Oriyomi Hamzat: Olùdásílẹ̀ iléeṣẹ́ rédíò Agidigbo, Oriyomi Hamzat ti gba ìtúsílẹ̀

oriyomi Hamzat

Oríṣun àwòrán, other

Oriyomi Hamzat: Ó tọ́pẹ́! Oriyomi Hamzat ti gba ìtúsílẹ̀.

Gbajugbaja akọroyin to tun jẹ oludasilẹ ileeṣẹ redio Agidigbo FM, Oriyomi Hamzat ti gba itusilẹ.

Hamzat ni wọn fi panpẹ ọba mu ti wọn si gbe lọ si ilu Abuja, ni wọn ti tusilẹ bayii.

Kaakiri Naijiria ni iroyin gbode kan pe ileeṣẹ ọtẹlẹmuyẹ ni Naijiria fi iwe pe Hamzat, ti wọn si fi panpẹ ọba mu lai sọ ẹṣẹ rẹ fun ẹnikẹni.

Amọ ninu fidio ti Hamzat fun ara rẹ gbe jade lo ti sọ wi pe nitori iroyin iku akẹkọọ fasiti OAU ti wọn pa ni Ile Ife, ti oun ko si jawọ ninu iroyin naa lo fa a ti wọn fi n wa ẹmi oun.

O fikun pe oun ko ni jawo ninu iroyin otitọ ati ododo ninu iṣẹ ti oun yan laayo.

Amọ ileeṣẹ ọlọpaa lorilẹede Naijiria ni idi ti wọn fi fi panpẹ ọba mu wọn ni nitori pe wọn fi ẹsun idukoko lori ayelujara kan ọkunrin naa, eleyii to si jasi ẹsẹ si ofin.

Àkọlé fídíò, Children Day 2022: Àwa Obìnrin kìí ṣe àpínmógún, àtẹ̀mẹ́rẹ̀; àwa ní iyọ̀ àti ìrèké ayé

Ninu atẹjade ti ileeṣẹ iroyin Agidigbo 88.7fm fi lede ni wọn ti dupẹ lọwọ gbogbo awọn ọmọ Naijirira fun aduroti wọn.

Bakan naa ni wọn ni ọga awọn ko jẹbi ẹsun ti wọn fi kan an ti ko si dunkoko mọ ẹnikẹni, eleyii to tako ohun ti ileeṣẹ ọlọpaa sọ.

Hamzat

Oríṣun àwòrán, @Agidigbo

Wọn fikun un pe awọn agbẹjọrọ Maye ti Ife, Ramon Adedoyin ti wọn fi ẹsun ipaniyan Adegoke kan lo wa ni idi iṣẹlẹ naa.

Wọn ni igbesẹ ti ijọba gbe naa ni lati dunkoko mọ Hamzat nitori oun ko iroyin lati pe fun idajọ otitọ ati ododo lori ipaniyan akẹkọọ fasiti OAU, Timothy Adegoke.

Ẹ̀sùn títàpá sófin tó tako ìwà kòtọ́ lórí ayélujára 'Cybercrime' la fi gbé Oriyomi Hamzat - Ọlọ́pàá

Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ní sùn títàpá sófin tó tako ìwà kòtọ́ lórí ayélujára 'Cybercrime' la fi gbé Oriyomi Hamzat, àwọn sì gbàyọ̀ǹda níléẹjọ́

Ileeṣẹ iroyin Agidigbo ni ifipanpẹ mu ni naa niise pẹlu Maye ti Ife, Ramon Adedoyin lori ẹsun ipaniyan Timothy Adegoke

Àkọlé fídíò, Oba Adedokun Abolarin ti Oke Ila: Ó ya ọ̀pọ̀ tó súnmọ́ mi lẹ́nu bí mo ṣe ń kọ́

Ileeṣẹ ọlọpaa ti sọrọ lori bi wọn ṣe mu gbajumọ agbohusafẹfẹ kan nilu Ibadan, Oriyọmi Hamzat lọjọbọ.

Oriyọmi ti kọkọ sọ ninu fidio kan to fi ṣọwọ si BBC News Yoruba pe nitori awiiyannu oun lori wiwa idajọ ododo fun oku Timothy Adegoke, akẹkọọ fasiti OAU kan to ku sileetura Hilton Hotel to jẹ ti Oloye Rahaman Adedoyin nile Ifẹ.

Amọṣa ileeṣẹ ọlọpaa Naijiria ti sọ pe otitọ to jina sootọ pata leyi ati pe titapa si ofin iwa kotọ lori ayelujara, Cybercrime Act 2015 ni wọn fi gbe.

Alukoro ileeṣẹ ọ̀lọ̀paa Naijiria, Ọmọọba Olumuyiwa Adejọbi ṣalaye fun BBC News Yoruba pe lootọ ni wọn mu Oriyọmu Hamzat nitori awọn eeyan kan fi sun pe awọn ohun to n ṣe lori ayelujara tako ofin to gbogun ti iwa kotọ lori ayelujara, iyẹn Cybercrime Act.

O ni fun ọpọlọpọ igba lawọn ọ̀lọpaa si ti kọwe pe Oriyọmi Hamzat lori afẹfẹ ṣugbọn to kọ lati farahan lọdọ awọn ọlọpaa.

