Nigeria Insecurity: Àwọn ọdọ́ Arewa ké sáwọn aṣáájú láti pe ìpàdé àjọ tó ńi ìrònú lórí Nàíjíríà

olori ijọba ologun tẹlẹ, Ibrahim Babangida ,Aarẹ tẹlẹ, Oluṣẹgun Ọbasanjọ ati aarẹ Muhammadu Buhari

Oríṣun àwòrán, other

Ipe kan ti lọ sọdọ awọn adari orilẹede Naijiria pe ki wọn dide giri lati daabo bo orilẹede Naijiria, ki o ma baa dawo.

Ẹgbẹ awọn ọdọ kan lapa oke ọya NYLF ṣalaye pe ki awọn aṣiwaju wọnyii wa ọna lati pe ipade ironu laarin ara wọn, ki wọn lee wa ojutu si isoro to nkoju orilẹede Naijiria.

Bakan naa lẹgbẹ NYLF ke si Aarẹ tẹlẹ, Oluṣẹgun Ọbasanjọ, olori ijọba ologun tẹlẹ, Ibrahim Babangida ni wọn ni ko ṣaaju ijiroro naa.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Ẹgbẹ awọn ọdọ apa oke ọya naa tun rọ awọn eekan bii Theophilous Danjuma, Abdulsalami Abubakar, Oloye Earnest Sonẹkan atawọn miran, lati ko ipa to jọju ninu irufẹ apero bẹẹ. lọna ati koju ipenija to n koju orilẹede Naijiria.

Alaga apapọ ẹgbẹ naa, Elliot Afiyo ṣalaye nilu Abẹokuta, lẹyin ifikuluku pẹlu oloye Ọbasanjọ pe kii ṣe iroyin tuntun mọ pe ijinigbe ati ọrọ aje to dagun, n da Naijiria laamu.

Àkọlé fídíò, Senato francis Fadahunsi: Ká ni wọ́n fún Buhari ladún mẹ́wàá sẹ́ypin ní, bóyá kò bá rí i ṣ

Bakan naa lo ni ijẹkujẹ, ipe fun ipinya wa lara awọn ipenija to n koju Naijiria lọwọ, eyi lo si mu ko di ọranyan fawọn olori wọnyii lati dide wa ọna abayọ si awọn ipenija naa.

Ẹgbẹ naa ni ododo ọrọ to koro ni pe, ẹgbẹ oṣelu APC to n ṣe ijọba ko ni ipinnu ati eroja oṣelu to yẹ lati koju ọpọ ipenija to n ba Naijiria finra, bakan naa lo fi kun un pe ẹgbẹ oṣelu PDP pẹlu ni iṣoro dukuu laarin ara wọn, leyi to fẹ ki oloye Ọbasanjọ ba wọn da si.

Ẹgbẹ naa ni awọn wa lara awọn ẹgbẹ to fọnrere ibo fun aarẹ Muhammadu Buhari ki o to ja jo awọn loju pe, aṣiyan patapata ni awọn yan, ti awọn si gbọdọ gbe igbesẹ atunṣe gbogbo to ba yẹ.

Àkọlé fídíò, Nítorí kí aafa lè máa rí iṣẹ́ ṣe ní wọ́n kò ṣe kó Alumaajiri nílẹ̀ tó fi di ohun tó dà yìí