Harira Jubril: Aare Muhammadu Buhari ti ṣe ìkìlọ̀ lórí ìkọlù tó ṣekú pa Obìnrin kan àti ọmọ mẹ́rin ní Anambra

Buhari

Oríṣun àwòrán, @Presidency

Ohun ìbànújẹ́ ló ṣẹlẹ̀ ní Anambra, ẹ dákún mi ò fẹ́ kẹ́nikẹ́ni fi oró ya oró lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà- BuhariOhun ìbànújẹ́ ló ṣẹlẹ̀ ní Anambra, ẹ dákún

Aare Muhammadu Buhari ti ṣe ìkìlọ̀ lórí ìkọlù tó ṣekú pa Obìnrin kan àti ọmọ mẹ́rin ní AnambraGómìnà Anambra, Àjọ CAN, Àjọ Arewa bu ẹnu àtẹ́ lu obìnrin àti àwọn ọmọ rẹ̀ tí wọ́n ṣekúpa

Aare Buhari ti sọrọsoke nipa ohuin to ṣẹlẹ ni ipinlẹ Anambra ti ọpọ ẹmi si n sọnu.Afurasí 4,000 la fi ṣìkùn òfin mú láàrín ọṣù márùn ún- Amotekun Ondo

Buhari sọrọ ni kikun nipa obinrin alaboyun ti awọn agbebọn pa pẹlu ọmọ rẹ mẹrin.

Bakan naa ni Aarẹ Buhari ni pe ki enikeni maṣe gbero pe oun fẹ fi oro ya oro lasiko yii.

Àkọlé fídíò, Ayodeji Rotinwa ni ìròyìnn òfegè gbé àwòrán rẹ̀ síta pè dókítà tó ń pa àwọn Hausa mùsùlùmí

O( ni pe orilẹ-ede yii jẹ ti gbogbo wa fun idi eyi, ẹnikeni ko gbọdọ gbiyanju lati fi oro ya oro.

O tun ni pe ki ẹnikeni maṣẹ bẹru nitori awọn fọnran fidio orisiirisi to n jade lori ayelujara nipa awọn to n pa ara oke ọya nile Ibo.

Àkọlé fídíò, Títí ayé yóò fi parẹ́, wọ́n ó máa sọ̀rọ̀ sí Ànọ́bì ni, wọ́n ó sì máa bú Jésù ni, ẹ wá gbọ́ òótọ́ ohun tí Quaran sọ – Akeugbagold

Garba Shehu lo fi atejade yii sita loruko aarẹ Buhari.

O ni awọn akọsẹmọṣẹ eleto abo ti bẹrẹ iṣẹ lati wadii ohun to ṣẹlẹ gangan.

Ni afikun, ileese Aarẹ ni ki awon eeyan ṣọra fun pinpin awọn ayederu iroyin tabi fọnran fidi ofege to ti pẹ.

HARIRA JUBRIL ÀTI ÀWỌN ỌMỌ RẸ̀

Inú ọ̀sẹ̀ yìí ló yẹ kí ìyàwó mi bímọ kí wọ́n tó dá ẹ̀mí rẹ̀ légbodò Jubril- ọkọ aláboyún Anambra.

Gbogbo ohun tí mo ní ni àwọn agbébọn ti pa yẹn.

Alàyé rèé lẹ́nu ọkọ aláboyún tí àwọn agbébọn ṣekúpa ní Anambra.

Àkọlé fídíò, Amputee: Toheeb Abiodun Olaniyan: Ẹ̀rọ lílọ̀ ní ẹni ọdún mẹ́sàn án ni apa kan mi lọ sí

Ọkọ aláboyún, Harira Jubril tí àwọn agbébọn pa òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ mẹ́rin ní ìpínlẹ̀ Anambra ní ohun burúkú tí yóò ṣẹlẹ̀ sí òun láyé ni bí wọ́n ṣe pa gbogbo mọ̀lẹ́bí òun run.

Ó ní kò yẹ kí ẹnikẹ́ni lá irú inirá àti ìbàjẹ́ ọkàn èyí tí òun ń là kọjá lásìkò yìí nítorí ìbànújẹ́ ayérayé tí àwọn agbébọn náà dá sí ìgbésí ayé òun.

Ahmed Jubril sọ fún BBC News Pidgin wí pé nínú ọ̀sẹ̀ yìí ló yẹ kí ìyàwó òun bímọ gẹ́gẹ́ bí gbèdéke tí àwọn dókìtà àmọ́ àwọn agbébọn kò jẹ́ kí ìyàwó àti ọmọ tuntun jòjòló tó ń bọ́ gbáyé.

