APC primaries list: Ìwé orúkọ àwọn olùdíje tó bórí ìbó abẹ́nú gómìnà ní APC

Gomina APC

Oríṣun àwòrán, Others

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 4

Ni kete ti asiko ti ajo eleto idibo fun awọn ẹgbẹ oṣẹlu ti n kan ilẹkun gbọngbọn ni pọpọ ṣinṣin ti bẹrẹ kaakiri.

Opọ ẹgbẹ oṣelu lo tun ile iya ẹgbẹ ṣe ti wọn si fi gbendeke sii iye owo gbigba fọọmu idije ati asiko to tọ.Ẹgbẹ́ òṣèlú APC Oyo sún ètò ìdìbò abẹ́nú sí òní, ìdí rèé

Lẹyin naa ni eto ipolongo ati eto idibo bẹrẹ kaakiri awọn ipinlẹ.

Bi awọn kan ṣe n jawe olubori ni awọn mii n fidiremi.Ìwé orúkọ àwọn olùdíje tó bórí ìbó abẹ́nú gómìnà ní APC

Gomina Sanwo Olu- ipinle Eko, Dapo Abiodun- ipinle Ogun ati Abdularamon Abdulrazak- Ipinle Kwara ti jawe olubori lati dije ni abẹ APC.

Awọn aṣojudibo APC

Oríṣun àwòrán, dapo abiodunmfr/twitter

Bakan naa ni gomina Mai Mala Buni jawe olubori lati tesiwaju ni ipinle Yobe

Gomina Zulum n tesiwaju labe APC ni ipinle Borno

Gomina Inuwa n soju APC ni ipinle Kebbi

Nigba ti gomina Abullahi Sule n t4esiwaju lati dije dupo ni ipinle Nasarawa.

Àkọlé fídíò, Children Day 2022: Àwa Obìnrin kìí ṣe àpínmógún, àtẹ̀mẹ́rẹ̀; àwa ní iyọ̀ àti ìrèké ayé

Ìwé orúkọ àwọn olùdíje tó bórí ìbó abẹ́nú gómìnà ní APC

Lẹyin ọpọlọpọ kukukẹkẹ lati gbaradi fun idibo ọdun 2023, aworan bi awọ̀ọn oludibo yoo ṣe ri kaakiri ẹgbẹ oṣelu ti n gbera sọ bayii.

Lọjọbọ ọjọ kẹrindinlọgbọn oṣu karun un ọdun 2022 lẹgbẹ oṣelu APC ṣeto ibo abẹnu lati yan awọn oludije fun ipo gomina kaakiri awọn ipinlẹ lorilẹede Naijiria.

Laideena pẹnu, oniruuru iṣẹlẹ awodamiẹnu lo waye lawọn ibudo idibo abẹnu naa kaakiri orilẹede Naijiria.

Eyi wa ni bi awọn to gbegba oroke ṣe bori.

Babajide sanwo-olu

Oríṣun àwòrán, Babajide sanwo-olu/twitter

Eko akete gbe Sanwo-olu lẹẹkeji

Gomina Babajide Sanwo-Olu lo bori ibo abẹnu ni ipinlẹ Eko. Ibo kolatako ni wọn ṣe fu n un.

Eyi waye lẹyin ti iroyin jade pe awọn meji to ku ti wọn n baa du oye naa- kọmiṣọna fohun amuṣagbara nipinlẹ Eko tẹlẹ, Wale Oluwo ati akọwe agba tẹlẹ nilleṣẹ ohun amugbara yii kan naa, Mustapha Ọlọrunfẹmi- ko kogoja

Iyen, ninu eto ayẹwo ti wọn ṣe fawọn oludije ẹgbẹ fun ipo gomina lolu ileeṣẹ ẹgbẹ oṣelu naa nilu Abuja.

Gomina Dapo Abiodun laarin awọn ero

Oríṣun àwòrán, dabiodunMFR/twitter

Laarin ọpọlọpọ awuyewuye, Dapọ Abiọdun yọ ni ipinlẹ Ogun

Oludije marun un miran lo ba gomina ipinlẹ Ogun, Dapọ Abiọdun figagbaga fun aṣia ẹgbẹ APC, amọṣa Gomina Abiọdun bori pẹlu ibo ẹgbẹrun kan ati mejidinlaadọsan, (1,168)

Amọṣa, meji ninu awọn oludije naa, Adekunle Akinlade ati Biyi Ọtẹgbẹyẹ ni wọn ti tako alaga igbimọ idibo ti ẹgbẹ oṣelu naa fi ranṣẹ si ipinlẹ naa, iyẹn ọgbẹni Wale Ohu

Awọn oludije naa sọ ọ ninu atẹjade kan ti wọn jumọ fọwọ si tun kọminu lori iwe orukọ awọn aṣojudibo ti wọn lo fun idibo abẹnu naa.

Skip Facebook post

Content is not available

View content on FacebookBBC kò mọ̀ nípa àwọn ohun tí ó wà ní àwọn ojú òpó tí ó wà ní ìta.

End of Facebook post

Ni ipinlẹ Rivers

Tonye Cole lo bori ibo abẹnu fun ipo gomina labẹ aṣia ẹgbẹ oṣelu APC nipinlẹ Rivers.

Ibo ọrinlelẹẹdẹgbẹrun o le mẹfa, (986) lo ni.

Bi idibo naa si ṣe lọ niyi:

Michael West 43,

Tonye Cole Patrick 986,

ibudo idibo APC kan

Oríṣun àwòrán, Babajide sanwo-olu

Bernard Mikko 2,

Magnus Abe 1,

Sokonte Davies 49,

Ojukaye 190.

