Adebayo Titus ni oun ati Akintelure Festus jọ ja to si mu ẹ̀mí Festus lọ

Oríṣun àwòrán, Others
Ori ma jẹ ki a ṣì rin ni ariow to gba ẹnu awọn ero agbegbe Oke Aro nijọba ibilẹ Guusu Akure nipinlẹ Ondo kan.
Eyi ko ṣẹyin bi ija ṣe bẹ silẹ laawrin awakọ ero kẹkẹ 'Marwa' meji ti ọkan si gab ibẹ di ero ọrun.
Awakọ kẹkẹ ẹlẹsẹ mẹta taa mọ si kẹkẹ Marwa kan nilu Akure, Adebayo Titus, lo ti gbẹmi mi lẹyin ede aiyede to waye laarin oun ati akẹgbẹ rẹ kan, Akintelure Festus.
Adebayo ni iroyin fi yeni pe o padanu ẹmi rẹ lakoko ti oun ati Akintelure n fa laasigbo lori ọrọ kiko iyẹpẹ ni ibudokọ wọn lati di awọn koto kan loju popo, leyi ti Adebayo kọ lati ba wọn kopa nibẹ.
- Toͅkoͅ-taya àti àwoͅn 16 míràn rí èͅwòͅn he lórí èͅsùn 419 ní ìpínlẹ̀ Oyo
- À-rá sán lù ojú òpó ìgbéra ní pápákọ̀ òfúrúfú, kò sí bàálù tó lé gbéra
- 100 ọmọ ló ń kú ní Nàìjíríà láàrín wákàtí kọ̀ọ̀kan lójúmọ́- UNICEF
- Báwo ní akẹ́kọ̀ọ́ fásitì 'Michael Okpara' méjì ṣé kú sínú iyàrá lójú oorun-
- Darandaran kan rí ẹ̀wọ̀n he fún ẹ̀sùn jíjí màálù 61 nìpínlẹ̀ Oyo
- À-wọn jàndùkú dáná sun ọ́fíìsì INEC nípìnlẹ̀ Ogun
Kini ọ ṣẹlẹ gangan?
Awọn oṣojumikoro to ba BBC Yoruba sọrọ wi pe Akintelure lo koro oju si Adebayo latari pe ko bawọn lọwọ ninu iṣẹ ọhun
Eleyi to mu ki awọn mejeeji o maa tahun si ara wọn ko too di pe wọn wọ ijakadi leyi to mu ki Adebayo o ṣubu lulẹ ti wọn si sare gbe lọ ile iwosan.
Awọn kan ninu wọn wipe Akintelure lo lu Adebayo ni alubami leyi to mu ki wọn gbe digbadigba lọ ile iwosan.
Kini Olọpaa sọ lori iṣẹlẹ ọhun?
Alukoro ajọ ọlọpa nipinlẹ Ondo, Funmilayo Odunlami, lakoko to ba BBC Yoruba sọrọ lori iṣẹlẹ naa wi pe ọjọ Satide ni iṣẹlẹ naa waye lagbegbe Oke-aro ni llu Akure.
- Ogun tí Russia ń gbé kojú wá ń parí lọ díẹ̀díẹ̀ - Ààrẹ Ukraine, Zelensky
- Iléeṣẹ́ ọmọ ogun kéde orúkọ agbésùnmọ̀mí 19, àti ẹ̀bùn owó ₦-5m fún ẹni tó bá lè ṣamọ̀nà bí ọwọ́ yóò ṣe tẹ̀ wọ́n
- Ọwọ́ NDLEA tẹ bàbá ìsàlẹ̀ àwọn tó ń gbé oògùn olóró, gbẹ́sẹ̀lé kóró tramadol 497,900
- B-alógun ikọ̀ Tunisia, Khazri gbàgbọ́ pé ìdíje World cup yóò ṣẹnure
- Àtúpalẹ̀ àwọn àròsọ márùn ún nípa àyípadà ojú ọjọ́ tí kìí ṣe òótọ́
- 'À-wọn obìnrin tó n fi ọṣẹ tó ní kẹ́míkà sí irun wà nínú ewu jẹjẹrẹ ilé ọmọ'
- U.S Midterm Elections- Buhari kí àwọn ọmọ Naijiria tó jáwé olúborí nínú ètò ìdìbò ilẹ̀ Amẹrika kú oríire
Odunlami to wi pe aarọ ọjọ Isinmi ni oloogbe naa gbẹmimi nile iwosan ti wọn gbe e lọ lẹyin iṣẹlẹ naa.
Ni ṣe ni awọn agbofinro parọwa si awọn mọlẹbi oloogbe naa lati tẹle ilana ofin ki wọn ma ṣe da rugudu silẹ lagbeegbe naa.
O wa fikun pe Akintelure lo ti wa ni ihamọ awọn agbofinro ti iwadi kikun si n lọ lori ohun to ṣokunfa ikun Adebayo gan.