"Gbogbo nǹkan tí mo ní láyé ni àwọn agbébọn yìí ti gbà lọ́wọ́ mi, ìyàwó tó wà nínú oyún àti àwọn ọmọ mẹ́rin ni mo pàdánù ní ọjọ́ kan ṣoṣo yìí."

Ó sọ wí pé èyí tó dàgbà jù nínú àwọn ọmọ náà ni ọmọ ọdún mẹ́sàn-án, tí àbúrò tó tẹ̀lé sì jẹ́ ọmọ ọdún méje kó tó kan ọmọ ọdún márùn-ún àti abúrò pátápátá tó jẹ́ ọmọ ọdún méjì.

Àkọlé fídíò, 'Ọ̀pọ̀ ìgbà l'èmí gan fẹ́ du àwọn ipò òṣèlú kan, bíì '2015, 2019' àmọ́ mo tẹ 'slow' torí bàbà mi, Akala náà ń jáde'

Jubri ṣàlàyé bí àwọn agbébọn ṣekọ̀lù ìyàwó rẹ̀

Nígbà tó ń ṣàlàyé bí àwọn agbébọn náà ṣe ṣe ìkọlù sí ìyàwó rẹ̀ tí wọ́n sì dá ẹ̀mí rẹ̀ légbodò, Jubril ní ìyáwó àti àwọn ọmọ òun lọ ṣe àbẹ̀wò sí àbúrò òun gẹ́gẹ́ bí ìṣe rẹ̀ lọ́sọ́ọ̀sẹ̀ àti pé ìgbà tí wọ́n ń bọ̀ wá sílé ni ìkọlù náà wáyé.

Ó ní nígbà tí òun ń darí bọ̀ láti ibi iṣẹ́ ni àbúrò òujn tó ti mọ ohun tó ṣẹlẹ̀ ló sáré wá pàdé òun láti sọ ohun tó ti ṣẹlẹ̀ fún òun.

Bákan náà ló ní láti ìgbà tí ìṣẹ̀lẹ̀ láabi náà sì ti wáyé lọ́jọ́ Àìkú, àwọn ọlọ́pàá àti ìjọba kankan kò ì tíì yọjú sí òun.

Àkọlé fídíò, Oba Adedokun Abolarin ti Oke Ila: Ó ya ọ̀pọ̀ tó súnmọ́ mi lẹ́nu bí mo ṣe ń kọ́

Ó ní òun fẹ́ kó òkú àwọn ọmọ náà àti ìyàwó òun lọ sin ní ìpínlẹ̀ Adamawa tí òun ti wá nítorí kò wu òun láti sin wọ́n sí ìpínlẹ̀ Anambra.

"Owó tí mo máa fi gbé wọn lọ sí ìpínlẹ̀ Adamawa àti [yí tí máa fi sin wọ́n ni mò ń wá báyìí."

"Àwọn ènìyàn tilẹ̀ ti ń fún mi lówó láti fi gbé wọn kúrò ní Anambra."

ÀWỌN ỌMỌ TÍ ÀWỌN AGBÉBỌN ṢEKÚPA

Kí ni ọlọ́pàá sọ?

Nígbà tí BBC News Pidgin kàn sí agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Anambra, Ikenganyia Anthony tó fìdí ìṣẹ̀lẹ̀ náà múlẹ̀ ní ìwádìí ti ń lọ lọ́wọ́ lórí ìkọlù náà.

Anthony ṣèlérí wí pé àwọn yóò sa gbogbo ipá wọn láti fojú àwọn tó ṣiṣẹ́ láabi náà winá òfin.

Àkọlé fídíò, Tàá bá lè bá àwọn ọmọ tó pa Deborah ní Sokoto sọ̀rọ̀ pé ìwà ẹranko ni wọ́n hù, ó burú - Òṣèré Sokoti

Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ti di ẹrù gbogbo àwọn ipá àti ìpáǹle tó ń wáyé ní ẹkùn ìlà oòrùn Nàìjíríà ru àwọn IPOB .

Ó fi kun pé IPOB ti ń wẹ ara wọn mọ́ lórí àwọn ìkọlù kan ní agbègbè ṣùgbọ́n wọ́n kò tíì sọ ohunkóhun lórí àwọn mọ̀lẹ́bí yìí.

Ẹ ó rántí pé láìpẹ́ yìí ni àwọn agbébọn gé orí ọmọ ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin ìpínlẹ̀ Anambra ní ìpínlẹ̀ náà.

Àkọlé fídíò, Lasisi Jasper:Wo ìtàn ayé ọ̀gọ́ àgbà iléẹ̀kọ́ Adeniran Memorial ni Ogbomoso