MC Oluomo, òpin ti débá gbígba owó orí lọ́wọ́ àwọn awakọ̀ ní Eko - Iléẹjọ́

OluOmo

Oríṣun àwòrán, Others

MC Oluomo: Iléẹjọ́ pàṣẹ òpin śi gbígba 800 lójúmọ́ lọ́wọ́ àwọn awakọ̀ ní Eko

Ileẹjọ giga nipinlẹ Eko ti paṣẹ fun alaga awọn awakọ nipinlẹ Eko, Musiliu Akinsanya ti wọn n pe ni MC Oluomo ki wọn dẹkun gbigba owo ori lọwọ awọn awakọ ni Eko.

Ileẹjọ naa pa aṣẹ fun MC Oluomo ati awọn mẹjọ miran lori ẹsun pe ko tọ si wọn lati ma a gba a.

Agbẹjọro Agba, Peter Lifu fi aṣẹ naa lele lasiko ti agbẹjọrọ Olukoya ati ẹgbẹ awọn awakọ tuntun, Transport Society of Nigeria pe wọn lẹjọ.

Lara awọn ajọ ti ọrọ naa tun kan ni Ajọ National Union of Road Transport Workers, Registered Trustees of Road Transport Employers Association of Nigeria, Registered Trustees of the Nigerian Association of Road Transport Owners.

Olotu idajọ nipinlẹ Eko, Alhaji Lawal Othman naa ko gbẹyin ninu awọn ti wọn pe lẹjọ naa, to fi mọ Ọga Agba ọlọpaa patapata ati adari ajọ ọtẹlẹmuyẹ DSS.

Àkọlé fídíò, Ayodeji Rotinwa ni ìròyìnn òfegè gbé àwòrán rẹ̀ síta pè dókítà tó ń pa àwọn Hausa mùsùlùmí

Bakan naa ni wọn bẹ ileẹjọ ki o paṣẹ ki wọn ye fi iya jẹ awọn awakọ lọna aitọ abi ki wọn fi panpẹ mu wọn lati san owo naa ni ojojumọ.

Saaju ni Adajọ ti ni oun fun wọn ni ọjọ meje lati dahun si ipẹjọ ti Ajọ awọn awakọ naa pe mọ wọn ati idi ti ko yẹ ki wọn fofin de won lori ipẹjọ naa.

Àkọlé fídíò, Oba Adedokun Abolarin ti Oke Ila: Ó ya ọ̀pọ̀ tó súnmọ́ mi lẹ́nu bí mo ṣe ń kọ́

Amọ adajọ nibi igbẹjọ naa ni wọn kọ lati dahun si iwe ipẹjọ naa laarin ọjọ meje ọhun.

Nitori naa ni adajọ ṣe paṣẹ ki wọn ye gba owo ori to to ọgọrun mẹjọ naira naa lọwọ awọn awakọ to si sun igbẹjọ si Ọjọ Kẹfa, Oṣu Kẹfa, ọdun 2022.

Àkọlé fídíò, Amputee: Toheeb Abiodun Olaniyan: Ẹ̀rọ lílọ̀ ní ẹni ọdún mẹ́sàn án ni apa kan mi lọ sí