Fete Gede: Wo àwọn èèyàn tó ń jí àwọn òkú láti bèèrè ààbò ẹ̀mí

Oríṣun àwòrán, Travel Noire
Airin jinna, lai ri abuke ọkẹrẹ, t'eeyan ba rin jinna, yoo ri ẹja to yarọ ninu ibu.
Awọn eeyan kan ma ree, ti wọn maa n ba oku sọrọ lọdọọdun fun aabo ẹmi, owo, ọmọ ati fawọn ipese nnkan miran.
Ọdun awọn to ti ku ti wọn maa n pe ni Fete Gede, jẹ ọkan lara ayẹyẹ to ṣe pataki julọ fawọn ẹlẹsin ibilẹ to n lo oogun dudu, ti wọn n pe ni Voodoo.
Àwọn ìtàn mánigbàgbé tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ọbasanjọ sọ àsírí sàgbàdèwe rẹ̀
- Jesu Oyingbo rèé, pásítọ̀ tó láṣẹ ìbálòpọ̀ lóri ọmọ ìjọ obìnrin
- Igbó mímu lè ṣe kóríyá, kò lé fi kún orín ẹnu òṣèré - 9ice
- Ìtàn tó wà nídi òwe ‘Sebótimọ Ẹlẹ́wà Sàpọ́n’
- Iṣọla Oyenusi rèé, ẹnití ìfẹ́ obìnrin ṣun dé ìwà ìdigunjalè
- Taiwo Akinkunmi, ọmọ Ibadan tó ya àsìá Naijiria
- Ayinla Ọmọwura, orin èébú àti oríyìn lo fi di ọ̀rẹ́ àwọ̀n obìnrin
Ayẹyẹ ọhun to maa n waye lọdọọdun, ni wọn ti maa n ṣe ajọyọ lori awọn ẹmi airi, awọn to wa lajule ọrun at'awọn oku lorilẹede.

Oríṣun àwòrán, Travel Noire
Ọdun naa ti wọn maa n ṣe lọjọ meji akọkọ ninu oṣu kọkanla, lawọn eeyan maa n lo lati wa agbara, abo ati ibaṣepọ ọtun pẹlu awọn oku.
Ọpọ eeyan lo maa n lo asiko yii lati ba awọn eeyan wọn to ti ku sọrọ, awọn ti wọn jọ ni asọti ọrọ papọ ki iku to mu wọn lọ.
N ṣe ni ẹmi awọn oku maa n ba le awọn eeyan lori nibi ajọdun naa.
Awọn ẹlẹsin ibilẹ to n lo oogun dudu Voodoo, to jẹ ọkan lara awọn ẹsin to ti wa nilẹ Afirika tipẹ, lo ni ajọdun yii.

Oríṣun àwòrán, Travel Noire
Ọpọ ninu awọn eeyan to n se ajọdun awọn oku yii, lo wa lati orilẹ-ede Benin, awọn mii wa lati iran Yoruba ni Naijiria, awọn kan lati Ghana, nigba ti awọn mii lati ẹkun ijọba Kongo.
Koda, awọn ẹlẹsin Kristẹni gan an maa n darapọ mawọn to n ṣe ajọdun yii lorilẹede Haiti.
Orilẹ-ede Haiti ni ẹsin yii ti bẹrẹ ati apa ilẹ Caribbean, nibi tawọn eeyan ti wọn ko lẹru lati iwọ oorun Afirika wa.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ọ̀pọ̀ Yorùbá kò fẹ́ àtúntò mọ́, wọ́n fẹ́ ká dá dúró ni, èrò tèmi nìkan kọ́ - Gani Adams
- Ọ̀gá iléèwé mẹ́ta wọ gàù lọ́dọ̀ ìjọba Ọsun torí ìpolongo ìdásílẹ̀ orílẹ̀-èdè Odùduwà
- Ọ̀fọ̀ ńlá ṣẹ̀! Iná sọ níléèwé, yàrá ìkàwé 22 jóná, akẹ́ẹ̀kọ́ 20 dèrò ọ̀run
- Á fojú Sunday Igboho balé ẹjọ́, á sì gba ₦500m owó ìtanràn fún Seriki - Ẹgbẹ́ Fulani
- Yorùbá sọ̀kò ọ̀rọ̀ sí Arewa lórí bó ṣe fẹ́ àtúntò Nàíjíríà àmọ́ tó tako pínpín ipò ààrẹ
- Ọ̀rọ̀ agọ̀ ni Dambazau sọ bó ṣe fi OPC wé Boko Haram - Àgbààgbà Yorùbá
- Ẹ̀ẹ̀mẹrin ni ọ̀dá owó já mi kulẹ̀ lásìkò tí mo fẹ́ wọ Fáṣítì - Biola Adebayo
- Kí ló pa òkú mẹ́jọ tí wọ́n bẹ́ lórí ní Calabar?
Fun ọpọ ọdun bayii, ẹsin Voodoo ti dapọ mọ ẹsin Kristẹni ati Musulumi.
Ajọdun Fete Gede bẹrẹ pẹlu awọn to maa n mura bi ẹmi airi ti wọn maa n pe ni Loas.

Oríṣun àwòrán, Travel Noire
Awọn mii maa n wọ aṣọ funfun, ti wọn o si maa jo lọ si oju saare ti wọn n sin oku, si pẹlu ẹbun ti wọn fẹ fun awọn oku.
Bakan naa ni wọn maa n gbe ounjẹ dani fawọn oku fun aabo wọn lori awọn alaaye.
- Ìtàn tó rọ̀ mọ́ òwe ‘aṣọ kò bá Ọ́mọ́yẹ mọ́...’ rèé
- Ọọ̀ni obìnrin, Lúwòó Gbàgídà rèé, akọni tó ń gun ọkùnrin ní ẹṣin rìn
- Ìtàn Ọba Yorùbá tí wọ́n yẹgi fún torí ó jí ọmọ gbé ṣe ètùtù
- Mọ̀ síi nípa Shina Rambo tó pàdé Jesu lọ́gbà ẹ̀wọn lẹ́yìn tó ti jalè
- Ogun Àgbẹ́kọ̀yà, ìjà òmìnira fáwọn àgbẹ̀ ni àbí ìfẹ̀míṣòfò?
- Irú èpè wo ni Aláàfin Aolẹ ṣẹ́ fún ìran Yorùbá?
Ajọdun yii maa n gba okun ati agbara awn to ba n se e nitori ẹmi awọn oku maa n gun wọn, ti ẹmi awọn oku naa yoo si dabi ti alaaye.
Ajọ̀dun awọn oku yii lo maa n se pẹki n pẹki pẹlu ayajọ ọjọ awọn oku ninu ẹsin Kristiẹni, ti wọn n pe ni All Saints Day.

Oríṣun àwòrán, Travel Noire
Wọn tun maa n fi ajọdun yii ṣe iranti Papa Gede, ẹni ti wọn gbagbọ pe oun lo kọkọ ku, ti o sí ṣaaju awọn oku miiran lọ si ilẹ tuntun tii ṣe ibugbe awọn oku.
Wọn tun maa n fi oríṣìíríṣìí nkan pa ara wọn to fi mọ fifi ata soju ara wọn, nigba ti akoko wọn ba to lati fawọn oku ni ẹbun.
Awọn eeyan tun maa n lo ajọdun Fete Gede lati beere fun owo, ẹmi gigun, ọmọ ati abo lọwọ awọn ẹmi airi.
















