Nollywood, Yollywood: Tayo Sobola tí ọ̀pọ̀ mọ̀ sí Ṣótáyọ̀ Gaga ní wọ́n ti fi Òun jẹ ìyá Ọba ní Nasarawa

Tayọ Sobọla ti ọpọ mọ si Ṣotayọ Gaga

Oríṣun àwòrán, Sotayogaga/instagram

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 1

Ọpọ awọn ololufẹ gbajugbaja oṣere tiata Yoruba ni, Tayọ Sobọla ti ọpọ mọ si Ṣotayọ Gaga ni ko lee pa idunnu wọn mọra bayii.

Eyi ko ṣeyin igba ti eekan oṣere sinima naa kede loju opo Instagram rẹ ni ọjọ diẹ sẹyin pe wọn ti fi oun jẹ Iya oba ni ilu Uke ni ipinlẹ Nasarawa.

Sotayo Gaga ni Emir ti ilu Uke, Abdullah Hassan lo fi oun jẹ oye tuntun naa ni aafin rẹ.

Sotayo ni lede Hausa, orukọ oye naa ni Sarauniya to tumọ si iya ọba.

Igbesẹ nla lọpọ awọn ololufẹ rẹ ri eyi si nitori pe gẹgẹ bi awọn kan ninu wọn ṣe sọ ninu idahun wọn si atẹjade rẹ naa, o fihan pe awọn ara oke ọya pẹlu n gbadun iṣẹ ọwọ rẹ, wọn si mọ riri rẹ pẹlu.

Àkọlé fídíò, hhhhhh

Lara awọn to wa nibi ayẹyẹ naa ni Ambasadọ Sadiq Ibrahim atawọn eekan ọmọ ilu naa.

Aworan ajade Sotayo Gaga

Oríṣun àwòrán, Tsotayogaga/instagram/screenshot

Skip Instagram post
Allow Instagram content?

This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of Instagram post

Àkọlé fídíò, Akomolede ati Aṣa lori BBC Yoruba: Ẹ̀yà Ara Ifọ̀ ní olùkọ́ Adedokun kọ́ wa