akojọ NYSC jakejado Naijiria nitori ajakalẹ Covid-19.