Texas School Shooting: Ọkọ olùkọ́ tó bá ìṣẹ̀lẹ̀ ìpànìyàn tó wáyé nílé ẹ̀kọ́ Texas dágbére fáyé lẹ́yìn ọjọ́ méjì tí ìyàwó rẹ̀ kú

Ọkọ ọ̀kan nínú àwọn olùkọ́ méjì tó bá ìṣẹ̀lẹ̀ ìpànìyàn tó wáyé ní ilé ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ ní Uvalde, Texas ti dágbére fáyé lẹ́yìn ọjọ́ méjì tí ìyàwó rẹ̀ kú.
Gẹ́gẹ́ àwọn mọ̀lẹ́bí rẹ̀ ṣe sọ, ìpòruru ọ̀kan lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ikú ìyàwó rẹ̀ ló ṣekúpa á.
Joe Garcia ní ọkọ Irma Garcia tí agbébọn tó yìbọn pa àwọn akẹ́kọ̀ọ́ mọ́kàndínlógún àti olùkọ́ méjì ní Robb Elementary School ní ọjọ́ Karùndínlọ́gbọ̀n, oṣù Karùn-ún, ọdún 2022 rán lọ sọ́run àrèmabọ̀.
- Ìwé orúkọ àwọn olùdíje tó bórí ìbó abẹ́nú gómìnà ní APC
- Ìkò Ipolongo tí APC yàn sá̀ájú ìdìbò sípò gómínà ní Ekiti rè é…
- Mà á dá fijilanté sílẹ̀, òmìnira á wà fún ìjọba ìbílẹ̀ láti ná owó wọn- Oluwole Oluyede
- Mọ̀ síi nípa àwọn tó máa díje dupò gómìnà lábẹ́ àsíà ẹgbẹ́ PDP lẹ́yìn tí wọ́n ti yegé nínú ìdìbò abẹ́lé
- Àwọn ọmọ tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ bí mọ́kànlá pàdánù ẹ̀mi wọn lẹ́yìn iná tó ṣẹ́yọ
- Ẹ̀sùn títàpá sófin tó tako ìwà kòtọ́ lórí ayélujára 'Cybercrime' la fi gbé Oriyomi Hamzat - Ọlọ́pàá
Ọdún mẹ́rìnlélógún ní àwọn tọkọtaya náà fi gbé papọ̀ tí wọ́n sì bí ọmọ mẹ́rin.
Ọkùnrin méjì àti obìnrin méjì tí ọjọ́ orí wọn wà láàárín ọdún méjìlá sí ọdún mẹ́tàlélógún ni àwọn tọkọtaya náà fi sáyé lọ.
Ní orí ẹ̀rọ ayélujára, Twitter ni John Martinez, tó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn mọ̀lẹ́bí Garcia ní ó jẹ́ ohun ìbànújẹ́ fún àwọn wí pé àwọn tún pàdánù Joe sọ́wọ́ ikú nítorí ọgbẹ́ ọkàn tí ikú ìyàwó rẹ̀ dá si lára.
Wọ́n ṣe ìkówójọ fún Garcia
Ní ìgà tí yóò fi di alẹ́ ọjọ́bọ̀, owò tí àwọn ènìyàn ti dá fún ẹbí Garcia ti le ní mílíọ̀nù kan lé ọwọ mẹ́fà dọ́là, èyí tó fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ iye lé sí ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá dọ́là tí wọ́n gbèrò láti dá fún-un.
Debra Austin tó jẹ́ ọ̀kan lára ẹbí Garcia ló bẹ̀rẹ̀ ìkówójọ́ náà.
- Mi ò mọ nǹkan kan nípa 'receipt' ṣùgbọ́n èmi ní mó kó Ẹ̀dá ìwé account- Adeniyi Aderogba, ẹlẹ́rìí ẹjọ́ ikú Timothy Adegoke
- Wo ojú àwọn tó fẹ́ díje dupò gómìnà lábẹ́ ẹgbẹ́ APC ní ìpínlẹ̀ Oyo lónìí
- Ìjọba kéde òfin kónílé-ó-gbélé ní ìjọba ìbílẹ̀ mẹ́sàn-án ní ìpínlẹ̀ Anambra
- Ohun ìbànújẹ́ ló ṣẹlẹ̀ ní Anambra, ẹ dákún mi ò fẹ́ kẹ́nikẹ́ni fi oró ya oró lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà- Buhari
- Gómìnà Anambra, Àjọ CAN, Àjọ Arewa bu ẹnu àtẹ́ lu obìnrin àti àwọn ọmọ rẹ̀ tí wọ́n ṣekúpa
- Ìdí tí mo fi fi ẹgbẹ́ òṣèlú PDP sílẹ̀ - Peter Obi
Austin ni òun ní ìgbàgbọ́ pé ìṣẹ̀lẹ̀ ikú Irma bá Joe lójijì, òhun ló sì fa ikú rẹ̀.
"Ọdún mẹ́rìnlélógún ni Irma Garcia fi ṣe olùkọ́ ní ilé ẹ̀kọ́ Robb Elementary School tó sì fẹ́ràn àwọn ọmọdé púpọ̀."
Austin ní akitiyan Garcia láti dá ààbò bo àwọn ọmọ tó wà ní yàrá ikẹ́kọ̀ọ́ nítorí ó ràgà bò wọ́n títí ẹ̀mí fi bọ́ lọ́rùn rẹ̀ ni.
Garcia àti olùkọ́ kejì tó bá ìṣẹ̀lẹ̀ náà lọ, Eva Mireles ti jọ ṣiṣẹ́ papọ̀ gẹ́gẹ́ bí olùkọ́ n;i ilé ẹ̀kọ́ fún ọdún márùn-ún kí wọ́n tó papòdà.

















