Lagos Okada ban: Àwọn ọmọ bíbí Arewa nípínlẹ̀ Eko ní àwọn àjèjì ló ń fi ọ̀kadà dáràn nípínlẹ̀ Eko

Awọn ọlọkada

Oríṣun àwòrán, lagos task force

Ẹgbẹ awọn ọmọ ẹkun ariwa orilẹ-ede Naijiria, Arewa Comunity, (LASACOMM) ni ipinlẹ Eko ti ke si ijọba ipinlẹ Eko pe gba-gba-gba- lawọn wa lẹyin aṣẹ to pa pe ki wọn ko igbokegbodo ọkada kuro nlẹ lawọn ijọba ibilẹ kan nipinlẹ Eko.

Ẹgbẹ awọn ọmọ ẹkun ariwa Naijiria naa ni ofin yii kii ṣe tuntun nitori pe awọn mọ pe o ti le ni ọdun mẹwaa ti aṣẹ naa ti wa nilẹ.

Ipinnu atilẹyin yii waye nibi ipade apero awọn ọmọ Arewa nipinlẹ Eko to waye nilu Eko.

Ninu atẹjade kan ti wọn fi sita lẹyin ipade naa, ti akọwe wọn, Alhaji Musa Saleh, fọwọ si ẹgbẹ naa ni awọn yoo maa tẹẹ mọ gbogbo awọn ọmọ ẹgbẹ Arewa nipinlẹ Eko leti nitori pe awọn mọ pe ofin naa wa fun idaabo bo ẹmi ati dukia araalu ni.

Àkọlé fídíò, Lasisi Jasper:Wo ìtàn ayé ọ̀gọ́ àgbà iléẹ̀kọ́ Adeniran Memorial ni Ogbomoso

Ẹgbẹ awọn ọmọ ẹkun ariwa Naijiria naa wa fi kun un pe awọn mọ pe awọn atọhunrinwa lati orilẹ-ede bii Niger Republic, Chad, Cameroun atawọn orilẹ-ede alamuleti miran lo n ṣọṣẹ.

Wọn ni pe won ti darapọ mọ awọn ọlọkada lo n hu iwa ọdaran gbogbo wọnyii eleyii to n ti igi bọ oju eto abo fun ẹmi ati dukia araalu ni ipinlẹ Eko.

Àkọlé fídíò, Oromidayo Daniel: Mo tú gbogbo ilé Dayo bóya á máa rí ǹkan tó ṣokùnfà ikú rẹ̀ ṣùgbọ́n...

Wọn wa ke si gbogbo awọn ileeṣẹ alaabo gbogbo, paapaajulọ ileeṣẹ wọlewọde lorilẹede Naijiria, iyẹn Nigeria Immigration Service lati tubọ mojuto bi awọn eeyan ṣe n wọle sorilẹede Naijiria latawọn ẹnubode rẹ gbogbo.

Bakan naa ni wọn tun ke si awọn ọmọ Arewa ati gbogbo awọn ọmọ Arewa to n ṣowo ọkada gigun jẹun lati yago si awọn ijọba ibilẹ Apapa, Surulere, Lagos Island, Lagos Mainland, Eti-Ọsa ati Ikẹja nibi ti ijọba ti fofin de igbokegbodo ọkada.

Àkọlé fídíò, Wo àwọn ohun tí BBC fìdí rẹ̀ múlẹ̀ nípa ohun tí àwọn ọmọ ẹgbẹ́ IPOB ń gbé sorí ayélujára

Idi ti ijọba fi gbẹsẹ le ọrọ ọkada nipinlẹ Eko

Lẹyin ti okiki iroyin bi awọn ọlọkada kan ṣe ṣekupa amojuẹrọ kan David Imoh ni ọjọ karundinlogun oṣu karun ni ijọba ipinlẹ Eko ba fi paṣẹ pe ki wọn palẹ gbogbo igbokegbodo ọkada mọ lawọn ijọba ibilẹ mẹfa kan- Apapa, Surulere, Lagos Island, Lagos Mainland, Eti-Ọsa ati Ikẹja- nipinlẹ naa.

Àkọlé fídíò, Títí ayé yóò fi parẹ́, wọ́n ó máa sọ̀rọ̀ sí Ànọ́bì ni, wọ́n ó sì máa bú Jésù ni, ẹ wá gbọ́ òótọ́ ohun tí Quaran sọ – Akeugbagold

Ijọba ipinlẹ Eko fi gbedeke ọjọ kini, oṣu kẹfa, gẹgẹ bi ọjọ ti aṣẹ yii gbọdọ bẹrẹ si ni fi idi mulẹ.

Amọ, ṣaaju aṣẹ yii ni ikọ amuṣẹya ijọba ipinlẹ Eko, Lagos State Taskforce ti ya bo agbegbe naa nibi ti wọn ti ko awọn ọlọkada to n ṣiṣẹ lọna ti ko ba ofin mu lagbegbe naa.

Àkọlé fídíò, 'Ọ̀pọ̀ ìgbà l'èmí gan fẹ́ du àwọn ipò òṣèlú kan, bíì '2015, 2019' àmọ́ mo tẹ 'slow' torí bàbà mi, Akala náà ń jáde'

Alaga ajọ naa, CSP Shọla Jẹjẹloye ni pẹlu gbogbo igbesẹ ti wọn ti gbe ṣaaju awọn ọlọkada naa kọ lati jawe tuntun sobi iṣẹ ati iṣe wọn lẹnu iṣẹ.