Rape: Wo bí àwọn ọlọ́pàá ṣe yìnbọn pa afurasí ajínigbé nínú igbó l‘Ogun

Oríṣun àwòrán, Ogun state Police Command
Wo bí àwọn ọlọ́pàá ṣe yìnbọn pa afurasí ajínigbé nínú igbó Abeokuta
Ile iṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Ogun ti ṣàlàyé bi o ṣe yinbọn pa afurasi ajinigbe kan, ti o sí tún fọwọ ofin mu omiran ninu Igbo Ilala lagbegbe Imala nipinlẹ Ogun.
Alukoro ile iṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Ogun, DSP Abímbóla Oyeyemi ṣàlàyé pé, isẹlẹ naa waye lẹyìn ọjọ kan tàwọn ọlọpaa tun yinbọn pa awọn janduku ajinigbe meji mii ni Itori ni ijọba ibilẹ Ewekoro nipinlẹ Ogun.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Kò sí ‘Constitution’ tuntun, kò sí ìbò ní Nàíjíríà ní 2023 - Afenifere
- Ọ̀pọ̀ ẹgbẹ́ agbábọ́ọ́lù mójú lọ sọ́jà, bí kátàkárà agbábọ́ọ́lù ṣe dópin
- Ṣe ìgbọ̀nsẹ̀ sí gbangba òde, kóo rugi oyin lábẹ́ òfin tuntun
- Wàláhà ń bọ̀, tíjọba bá ní ká gba abẹ́rẹ́ Covid-19 ní tipá - NMA, JOHESU
- Àṣírí tú lórí ìdí tí DSS kò ṣe fi mẹ́rin sílẹ̀ nínú amúgbálẹ́gbẹ̀ẹ́ Sunday Igboho - Amòfin Olajengbesi
- Akeredolu buwọ́lu òfín máfi ẹran jẹko láàrín ìgboro l'Ondo
- Ìmáàmú àgbà kan ní Abuja ti fi ìbínú sọ̀rọ̀ sí Buhari torí ìkọlù agbébọn
- O kò ní wọ ṣọ́ọ̀ṣì àti mọ́ṣáláṣí tó ò bá gba abẹ́rẹ́ Covid-19 - Ìjọba Ondo
- Owó ilẹ̀ òkèèrè ta yá, orí pípé la fi ya - Mínísítà
- Sunday Igboho fi ọ̀rọ̀ ìyànjú ránṣẹ́ sáwọn olólùfẹ́ rẹ̀ láti Cotonou
DSP Oyeyemi ṣàlàyé pe awọn ọlọpaa mori le inú igbo Imala lẹyin ti ile iṣẹ ọlọpaa to wa lagbegbe naa ni awọn ri ajinigbe mẹfa pẹlu ibọn lọwọ wọn ninu igbo.
"Lẹyin naa ni CSP Bernard Ediagbonya ko àwọn ọlọpaa, fijilante, awọn ọlọdẹ at'awọn ọdọ Fulani, ti wọn sì mori le igbo naa.
Lati okeere tàwọn ajinigbe ti ri awọn ọlọpaa ni wọn ti bẹrẹ sí ní yinbọn, ti awọn ọlọpaa sí bẹrẹ si ni dáa pada.
Nigba ti ọta ibọn n ro yìí gan an ni ọkan lára àwọn ajinigbe ọhún gbẹmi mi.
Bakan naa ni ọwọ tẹ ọkàn lára wọn ti o pe orúkọ ará rẹ ni Usman Maidama.
Awọn mẹrin to ku sa wọ inu igbo lọ pẹlu ọgbẹ ọta ibọn lára wọn.
Awọn nkan ti ọlọpaa gba lọwọ awọn janduku ọhún ni ibọn kan, iboju ati bàtà meji," Oyeyemi ṣàlàyé.
DSP Oyeyemi ni kọmiṣọnna ọlọpaa ipinlẹ Ogun, Edward Ajogun ti paṣẹ pe kí àwọn ọlọpaa wa awọn janduku ajinigbe to sa lọ ri ni kiakia.

