Ortom: Àwọn Fulani tó fẹ́ gbẹ̀mí mi ní àwọn ló ni gbogbo Nàíjíríà

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Gomina ipinlẹ Benue, Samuel Ortom, si duro lori ọrọ to sọ pe awọn Fulani daran-daran n gbero lati gba gbogbo ilẹ orilẹ-ede Naijiria.
Gomina Ortom so fún BBC pe oun ni ẹri to daju ti o lè fìdí rẹ múlẹ pe awọn Fulani n gbero lati gba Naijiria.
Ortom ni ẹgbẹ Fulani Nationality Movement, FUNAM ti wọn gbiyanju lati gbẹmi oun, sọ pe awon lo ni gbogbo Naijiria.
FUNAM ni Naijiria nikan ni orile-ede to jẹ ti tawọn. Gomina Benue ni ọrọ naa wa ni akọsilẹ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ìdí rèé tí ń kò fi pòórá ní àhámọ́ ọlọ́pàá lẹ́yìn ìwọ́de Yoruba Nation - Ọba Ogboni
- Ilé Ife tako èrò Alaafin lórí ìfoyè dánilọ́lá nílẹ̀ Yorùbá
- Rotimi Ameachi sọ̀rọ̀ lórí bóyá lóòtọ́ ni àjọsọ wà láàrin Tinubu àti Buhari
- Ṣé lóòtọ́ ni tírélà ti gba ààrin Laide Bakare àti Kemi Afolabi nítorí ọkunrìn?
- "Ọkàn mi gbọgbẹ́ lórí aya, ọmọ àti ẹbí mi márùn ún tí agbébọn pa lọ́jọ́ kan"
- Èmi nìkan ni ọba tó lẹ́tọ̀ọ́ láti fi oyè ilẹ̀ Yorùbá dá èèyàn ńlá lọ́lá - Alaafin
- Wo àṣírí márùn-ún tí obìnrin kò gbọdọ̀ sọ fún ọkọ rẹ̀
"Mo ti fi ẹda iwe ti mo kọ ọrọ naa ranṣẹ si aarẹ, awọn ọlọpaa ati ajọ DSS.
FUNAM ni awọn gbiyanju lati jija yii lọdun 1800 laye Usman Danfodio , ṣugbọn kò ṣeeṣe.
Won ni agbara wa, owo wa, awọn sí ni ohun tó máa gbà láti gba gbogbo Naijiria," Ortom ṣalaye.
Gomina Ortom ti n tako ìjọba àpapọ lori eto abo to mẹhẹ ni Naijiria.
O ni ijọba Aarẹ Muhammadu Buhari fi ọwọ yẹpẹrẹ mu eto abo ni Naijiria.
Ortom ni iroyin igbesunmọmi ti awọn ọmọ Naijiria maa n gbọ lokeere tẹlẹ nipa Afghanístàn, Iraq at'awọn orileede agbaye mii ti wa n ṣẹlẹ ni Naijiria bayii.
"O dàbí ẹni pé ijọba n ṣegbe lẹyin awon janduku adaluru yii, tori ijọba ko sọ ohun kan nipa gbogbo nkan ti o n ṣẹlẹ," gomina Benue lo sọ bẹẹ.

Àwọn agbébọn ti yìbọn pa ọmọ sẹ́nétọ̀ kan ní Kaduna

Oríṣun àwòrán, others
Awọn agbebọn ti ṣekupa akọbi ọmọ sẹnetọ to n ṣoju ẹkun ila oorun Kebbi nile igbimọ aṣofin agba, Abdulkarim Bala Na'allah.
Oloogbe naa, to jẹ awakọ ọfurufu ni wọn pa nile rẹ to wa lagbegbe Malali niluu Kaduna.
Agbẹnusọ ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Kaduna, ASP Muhammad Jalige ṣalaye fun BBC pe awọn agbebọn naa gbe ọkọ oloogbe ọhun lọ lẹyin ti wọn gbẹmi rẹ tan.
- Wo àṣírí márùn-ún tí obìnrin kò gbọdọ̀ sọ fún ọkọ rẹ̀
- Ẹ̀yin ọ̀dọ́, ẹ lo okun yín fún ìdàgbàsókè Naijiria bíi ti àwọn Awolowo àti Akintola - Alaafin
- Amotekun mú afurasí ajínigbé mẹ́rin lọ́nà Iseyin sí Oyo
- Nàíjíríà ń wó lọ o, Obasanjo, Babangida, ẹ má wo Nàìjíríà níran - Ẹgbẹ́ ọ̀dọ́ Arewa figbe ta
- Wo obìnrin tó ní ojú ara méjì, ilé ọmọ méjì àti ẹsẹ̀ mẹ́rin
- Gómìnà mẹ́ta láti Òkè Ọya ń dírẹ̀ẹ́bẹ̀ lọ́dọ̀ àgbà Yorùbá fún Buhari
- Ìdí tí mo fi ń gbẹjọ́ rò fún Baba Ijesha - Amofin Ogala
O ni "Lootọ ni awọn agbebọn ti yinbọn pa ọmọ sẹnetọ naa nile rẹ lagbegba Malali ni irọlẹ ọjọ Aiku ti wọn si gbe ọkọ rẹ lọ."
"Ṣugbọn nigba ti wọn lọ sibi ti iyawo rẹ wa, ko si nible tọkọ-taya naa ko si tii bi ọmọ."
Iku ọmọ sẹnetọ yii lo waye lẹyin ti awọn agbebọn ti kọkọ n ṣekupa awọn eeyan mii nipinlẹ ọhun.
Lọjọ Abamẹta, awọn agbebọn ṣekupa eeyan meji ni abule Makoro to wa ni ijọba ibilẹ Kajuru, nipinlẹ Kaduna yii kan naa.
Kọmiṣọna fun ọrọ eto abo abẹle, Samuel Aruwan sọ fun awọn akọroyin pe awọn agbebọn ọhun yabo abule naa ki wọn to ṣekupa awọn eeyan meji ọhun to fi orukọ wọn lede gẹgẹ bii Gideon Mumini ati Barnabas Ezra.
Ẹwẹ, ori ko awọn arinrinajo mẹta kan yọ lọwọ awọn agbebọn loju ọna Gidan Waya-Godogodo ni ijọba ibilẹ Jema ni ipinlẹ yiin kan naa lọsẹ to kọja.
- Háà! Ẹ wò ó bí ayé ṣe le mọ́ wa ní Afghanistan - Aráàlú figbe ta
- Mo bú sẹ́kún nígbà tí mo gba owó oṣù gelemọ àkọ́kọ́ ní Saudi-Arabia - Dokita
- Èèkàn amúlúdùn méjì jáde láyé láàrín ọjọ́ méjì síra wọn
- Obìnrin tí ọjọ́ orí rẹ̀ lé ní 60 dèrò àtìmọ́lé lẹ́yìn tó jì ẹ̀ṣọ́ ara òkú
- "Ìbínú aráàlú ń bọ̀ lọ́dọ̀ gómìnà tó bá gbé ilẹ̀ wa sílẹ̀ fétò ìdaranjẹ̀"
- Wo ìdí tí Ìje ṣe ṣe pàtàkì nílùú Ijare lẹ́yìn tí ọba bá wàjà
- Olórí ijọ kan àti Olùjọ́sìn mẹ́sàn án ko ìjàmbá ọkọ̀ nílùú Eko


















