Timothy Adegoke: Ẹlẹ́rìí ẹjọ́ ikú Timothy Adegoke ṣàlàyé fún ilé ẹjọ́ pé Ọlọ́pàá fipà mú òun láti bu wọ lùwé àkọsílẹ̀ 'statement' òun ni

Iléẹjọ́ sún ìgbẹ́jọ́ lórí ikú Timothy Adegoke sí ọjọ́ Aje
Ileẹjọ giga ipinle Osun ti o gbọ ẹjọ lori iku Timothy Adegoke akẹkọọ Fasiti Obafemi Awolowo ti sun igbejo si ọjọ́ Aje.
Adajo Adepele Ojo so elẹyi lẹyin ti agbejoro fun ookan lara awọn afurasi, Ita Edet Okon ni awọn ẹlẹrii oun o ri aye lati yoju si Ile ejo ni oni.
Okon ro ile ejo giga ipinle Osun lati fun awọn ẹlẹrii ni anfani lati wa si ile ẹjọ ni ojo Aje.
Lẹyin ti Agbejoro Ita Edet Okon ro ile ejo ni Adajo Adepele Ojo wa sun igbejo si ọjo Aje ti o jẹ ogbon ọjọ, oṣu karun-un, ọdun 2022.
- Ìkò Ipolongo tí APC yàn sá̀ájú ìdìbò sípò gómínà ní Ekiti rè é…
- Mà á dá fijilanté sílẹ̀, òmìnira á wà fún ìjọba ìbílẹ̀ láti ná owó wọn- Oluwole Oluyede
- Ó ṣe! ọkọ olùkọ́ tó bá ìṣẹ̀lẹ̀ ìpànìyàn tó wáyé nílé ẹ̀kọ́ Texas dágbére fáyé
- Ọlọ́pàá fipá mú mi láti buwọ́lu 'Statement'ti mí ò kọ̀ fúnra mi nípa ikú Timothy Adegoke-Adeniyi
- Ohun ìbànújẹ́ ló ṣẹlẹ̀ ní Anambra, ẹ dákún mi ò fẹ́ kẹ́nikẹ́ni fi oró ya oró lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà- Buhari
- Olùdásílẹ̀ iléeṣẹ́ rédíò Agidigbo, Oriyomi Hamzat ti gba ìtúsílẹ̀
- Ẹgbẹ́ òṣèlú APC Oyo sún ètò ìdìbò abẹ́nú sí òní, ìdí rèé
- Ìjoba ti fi èsùn ìpànìyàn kan oko Osinachi, Peter Nwachukwu
Mi ò mọ nǹkan kan nípa 'receipt' ṣùgbọ́n èmi ní mó kó Ẹ̀dá ìwé account- Adeniyi Aderogba, ẹlẹ́rìí ẹjọ́ ikú Timothy Adegoke
Alamojuto ilé itura Hilton hotel, Ogbeni Adeniyi Aderogba sọ fun Ile ejo giga ipinle Osun pe oun o ko mọ nǹkan kan nipa bi wọn ṣe fun oloogbe Timothy Adegoke ni recipt sugbọn ohun ni o ko eda
iwe account ti wọn gbe fun awọn olopaa.
Iwe account ni Adeniyi Aderogba ṣe eda rẹ miiran ti ko ni oruko Timothy Adegoke gege alejo akoko lẹyin ti afurasí miiran Adedeji Adesola ko orúkọ oloogbe naa silẹ gege alejo akoko.
Aderogba, ẹni ọdun marundilogoji ní ọmọ oloye Ramon Adedoyin ti o jẹ Roheem Adedoyin ni o pa lase fun oun lati tun iwe account miiran ko.
- Mà á dá fijilanté sílẹ̀, òmìnira á wà fún ìjọba ìbílẹ̀ láti ná owó wọn- Oluwole Oluyede
- Àwọn ọmọ tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ bí mọ́kànlá pàdánù ẹ̀mi wọn lẹ́yìn iná tó ṣẹ́yọ
- Ẹ̀sùn títàpá sófin tó tako ìwà kòtọ́ lórí ayélujára 'Cybercrime' la fi gbé Oriyomi Hamzat - Ọlọ́pàá
- Wo ojú àwọn tó fẹ́ díje dupò gómìnà lábẹ́ ẹgbẹ́ APC ní ìpínlẹ̀ Oyo lónìí
O tesiwaju lati sọ fun Adajo Adepele Ojo pe awọn olopaa ipinlẹ Osun fi agidi mo oun lati gba ohun lenu oun ati pe pẹlu agídí ni oun fi ti owo bo iwe àkọsílẹ̀ fun Ile ise olopaa.
Aderogba tun so fun Ile ejo giga ipinle Osun pe oun pẹlu Oyetunde Kazeem ati Roheem Adedoyin lati gbe oku Timothy Adegoke lọ sí Ede road pẹlu oko funfun Hilux.
"Magdalene Chiefuna ni o pe mi lẹyin tí ati gbinyanju lati pe alejo to wa ninu yara 305 tí ko si da wa lohun.
