Buhari visit to Kano: A kò ní sinmi títí tí àlááfíà yóò fi padà sí Naìjíríà- Buhari

Buhari

Oríṣun àwòrán, @Presidency

Muhammadu Buhari ṣèlérí ètò amáyédẹrùn fún àwọn ọmọ ogun, àti láti pèsè ètò àbò tó péye

Aarẹ Muhammadu Buhari ti sọ pe ijọba oun ko ni sinmi ayafi to ba yanju iṣoro to n koju ẹka eto abo ni gbogbo kọrọkọndu orilẹ-ede Naijiria.

Buhari lo sọ ọrọ naa nibi ipade awọn ọmọ ileeṣẹ ọmọ ogun orufurufu kan to waye niluu Kano ni ariwa Naijiria.

O ni "Ijọba yii ko ni sinmi titi ti a oo fi da alaafia ati eto to peye pada si orilẹ-ede yii."

Buhari tun fi akoko naa ki awọn ọmọ ogun ọhun ku iṣẹ takun-takun ti wọn n ṣe lati dabo bo awọn araalu.

O ni ijọba oun ko ni fa ọwọ atilẹyin rẹ sẹyin lọdọ awọn ọmọ ogun naa latari iṣẹ akinkanju tio wọn n ṣe.

Àkọlé fídíò, Lasisi Jasper:Wo ìtàn ayé ọ̀gọ́ àgbà iléẹ̀kọ́ Adeniran Memorial ni Ogbomoso

A ti ṣetan lati jawe sobi akitiyan wa

Nigba toi n fi ẹmi imoore han si awọn o logun naa fun bi wọn ṣe n fi wọn wewu, Buhari ni "Mo fẹ fi da yin loju pe awọn ọmọ Naijiria mọ riri iṣẹ akin ti ẹ n ṣe."

Àkọlé fídíò, Oromidayo Daniel: Mo tú gbogbo ilé Dayo bóya á máa rí ǹkan tó ṣokùnfà ikú rẹ̀ ṣùgbọ́n...

Lẹyin naa lo rọ wọn lati maṣe fa sẹyin ninu ojuṣe wọn nitori obitibiti owo ti ijọba ti na lori ẹka eto abo, eyii to ti n so eso rere.

O ni "Ninu afojusun wa lati tubọ jẹ ki ileeṣẹ ọmọ ogun ofurufu ba igba mu, a oo tubọ maa na ọwọ si ileeṣẹ naa."

"Fun idi eyii, a ti gbe owo kalẹ lati ra awọn irinṣẹ ogun, to fi mọ awọn ọkọ UAV ati elikọpita lati mu ki iṣẹ yin rọrun."

"A fẹ ki ẹ mọ pe ijọba wa ti ṣetan lati ṣe gbogbo ohun to yẹ lati ri pe a ṣe gbogbo atilẹyin to yẹ fun yin lati yanju iṣoro to n koju eto abo."

Àkọlé fídíò, Wo àwọn ohun tí BBC fìdí rẹ̀ múlẹ̀ nípa ohun tí àwọn ọmọ ẹgbẹ́ IPOB ń gbé sorí ayélujára

Buhari tun ṣeleri lati ṣeto awọn ohun igbayegbadun fun awọn ọmọ ogun naa.

Lara awọn to wa nibi ipade naa ni gomina ipinlẹ Kano, Abdullahi Ganduje, awọn lọgalọga nileeṣẹ ọmọ ogun, awọn ọba alade, to fi mọ awọn ọmọ ile igbimọ aṣofin.

Àkọlé fídíò, Títí ayé yóò fi parẹ́, wọ́n ó máa sọ̀rọ̀ sí Ànọ́bì ni, wọ́n ó sì máa bú Jésù ni, ẹ wá gbọ́ òótọ́ ohun tí Quaran sọ – Akeugbagold