Àkọlé fídíò, Ayodeji Rotinwa ni ìròyìnn òfegè gbé àwòrán rẹ̀ síta pè dókítà tó ń pa àwọn Hausa mùsùlùmí

Buni bori ni Yobe

Alaga igbimọ afunṣọ ẹgbẹ oṣelu APC tẹlẹ, Mai Mala Buni lo bori fun aṣia ẹgbẹ oṣelu APC lati dije fun ipo gomina nipinlẹ naa.

Buni ni ibo marunlelẹgbẹrin ninu ẹgbẹrin ati aadọrun ibo, (890) to wa nilẹ.

Ko si ẹni to ba Buni du aṣia ẹgbẹ naa gẹgẹbi alaga igbimo alakoso ibo naa, Umar Lawan Kareto ṣe sọ.

Àkọlé fídíò, Oba Adedokun Abolarin ti Oke Ila: Ó ya ọ̀pọ̀ tó súnmọ́ mi lẹ́nu bí mo ṣe ń kọ́

Nwifuru firu yọ wọn nipinlẹ Ebonyi

Họnọrebu Ogbonna Nwifuru lo bori nipinlẹ Ebonyi pẹlu ibo ojilelẹẹdẹgbẹrin ati mẹta, (743)

Awọn oludije to ku ni Rosemary Okofe, Ucha Ali Julius, Edward Nkwegu, ati Elias Mbam.

Àkọlé fídíò, Amputee: Toheeb Abiodun Olaniyan: Ẹ̀rọ lílọ̀ ní ẹni ọdún mẹ́sàn án ni apa kan mi lọ sí

Matawalle gba Zamfara

Gomina Bello Matawalle lo bori ni ipinlẹ Zamfara.

Alaga igbimọ alakoso ibo abẹnu nipinlẹ Zamfara, Babagana Tijani kede matawalle pẹlu ibo ẹẹdẹgbẹrinle mẹtalelọgbọn.

Gomina Matawalle wọle lalailatako lẹyin ti gbogbo awọn to fẹ baa dije yọwọ kuro lawọ idije naa.

Àkọlé fídíò, Lasisi Jasper:Wo ìtàn ayé ọ̀gọ́ àgbà iléẹ̀kọ́ Adeniran Memorial ni Ogbomoso

Emenike gbegba oroke ni Abia

Oloye Ikechi Emenike ni awọn aṣojudibo yan nipinlẹ Abia lati gbe aṣia ẹgbẹ oṣelu APC lasiko idibo fun ipo gomina ti yoo waye lọdun 2023.

Àkọlé fídíò, 'Ọ̀pọ̀ ìgbà l'èmí gan fẹ́ du àwọn ipò òṣèlú kan, bíì '2015, 2019' àmọ́ mo tẹ 'slow' torí bàbà mi, Akala náà ń jáde'

Awọn meje ni wọn jumọ ra fọọmu idije fun ipo gomina ẹgbẹ oṣelu APC nibẹ ṣugbọn mẹta ninu awọn mẹfa yoku binu jade kuro nibudo idibo naa lori ẹhonu pe eto idibo boo roju mi oo rinu mi, Indirect process ni wọn lo fun idibo abẹnu naa.

Seneto Omo-agege

Oríṣun àwòrán, other

Sẹnetọ Ọmọ agege ni Delta.

Igbakeji aarẹ ileegbimọ aṣofin agba, Sẹnetọ Ovie Omo-Agege ni aṣia oludije ipo gomina ẹgbẹ oṣelu bọ si lọwọ ni ipinlẹ Delta.

Awọn ẹgbẹkan ati aadọwaa oludibo (1190) lo tẹka fun un.

Àkọlé fídíò, Tàá bá lè bá àwọn ọmọ tó pa Deborah ní Sokoto sọ̀rọ̀ pé ìwà ẹranko ni wọ́n hù, ó burú - Òṣèré Sokoti

Zulum ni APC fa kalẹ ni Borno

Gomina ipinlẹ Borno lọwọlọwọ, Ọjọgbọn Zulum ni awọn aṣojudibo fa kalẹ lẹẹkeji pẹlu ibẹ ẹgbẹrun kan ati irinwo o le mọkanla, (1411)

Gomina AA Sule

Oríṣun àwòrán, Governor nasarawa/ twitter

Nasarawa ati Sule

APC Nasarawa fa gomina ipinlẹ naa, Onimọ ẹrọ A.A. Sule kalẹ gẹgẹbi oludije wọn fun ipo gomina lasiko idibo apapọ ọdun 2023.

Gbogbo awọn aṣojudibo lati wọọdu mẹtadinlaadọjọ̀, 147 to wa kaakiri ijọba ibilẹ mẹtala ni ipinlẹ naa lo dibo fun gomina Sule.

Àkọlé fídíò, 'FUJI níkan ni ‘beat’ tó jẹ́ àṣà wa, ‘Highlife’ kìí ṣe tiwa, kò sóhun tó jọ pé àwọn ọmọ Sàtání ló ń kọ Fuji Gospel'

Inuwa Yahaya ni APC gbe ni Gombeapc

Gomina ipinlẹ Gombe lọwọlọwọ, Muhammadu Inuwa Yahaya lo bori.

Oun pẹlu ko latako lasiko idibo naa.

Àkọlé fídíò, Oromidayo Daniel: Mo tú gbogbo ilé Dayo bóya á máa rí ǹkan tó ṣokùnfà ikú rẹ̀ ṣùgbọ́n...