Twitter ban in nigeria: Kò bá òfin mu bí ìjọba Naijiria ṣe gbẹ́sẹ̀lé Twitter - Ẹgbẹ́ ajàfẹ́tọ́

Jack Dorsey an Buhari

Oríṣun àwòrán, ANC 24/7

Awọn ẹgbẹ ajafẹtọ bii aadọrin ti ke si ijọba apapọ lati yi igbesẹ rẹ pada lori bo ṣe fofin de lilo ẹrọ Twitter ni Naijiria.

Wọn tun ke si ijọba apapọ lati ma ṣe gbe ẹnikẹni ninu awọn to tapa si ofin naa lọ sile ẹjọ.

Ninu atẹjade kan ti awọn eeyan naa buwọlu, ti wọn si fi ṣọwọ si awọn akọroyin, wọn ni igbesẹ ti ijọba apapọ gbe ko ba ofin mu.

Gẹgẹ bii ohun ti wọn sọ "Inu wa bajẹ gidigidi bi ijọba Naijiria ṣe n tẹ ẹtọ awọn araalu loju mọlẹ, paapaa ominira lati ṣorọ bo ṣe wu wọn."

"A fẹ sọ ni gbangba pe a ko fọwọ si bi ijọba apapọ ṣe fofin de oju opo Twiter ni Naijria, eyii ti ko gba awọn eeyan laaye lati sọ erongba wọn lori ayelujara."

Ẹgbẹ naa tun bu ẹnu ẹtẹ lu aṣẹ ajọ to n ri si ọrọ igbohunsafẹfẹ ni Naijiria, NBC, to sọ pe ki gbogbo awọn ileeṣe iroyin yọ ara wọn kuro loju opo Twitter.

Àkọlé fídíò, 'Ọwọ́ mi ti ń jẹ́rà ká tó mọ̀ pé àfi kí wọ́n tún gé e bí mo bá ṣì fẹ́ máa ṣe iṣẹ́ awakọ̀ lọ'

Wọn ni "A rọ ijọba Naijiria lati yi aṣẹ rẹ pada lori ofin to fi de Twitter nitori aṣẹ naa ko ba ofin mu, to fi mọ igbeṣẹ lati fi panpẹ ofin mu gbogbo awọn to n tapa si aṣẹ ọhun."

Ẹgbẹ naa tun ni ki ijọba yi aṣẹ rẹ pada lori bo ṣe ni ki awọn ileeṣẹ iroyin yọ ara wọn kuro loju opo Twitter.

Lẹyin naa ni wọn rọ ijọba Naijiria lati ronupiwada lori iwa familete ki n tutọ to n wu, paapaa bo ṣe kan awọn araalu ati ẹtọ wọn labẹ ofin.

Àkọlé fídíò, 'Sister Tope Alabi yà mí lẹ́nu gan o pé "Oniduro mi" kìí ṣe orin tó yẹ kí ọlọ́run fún mi'

Wọn tun ke si ajọ iṣọkan agbaye, UN, ati ajọ iṣọkan ilẹ Afrika, AU, lati bu ẹnu ẹtẹ lu aṣẹ ijọba Naijiria lori Twitter.

Gẹgẹ bii ohun ti wọn sọ, oju opo ikansiraẹni lori ayelujara ti ran ọpọlọpọ ọmọ Naijiria lọwọ lati mọ ohun to n lọ kaakiri agbaye, eyii to tun gba wọn laaye lati jẹ ki ijọba mọ ibi to ku si ninu ojuṣe rẹ.

Lara awọn ẹgbẹ ajafẹtọ to buwọlu atẹjade naa ni ẹka Amnesty International ni Naijiria, Global Rights, Nigeria Mourns, ati bẹẹ bẹẹ lọ.

Àkọlé fídíò, 'Nínúu ká ṣe oríire níbí tàbí káa kú'! Àwọn tó ń fẹsẹ̀ rìn sálọ orílẹ̀èdè míì ṣe fídíò ráńṣẹ́ sílé