"Chiefuna ni oun ti rí eda kọkọrọ fun yara 305 tí òun si ba oku Timothy Adegoke ni o ri bedi to sun si, mo gbera lati lọ si ile ìtura naa lati woo nkan ti o sele.
"Emi pẹlu Magdalene Chiefuna lọ sí inu yara naa lati woo nkan ti o sele, orun naa poo gan tí mo si fi owo bo imu mi.
"Mo gbe ero ibanisoro mi láti pe Chairman Ramon Adedoyin, mọ salaye fun wọn ti wọn si ni awọn ma pe Roheem Adedoyin lati fi to ilé olopaa leti.
"Nigba ti Roheem Adedoyin de, a jọ lọ si inu yara naa ti a si ba oku Timothy Adegoke nibe. Roheem Adedoyin sọ fun mi pe oun fe lọ sí odo àwọn olopaa, lẹyin ọpọlọpọ wakati tí a fi rẹ tí Roheem Adedoyin.
"Roheem Adedoyin pada de ni asalale ti o si ni oun ti sọ fun awọn olopaa ti wọn si ni kí awọn ma gbe oku Timothy Adegoke lọ si ile oku ni ile eko giga fasiti Obafemi Awolowo Teaching Hospital.
"Ṣugbọn Roheem Adedoyin kọ lati gba ona ile eko giga fasiti Obafemi Awolowo ti o mú orí le ona ede road.
"Roheem Adedoyin gbe oku Timothy Adegoke kuro lẹyin oko lilux funfun ti o si gbe si ọna pẹlu bagi rẹ.
" Mo bi Roheem Adedoyin idi ti a fi gbe oku Timothy Adegoke lọ sí Ede road, O ni eru olopaa ba oun.
Adeniyi Aderogba tun wa sọ ile ejo giga ipinle Osun pe pẹlu agídí ni awọn olopaa fi gba ohun lenu oun lori iku Timothy Adegoke.
Agbejoro M.O Omashun bere lọwọ Arakunrin Adeniyi Aderogba pe boya o ri eje nigba ti o se ayẹwo si oku Timothy Adegoke nínu yara 305.
Ninu akọsilẹ ti Adeniyi Aderogba sọ fun awọn olopaa, o ni oun ri ẹ̀jẹ̀ ninu imu ologbe Timothy Adegoke nigba ti o ayẹwo si yara 305.
"Ikan ti mo ri nigba ti mo ṣe ayẹwo sì oku Timothy Adegoke nínu yara 305 ki n se eje rara sugbọn awọn olopaa fi lilu alubami gba ohun mi si ile
Adeniyi Aderogba tesiwaju pe oun ko kopa ninu ipade tabi imule kankan ni ile dokita Ramon Adedoyin lẹyin isele naa
"Mio fi oju mi kan dokita Ramon Adedoyin tabi lọ si ile wọn láti mule kankan.
"Nigba ti a de agoo olopaa ni mo ri dokita Ramon Adedoyin soju.
Àwa mẹ́ta la gbé òkú Timothy Adegoke lọ sí Ede road- Ẹlẹ́rìí Oyetunde Kazeem
Ọkan lara awọn afurasi tí o jẹri lori iku Timothy Adegoke, Oyetunde Kazeem ni Roheem Adedoyin ni o siwaju bi awọn ṣe gbé oku Timothy Adegoke lati ile ìtura Hilton Hotel Honour lọ sí Ede road niluu ile ife.
Oyetunde, ẹni to je osise ìle itura Hilton Hotel ni ọmọ Adedoyin woo oku naa pẹlu asọ duvet tí o fi bora.
O ni ọmọ Adedoyin ni eru olopaa ba ohun ni oun ṣe gbẹ igbese naa.
Ninu oro afurasi naa o ni oun pẹlu monija ile ìtura Adeniyi Aderogba ranse pe Roheem Adedoyin pe eeyan ti ku si ninu yara 305
"bi Roheem Adedoyin ṣe de, o gba kọkọrọ, o si ni kí a tẹlẹ oun lọ sí ninu yara naa.
"A ba oku Timothy Adegoke lori bed pẹlu laptop ati ero ibanisoro rẹ. Roheem Adedoyin ni ki a bosi ita pe oun fe lọ fi to olopaa leti.

"Nigba ti o di ale, Roheem Adedoyin pa da si ile ìtura pe oun ti ba awọn olopaa soro tí wọn si ki wọn gbẹ oku naa lọ si ile oku.
"A gbe oku naa si inu oko lilux funfun sugbọn o ya mi lenu nigba ti a mori le ona Ede road. Mo bere lowo Roheem Adedoyin sugbon ko dami lohun.
"Nigba ti a de ibi kan, Roheem Adedoyin pana moto ti o si woo oku naa si egbe ona pẹlu aso duvet, laptop ati ero ibanisoro silẹ.
"Mo tun bi Roheem Adedoyin idi ti a fi gbe oku Timothy Adegoke lọ si ede road, O sọ fun mi pe eru olopaa ba oun pupo nitori pe nnkan miiran le jade."
Oyetunde Kazeem wa fi idi e mule pe oun ko kopa ninu bi awọn akẹgbẹ ṣe múlẹ.

