Yakubu Dogara: Gómìnà Bauchi da ₦4bn owóyàá ìlú sápò iléeṣẹ́ àdáni kan

Oríṣun àwòrán, Yakubu Dogara Facebook
Olori tẹlẹ fun ile asoju-sofin, Yakubu Dogarati kede fun araye pe, ọna aibofin mu ti ijọba ipinlẹ Bauchi n gba gbe isẹ agbase jade, jẹ ọkan lara ohun to mu oun kuro ninu ẹgbẹ oselu PDP.
Dogara sisọ loju ọrọ yii lasiko to n ba BBC sọrọ lati ipasẹ amugbalẹgbẹ rẹ feto iroyin, Turaki Hassan.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Sunday Igboho yarí, ó fohùn ránsẹ́ sáwọn èèyàn tó ń pẹ̀gàn rẹ̀
- Magu gba ₦9.8bn owó àìtọ́ lọ́wọ́ mi ní tipá - Ẹlẹ́rìí
- Ìkúnlẹ̀ ló bá dé fún Oshiomole, Ize-Iyamu láti bẹ̀bẹ̀ fún ìbò aráàlú ní Edo
- Àwọn iléesẹ́ abáni fi ẹrù ránṣẹ bẹ̀rẹ̀ ìyaṣẹ́lódì tako àfikún owó Nipost
- Ikú Barakat Bello ní Akinyele gbé aláàánú pàdé ẹ́bí rẹ̀
- A ṣe ọdún Ọ̀ṣun lásìkò yìí láti kó Coronavirus lọ ni - Ooni ṣàlàyé
- Wo àwọn nǹkan tí o kò mọ̀ nípa 'Church of Satan'
- Àwọn afurasí ajínigbé tó tan oníṣòwò jáde ní ṣọ́ọ́sì wọ gàù Ọlọpaa
Bakan naa lo tun n kọminu lori aisan owo osu osisẹ lasiko ati bi gomina Bala Muhammed se kuna lati seto idibo ijọba ibilẹ laarin osu mẹfa akọkọ to gori oye, gẹgẹ bo ti seleri.

Oríṣun àwòrán, Femi Adesina Facebook
"Ijọba ya biliọnu mẹrin naira, ti wọn si ba owo naa ninu apo asunwọn banki fun ileesẹ adani kan, bi o tilẹ jẹ pe orukọ ijọba ipinlẹ Bauch ni wsn fi ya owo naa.
Bakan naa ni wọn tun n gbe isẹ agbase sita lai bikita, lai naani owo ilọpo meji ti wọn n na lori rẹ lai tẹle abala ofin to yẹ."
Dogara fikun pe, ọkan lara isoro ti oun ri pẹlu awọn asaaju ẹgbẹ oselu PDP ati ijọba ipinlẹ Bauchi ni bi gomina ko se bọwọ fun agba atawọn ọba alaye, lodi si ileri rẹ.
Gbogbo awọn isẹlẹ yii si ni olori ana nile asoju-sofin fi ni o mu ki oun ko aasa oun kuro ninu ẹgbẹ oselu PDP lọ si APC.
Amọ sa, Dogara ti wa sẹ lori ahesọ ọrọ kan to n ja ranin-ranin nilẹ pe, oun fẹ du ipo gomina ipinlẹ Bauchi tabi pada sile asoju-sofin, lo mu ki oun pada sinu ẹgbẹ oselu APC.
Yakubu Dogara padà sí APC, Buhari kí i kúàbọ̀ ní Aso Rock

Oríṣun àwòrán, @BashirAhmaad
Gẹgẹ bi a ṣe gbọ ọ, adari ile igbimọ aṣoju ṣofin tẹlẹ, Yakubu Dogara ti pada si ẹgbẹ oṣelu All Peogresives Congress, APC.
Alaga egbe naa, Mai Mala Buni lo fi lede lẹyin ti ohun ati Dogara kọwọ rin lọ si ile Aarẹ ni Aso Rock ni Abuja.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
Ẹgbẹ oṣelu APC ni Yakubu Dogara kọkọ wa ko to ṣi lọ si ẹgbẹ oṣelu PDP lasiko ti oun ati aarẹ ile igbimọ aṣofin tẹlẹ, Bukola Saraki jẹ adari awọn aṣofin.

Oríṣun àwòrán, @BashirAhmaad
Dogara ni adari ile igbimọ aṣoju-ṣofin nigba naa.
Ẹwẹ, Dogara ti ni oun yoo ba awọn oniroyin sọrọ laipẹ ọjọ.














