100 ọmọ ló ń kú ní Nàìjíríà láàrín wákàtí kọ̀ọ̀kan lójúmọ́- UNICEF

Oríṣun àwòrán, @Unicef
Ajọ to n risi ọrọ ọmọde ni agbaye ti a mó si United Nations Children's Fund ti sọrọsoke lori iku ọmọde ni Naijiria lasiko yii.
UNICEF ni eyi ko ṣẹyin airi ounjẹ to n ṣe ara loore jẹ bi o ti yẹ.
Nemat Hajeebhoy to jẹ adari ẹka to n mojuto eroja ounjẹ ti awọn ọmọde n jẹ lo sọ ọrọ yii nilu Abuja nibi ipade apero kan ti ajọ amojuto ohun jijẹ ni Naijiria.
O salaye pe pẹlu ajọṣepọ ọfiisi igbakeji aarẹ ati atilẹyin ajọ UNICEF at'awọn miran pe aisi ounjẹ to dara to n ṣe akoba fun igbayegbadun ati idagbasoke awọn ọmọde ni Naijiria.
- Ìjọba ya èèyàn 100 sọ́tọ̀ ní Ghana tórí àrùn pọ̀jẹ̀-pọ̀jẹ̀ Marburg
- Ẹ ṣọ́ra, Monkeypox tún lè dàbí àjàkálẹ̀ ààrùn bíi Coronavirus ní àgbáyé - WHO
- U.S. yóò máa fún àwọn ọmo Nàìjíríà kan ní físà ìwé ìrìnnà láì ṣe ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò
- Èdè Gẹ̀ẹ́sì tó wà lórí owó ilẹ̀ Algeria ń bí ilẹ̀ Faranse nínú
- Fídíò Tiktok kò èèyàn méjì sí gbaga Ọlọ́pàá torí wọ́n tàbùkù gómìnà Ganduje
Arabinrin Hajeebhoy sọ pe airi ounjẹ to dara jẹ n ṣe akoba fun ilera, idagbasoke ati afojusun ọjọ ọla awọn ọmọde, bẹẹni opo awọn ọmọ ni ko ri ounjẹ to ṣe ara loore jẹ ti wọn nilo fun didagba bi o ṣe yẹ.
"Bi wọn ko ba ri amojuto to yẹ, ni ilọpo mejila, o ṣeeṣe fun awọn ọmọ ti ko ri ounjẹ to sara loore jẹ o tete ku ju awọn to jẹun daada lọ.
"Bi igbesẹ to dara ko ba tete di gbigbe, nnkan bi miliọnu marundinlogun o din diẹ ọmọde tọjọ ori won ko ju marun un lọ ni yoo maa koju airi ounjẹ to sara loore jẹ lọdun yii.
O fi kun pe ipenija nla ni ọwọn ounjẹ jẹ fun ọjọ ọla Naijiria nitori pe ida kan ninu mẹta idile ni ko le pese ounjẹ to ṣe ara lore fun àwọn ọmọ wọn.