Oríṣun àwòrán, others
Ni ọjọ kẹẹdọgbọn, oṣu karun un, ọdun 2022 yii ni igbẹjọ lori iku oloogbe Timothy Adegoke n tesiwaju nile ẹjọ giga ni Osogbo
Dókítà mìíràn takò esi ayẹwo ara, Òṣìṣẹ́ Hilton Hotel jẹwọ pe otitọ nipé awon múlẹ
Ni ana ode yi ojo kedogbon osu karùn-ún ọdun 2022 ni igbẹjọ lori iku Arakunrin Timothy Adegoke tesiwaju,
Content is not available
View content on FacebookBBC kò mọ̀ nípa àwọn ohun tí ó wà ní àwọn ojú òpó tí ó wà ní ìta.End of Facebook post, 1
Igbejo beere pẹlu ohun iyalẹnu fun awọn akoroyin lẹyin ti Dokita Rahmon Adedoyin bẹrẹ si i ṣepe fun wọn pe awọn ti o n ya fọto oun.

Content is not available
View content on FacebookBBC kò mọ̀ nípa àwọn ohun tí ó wà ní àwọn ojú òpó tí ó wà ní ìta.End of Facebook post, 2
Adedoyin lo ni ileetura Hilton to wa niluu Ileefẹ, nibi ti akẹkọọ Fasiti OAU kan, Timothy Adegoke, ku si loṣu Kọkanla, ọdun to kọja.
- Gómìnà Anambra, Àjọ CAN, Àjọ Arewa bu ẹnu àtẹ́ lu obìnrin àti àwọn ọmọ rẹ̀ tí wọ́n ṣekúpa
- Àwọn agbébọn jí fadá ìjọ Kátólíkì méjì gbé ní Katsina
- Òní lònìí ń jẹ́, BBC Yorùbá ti ṣetán láti bẹ̀rẹ̀ Ipàdé Itagbangba ní Ekiti pẹ̀lú àwọn olùdíje sípò gómìnà
- Òtítọ́ ni pé a mùlẹ̀ láti má sọ fún ẹnì kankan- Magdalene Chiefuna, òṣìṣẹ́ Hilton Hotel jẹ́wọ́ nílé ẹjọ́
- Wo nkan tó yẹ kí o mọ̀ nípa 'BBC Yoruba Ekiti Governorship Debate' tí yóò wáyé lọ̀sẹ̀ yìí
- Gbajúmọ̀ Olórin Banky W ti rí tíkẹ̀ẹ̀tì ẹgbẹ́ òṣèlú PDP gbà láti díje dupò aṣòfin
- Afurasí 4,000 la fi ṣìkùn òfin mú láàrín ọṣù márùn ún- Amotekun Ondo
- Ta ni Anamekwe Nwabuoku tí ìjọba yàn láti delé sí ipò olùṣirò owó àgbà ní Nàìjíríà (AGF)?
Adedoyin ati awọn oṣiṣẹ rẹ mẹfa ni wọn n jẹjọ lori ẹsun bii mọkanla ti wọn fi kan wọn.
Loṣu kan sẹyin to yẹ ki awọn olujẹjọ bẹrẹ awijare wọn niwaju Onidaajọ Adepele Ojo ti ile-ẹjọ giga ipinlẹ Ọṣun ni agbẹjọro fun Adedoyin, Barisita Ẹlẹja (SAN), sọ pe ko ni ẹlẹrii kankan lati pe.
Dokita ẹni tí ó jẹ ojogbon lati ile eko giga fasiti Obafemi Awolowo Teaching Hospital, Olusegun Silvester Ojo ni esi ayẹwo ara ti wọn akẹgbẹ oun se lori iku Timothy Adegoke ni ko waye laito, ti oun si keyin si ọpọlọpọ oun ti wọn gbẹ jade ati pe ko si nnkan to jọ pe ẹjẹ n da lati inu wa.
Ojogbon Ojo naa pẹlu Dokita Akin Komolafe ni ayẹwo wọn yato esi ayẹwo awọn dokita mẹfa to ṣe ayẹwo ara Timothy Adegoke lẹyin tí wọn gbẹ oku rẹ ni Ede road niluu ile ife.
Ní afikun, okan lara awọn afurasi to jẹjọ lori iku Timothy Adegoke, Magdalene Chiefuna sọ fun Ile ẹjọ giga ipinlẹ Ọṣun ni ana pe otitọ ni awọn mulẹ lati maṣe sọ ọrọ lori iku Timothy Adegoke fun ẹnikẹni lẹyin iṣẹlẹ naa.
Chiefuna, ẹni ọdun mẹ́rìnlélógún, akẹkọọ fasiti Ọbafẹmi Awolọwọ to tun jẹ ọkan lara awọn òṣìṣẹ́ ìle itura Hilton Hotel ni ilu Ile-Ifẹ lo fi idi ọrọ náà mulẹ nigbati o dahun ibere lati ọwọ agbejoro Fẹmi Falana.
Ó ni idi ti awọn fi múlẹ lati ma sọ fún ẹni kankan ni làti dabo bo ilé itura Hilton hotel.
