Atẹjade lati ileeṣẹ ọlọpaa

Oríṣun àwòrán, Screenshot

O ni igba to kọ lati farahan lawọn ọlọpaa fi lọgba iwe igbayọnda lati mu u ni ile ẹjọ ti wọn si lọ mu u lọjọbọ.

Alukoro ileeṣẹ ọlọpaa Naijiria tun ṣalaye siwaju ninu atẹjade kan to fi sita lori iṣẹlẹ naa lọsan Ọjọbọ pe ẹsun idunmọ̀hurumọni lori ayelujara ni wọn fi kan an ni pato; awọn si n ṣewadii lori ẹsun naa lati mọ igbesẹ to kan ti awọn yoo gbe lori rẹ.

Àkọlé fídíò, 'FUJI níkan ni ‘beat’ tó jẹ́ àṣà wa, ‘Highlife’ kìí ṣe tiwa, kò sóhun tó jọ pé àwọn ọmọ Sàtání ló ń kọ Fuji Gospel'

Oriyomi Hamzat wọ gbaga ọlọ́pàá 'nítorí ọ̀rọ̀ Timothy Adegoke tó kú sílé ìtura Rahman Adedoyin'

Oriyomi Hamzat, ìlúmọ̀ọ́ká agbóhùnsáfẹ́fẹ́ wọ gbaga ọlọ́pàá nítorí ọ̀rọ̀ Timothy Adegoke tó kú sílé ìtura Rahman Adedoyin

Gbajumọ agbohunsafẹfẹ kan nilu Ibadan, Oriyọmi Hamzat ti wa lakata awọn ọlọpaa bayii.

Àkọlé fídíò, Ayodeji Rotinwa ni ìròyìnn òfegè gbé àwòrán rẹ̀ síta pè dókítà tó ń pa àwọn Hausa mùsùlùmí

Irọyin to tẹ ileeṣẹ BBC lọwọ fidi rẹ mulẹ pe owurọ Ọjọbọ ni awọn agbofinro wa gbe e ti wọn si taare rẹ si olu ileeṣẹ ọlọpaa nilu Abuja.

Ninu fidio to kan to tẹ BBC lọwọ, ilumọọka agbohunsafẹfẹ naa to tun jẹ oludasilẹ ileeṣẹ redio aladani kan nilu Ibadan ṣalaye pe awọn ọlọpaa ẹka ọtẹlẹmuyẹ SIIB lo wa gbe oun ti wọn si taare oun si ọwọ awọn ọlọpaa ọtẹlẹmuyẹ FIIB nilu Abuja.

Àkọlé fídíò, Oromidayo Daniel: Mo tú gbogbo ilé Dayo bóya á máa rí ǹkan tó ṣokùnfà ikú rẹ̀ ṣùgbọ́n...

Ninu fidio naa, Oriyọmi Hamzat ni ilu Abuja loun wa ni ọfiisi awọn ọlọpaa naa ati pe ki araalu lee mọ pe ara oun da pe nigba ti oun de ileeṣẹ ọ̀lọpaa ni oun ṣe ṣe fidio naa ai baa mọ bi ọrọ ba ba ibomiran yọ loun fi ṣe fidio naa.

Àkọlé fídíò, Amputee: Toheeb Abiodun Olaniyan: Ẹ̀rọ lílọ̀ ní ẹni ọdún mẹ́sàn án ni apa kan mi lọ sí

O ṣalaye siwaju sii pe awọn agbofinro naa jẹ ko di mimọ pe agboye ilu Ile Ifẹ to n jẹjọ lori iku akẹkọọ fasiti Ifẹ, Timothy Adegoke,

Iyẹn Oloye Rahaman Adedoyin lo kọwe si awọn agbofinro nipa gbọnmọgbọnmọ oun lori wiwa idajọ ododo fun Timothy Adegoke to doloogbe ati awọn mọlẹbi rẹ.

Atejade

Oríṣun àwòrán, Agidigbo fm

Ile ẹjọ Giga ipinlẹ Ọṣun nilu Osogbo n gbọ ẹjọ lori iku Timothy Adegoke lẹyin ti awọn agbofinro gbe Oloye Rahaman Adedoyin atawọn oṣiṣẹ ile itura rẹ, Hilton Hotel nilu ile ifẹ lọ sile ẹjọ.

Lori ẹsun pe ki wọn wa wi tẹnuwọn lori ohun to ṣokunfa iku akẹkọọ naa.

Nigba ti BBC kan si alukoro ileeṣẹ ọlọpaa orilẹ-ede Naijiria lati beere bi ọrọ naa ṣe jẹ pẹlu awọn ọlọpaa, alukoro ileeṣẹ ọlọpaa, Ọmọọba Olumuyiwa Adejọbi ṣalaye pe oun yoo bere lori rẹ lati jabọ fun wa lori bo ṣe n lọ.

Àkọlé fídíò, 'Ọ̀pọ̀ ìgbà l'èmí gan fẹ́ du àwọn ipò òṣèlú kan, bíì '2015, 2019' àmọ́ mo tẹ 'slow' torí bàbà mi, Akala náà ń jáde'