Okùnrin ẹni ọdún 33 fi ipá bá obìnrin ẹni ọdún 27 lòpọ̀ torí ó ní kò kí òun

Oríṣun àwòrán, Bimbola oyeyemi
Ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ ogun ti fi ṣikun ofin mu okunrin ẹni ọdun mẹtalelọgbọn kan, Imoleaye Adekoya, lori ẹsun pe o fiipa ba obinrin ẹni ọdun mẹtadinlọgbọn kan lopọ.
Iroyin ni Adekoya fi ipa wọ obinrin naa lọ kọrọ ẹyin kan lẹyin to ti kọkọ sọ pe ko ki oun, to si fi ipa ba lopọ.
Agbenusọ ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Ogun, ASP Abimbola Oyeyemi lo fi ọrọ naa lede fun awọn akọroyin ninu atẹjade kan.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ìdí rèé tí ń kò fi pòórá ní àhámọ́ ọlọ́pàá lẹ́yìn ìwọ́de Yoruba Nation - Ọba Ogboni
- Mo ní ẹ̀rí tó dájú pé àwọn Fulani fẹ́ gba gbogbo ilẹ̀ Nàìjíríà - Ortom
- Ilé Ife tako èrò Alaafin lórí ìfoyè dánilọ́lá nílẹ̀ Yorùbá
- Rotimi Ameachi sọ̀rọ̀ lórí bóyá lóòtọ́ ni àjọsọ wà láàrin Tinubu àti Buhari
- Ṣé lóòtọ́ ni tírélà ti gba ààrin Laide Bakare àti Kemi Afolabi nítorí ọkunrìn?
- "Ọkàn mi gbọgbẹ́ lórí aya, ọmọ àti ẹbí mi márùn ún tí agbébọn pa lọ́jọ́ kan"
- Èmi nìkan ni ọba tó lẹ́tọ̀ọ́ láti fi oyè ilẹ̀ Yorùbá dá èèyàn ńlá lọ́lá - Alaafin
- Wo àṣírí márùn-ún tí obìnrin kò gbọdọ̀ sọ fún ọkọ rẹ̀
Oyeyemi ni awọn fi panpẹ ofin mu afurasi naa lẹyin ti obinrin naa fi ẹjọ rẹ sun ni agọ awọn to wa ni Sakora, niluu Sagamu.
Agbenusọ ọlọpaa naa ṣalaye pe obinrin ọhun sọ pe Adekoya da oun lọna lagbegbe Ipoji, ni Sagamu, to si fi ẹsun kan oun pe oun ko ki i.
Atẹjade naa tẹsiwaju pe "O bẹ Adekoya pe ko ma binu pe oun ko mọ ni ko jẹ ki oun ki."
"Ṣugbọn ni ṣe ni Adekoya ki obinrin naa mọlẹ to si bẹrẹ si n lu nilu bara ko to wọ lọ si ẹyin ile rẹ nibi to ti fi ipa bọ aṣọ rẹ to si ba ni ajọṣepọ."
Oyeyemi sọ pe ni kete ti awọn gbọ nipa iṣẹlẹ naa ni awọn oṣiṣẹ awọn tẹkọ leti lọ si ibi ti iṣẹlẹ ọhun ti waye pẹlu baba obinrin ọhun, ti wọn si fi panpẹ ofin mu afurasi naa.
Gẹgẹ bii ohun ti atẹjade naa sọ, afurasi naa ti jẹwọ ni agọ ọlọpaa pe lootọ ni oun fi ipa ba obinri ọhun lopọ ṣugbọn ki wọn fori jin oun nitori oun mu ọti yo lọjọ naa ni.
Ẹwẹ, kọmiṣọna ọlọpaa ipinlẹ Ogun, Edward Ajagun ti paṣẹ pe ki wọn bẹrẹ iwadii ni kankan ki afurasi naa le foju bale ẹjọ laipẹ.
- Ọjà títà, ọ̀kadà gígùn àti epo títà dèèwọ̀ ní Zamfara torí ọṣẹ́ ajínigbé, agbébọn
- Wo àṣírí márùn-ún tí obìnrin kò gbọdọ̀ sọ fún ọkọ rẹ̀
- Àwọn agbébọn ti yìbọn pa ọmọ sẹ́nétọ̀ kan ní Kaduna
- Amotekun mú afurasí ajínigbé mẹ́rin lọ́nà Iseyin sí Oyo
- Nàíjíríà ń wó lọ o, Obasanjo, Babangida, ẹ má wo Nàìjíríà níran - Ẹgbẹ́ ọ̀dọ́ Arewa figbe ta
- Gómìnà mẹ́ta láti Òkè Ọya ń dírẹ̀ẹ́bẹ̀ lọ́dọ̀ àgbà Yorùbá fún Buhari

















