Ibadan train station: A kò lágbára láti yí àkókò tí ọkọ̀ reluwé ń gbéra kúrò nílùú Ibadan - Ìjọba ìpínlẹ̀ Oyo

Oríṣun àwòrán, Seyi Makinde
Ijọba ipinlẹ Oyo ti sọ pe awọn ti n ṣeto lati sọ agbegbe Moniya di gbagede karakata niluu Ibadan lẹyin ti Aarẹ Muhammadu Buhari ṣe ifilọleẹ papakọ ọkọ oju iri nibẹ.
Kọmiṣọna fun iṣẹ ode ati eto irinna ni ipinlẹ naa, Ọjọgbọn Dahud Kehinde Shangodoyin lo sọ bẹẹ ninu ifọrọwerọ kan pẹlu BBC Yoruba.
Shangodoyin sọ pe ijọba ipinlẹ Oyo ti gbero bi awọn yoo ṣe ko awọn ọkọ kan si agbege naa, eyii ti yoo maa ko awọn ero lati Moniya ti ibudokọ oju irin naa wa lọ si aarin igboro.
- Ìjọba Oyo ti bẹ̀rẹ̀ sí ní kó àwọn oníbárà kúrò láàrin ìgboro ìlú Ibadan
- Wo iye owó tí ìjọba Naijiria ti yá lọ́wọ́ China láti ìgbà tí Ààrẹ Muhammadu Buhari ti gorí àléfà
- Jamb ti rọ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ láti parí ìforúkọsílẹ̀ lónìí ọjọ́ ìṣẹ́gun
- Ẹgbẹ́ ajàfẹ́tọ́ 70 ké sí ìjọba Naijiria láti yí ìpinnu rẹ̀ padà lóró òfin tó fi de Twitter
O ṣalaye pe ijọba ipinlẹ Oyo ti n gbero bi awọn yoo ṣe sọ agbegbe naa di gbagede karakata, ninu eyii ti awọn araalu naa yoo ti maa ṣowo-jere, yatọ si pe ijọba n pa owo wọle nibẹ.
O ni "Ti ẹ ba de awọn orilẹ-ede nla nla kaakiri agbaye, e o ri awọn gbagede karatakata to sun mọ ibudokọ oju irin, iru rẹ ni ijọba Seyi Makinde fẹ ṣe siluu Ibadan."
"To jẹ pe ti eeyan ba de ibudokọ naa tan, yoo ri oniruru ọkọ ti yoo gbe lọ si ibikibi to ba n lọ, yala ọkọ aladani ni o tabi ti ijọba."
Ọjọgbọn naa ṣalaye pe ti awọn ba ti bẹrẹ awọn akanbṣẹ iṣẹ naa, gbogbo awọn nnkan meremere to yẹ ko wa ni ibudokọ oju irin ni yoo wa ni Moniya.
Yatọ si awọn ọkọ akero, o ni awọn tun yoo tun kọ ibudoko ti awọn awọn arinrinajo yoo ni anfaani lati maa gbe ọkọ wọn si ki wọn to pada de lati irinajo wọn, ti aabo to peye yoo si wa lori irufẹ ọkọ bẹẹ, ṣugbọn o ni awọn araalu yoo ni lati ni suuru fun igba diẹ.
Gẹgẹ bo ṣe sọ, "Gomina ti ṣeleri fun awọn eeyan to wa ni agbegbe naa pe wọn yoo ri iyatọ laipẹ yii nitori ijọba yoo sọ agbegbe ọhun di gbagede karakata ti gbogbo nnkan amayedẹrun ni yoo si wa nibẹ."
Nigaba to n sọrọ lori awọn akoko ti ọkọ oju irin reluwee yoo maa gbera kuro niluu Ibadan ati akoko ti yoo maa pada de, Shangodoyin sọ pe awọn ko lagbara lati yi awọn akoko naa pada.
Ṣaaju ni awọn eeyan kan ti kọkọ n sọ pe akoko ti ọkọ oju irin naa maa n gbera ko pe awọn, ṣugbọn o ni awọn ko lagbara lori awọn akoko naa nitori ko si ni ikawọ awọn.
Shangodoyin pari ọrọ rẹ pe awọn yoo dari awọn ọkọ ti yoo maa ko ero lati papakọ oju irin naa lọ saarin ilu laipẹ.
Ọjọ kẹwaa, oṣu Kẹfa, ọdun yii ni Aarẹ Muhammadu Buhari ṣi ibudokọ ọkọ oju irin naa
- Àsìkò tó fún Buhari láti kọ̀wé fi ipò sílẹ̀ - Ìgbìmọ̀ Àgbààgbà Yorùbá
- Sunday Igboho kan sárá sáwọn ọmọ Yorùbá tó wọ́de lọ́jọ́ Sátidé, ṣùgbọ́n kò sọ ìdí tí kò fi jáde
- Tope Alabi fẹ́ tọ́ Olórin "Oniduro mi e ṣe" sọ́nà, bí ọ̀rọ̀ ṣe laná nìyìí
- Kò sí olùfẹ̀hónúhàn kankan ní àhámọ́ ọlọ́paà nítorí ìwọ́dé June 12 - Frank Mba
- Agbára bọ́ lọ́wọ́ Benjamin Netanyahu, Naftali Bennett di olótú ìjọba tuntun ní Israel
- Wo ohun tí Dele Momodu sọ nípa TB Joshua lẹ́yìn ikú rẹ̀
















