Lagos state; Ó kéré tán ẹran N328 bilionu ni àwọn ará Eko ń jẹ ní ọdọọdún

Ijọba ipinlẹ Eko ti kede pe o kere tan ẹran biliọnu ọọdunrun o le ni awọn ara Eko n jẹ ni ọdọọdun.
Akọwe agba ni ileeṣẹ ijọba ipinlẹ Eko to n risi ọrọ iṣẹ agbẹ, Ibironke Emokpae lo fi iroyin naa lede.
Akọwe Agba to ṣoju fun kọmisọnna nibi ipade ti wọn ti pe awọn oniṣowo lati wa dowopọ pẹlu ijọba lori eto ọṣin maluu.
Ijọba ni o ṣeni laanu pe ida aadọrun ninu ẹran yii lo n wa lati ariwa orilẹede Naijiria.
- Wo àwọn iṣẹ́ méje tí o lè kọ́ láàrín oṣù mẹ́ta ti ASUU da iṣẹ́ sílẹ̀
- Ìdí mọ́kànlá nìyìí tí mo fi fẹ́ díje dupò ààrẹ ní Naijiria – Bukola Saraki
- Óṣe! ènìyàn kan kú ẹlòmíràn farapa bí ọkọ̀ ńlá ṣe jábọ́ léwọn lórí l'Eko
- Fí fún ẹkùn tàbí ẹ̀yà kan ní tíkẹ́ẹ̀tì 'zoning' kò sí nínú òfin ẹgbẹ́ wa - PDP
- Ààrẹ Buhari pàrọwà sí ASUU láti padà sẹ́nu iṣẹ́ nítorí àwọn akẹ́kọ̀ọ́
- Wo àwọn mínísítà ìjọba Nàìjíríà tó ti kọ̀wé fipò sílẹ̀ nítorí àṣẹ Ààrẹ Buhari
Kini ijọba Eko n ṣe lati pese ẹran labẹle?
O fikun pe ida piniṣin to ku nikan ni wọn n ṣe ni abẹle, eleyii ti ko to awọn eniyan lati jẹ.
Bakan naa ni wọn fikun un pe gomina ipinlẹ Eko, Babajide Sanwo-Olu ti gbe awọn eto kalẹ ni ẹka eto ọgbin ti yoo mu ki ẹka naa gbooro si ju ti tẹlẹ lọ.
Ijọba ipinlẹ Eko naa fikun un pe eto yii yoo pese ounjẹ ati eto ọgbin fun awọn eniyan ti wọn ko ni nilo ati maa lọ si ariwa Naijiria, ki wọn to le ni eto ọgbin to gbooro.
Wọn fikun un pe pẹlu eto ti ijọba Eko fẹ ṣe agbẹkalẹ rẹ yii yoo rọrun lati sin maluu ọlọgọọrọ loju kan naa, ti eyi yoo si pese ẹran lọpọ yanturu fun awọn ara ipinlẹ Eko.
Bakan naa ni yo fi opin si iyan ounjẹ ni ipinlẹ Eko ati lorilẹede Naijiria.
- Mọ̀ síi nípa IPOB tó ń gbé orí ayélujára dá rúgúdú sílẹ̀ nítorí ọ̀rọ̀ Biafra
- Kìí ṣe àwọn mínísítà tó fẹ́ dupò nìkan ní Buhari ní kó fi iṣẹ́ sílẹ̀ , wo àwọn tó tún kàn
- Ọ̀rọ̀ pátà dídọ̀tí tún rúná sí ìjà láàrin Nkechi Blessing àti ọ̀rẹ́kùnrin rẹ̀ tẹ́lẹ̀, Falegan
- Èèyàn 60 l'erin ti pa láàrín ọdún yìí nìkan lórílẹ̀èdè Zimbabwe
- Àwọn olùfẹ̀hónúhàn dáná sun dúkìá bí ìwọ́de ṣe ń le si
- Ẹ múra o, ọ̀wọ́n gógó bẹntiró ń rúgbó bọ̀- IPMAN ṣèkìlọ̀ fún àwọn ọmọ Nàìjíríà














