General Overseer arrested for drugs: NDLEA fi àlùfáà ìjọ tó gbé egbògi olóró sí àhámọ́

Oríṣun àwòrán, Others
Àjọ tó ń gbógunti lílo egbògi olóró ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, NDLEA ti nawọ́ gán àlùfáà àti olùdásílẹ̀ ilé ìjọsìn Christ Living Hope Church, Ugochukwu Emmanuel fẹ́sùn gbígbé egbògi olóró "cocaine".
Nínú àtẹ̀jáde kan tí agbẹnusọ àjọ NDLEA, Femi Babafemi fi léde lọ́jọ́ Àìkú ọjọ́ kejìlá, oṣù kẹta, ọdún 2022 ní pápákọ̀ òfurufú Muritala Muhammed International Airport ni ọwọ́ ti tẹ olórí ìjọ náà.
Babafemi ní ọwọ́ tẹ̀ Ugochukwu ní ọjọ́ Ajé tó kọjá nígbà tó fẹ́ wọ bàálù lọ sí orílẹ̀ èdè Kenya láti lọ kópa níbi ètò ìsọjí ọlọ́sẹ̀ mẹ́ta ní Nairobi.
Ó ṣàlàyé pé nígbà tí àwọn ń ṣe àyẹ̀wò fún àwọn tó fẹ́ wọ bàálù ni àwọn bá egògi tí àlúfàá náà sọ mọ ara lọ́nà mẹ́rìnléláàdọ́ta káàkiri ara rẹ̀.
Ó fi kun pé Ugochukwu, nígbà tí àwọn ń fi ọ̀rọ̀ wa lẹ́nu wò jẹ́wọ́ pé níbi ètò ìsọjí tí òun ń lọ ní Nairobi fún ọ̀sẹ̀ mẹ́ta náà ni òun ti fẹ́ lo àwọn egbògi náà.
- Tẹ̀gbọ́n tàbúrò jí ọmọ ará àdúgbò gbé láti gbowó, àmọ́ wọn fún ní òògùn eku jẹ
- Ọmọdé méje kú, ọ̀pọ̀ farapa nígbà tí ọ̀rọ̀ di bóòlọ, ko yàgò fún mí
- Portable Zazzu pariwo pe wọ́n ti dá ọjọ́ méje pé òun yóò kú
- Wo ọmọ Yorùbá mẹ́ta àti gbajúmọ̀ míì tó ní Lupus, àrùn tó n bá Kemi Afolabi fínra
- Malami pahùndà lórí ọ̀rọ̀ Kyari, ó ní kò jẹbi ẹ̀sùn kíkówó pamọ́
- "Èèdì àti ogun ayé ni awọn èèyàn n rò pé ó mú mi bí ìbejì ní ìgbà mẹ́fà"
- Ìjàmbá ọkọ̀ tún gbẹ̀mí ènìyàn mẹ́tàlá ní òpópónà márosẹ̀ Ilorin sí Ogbomoso
- Wo àwọn nǹkan tó le fa lupus - àìsàn tó ń bá Kemi Afolabi fínra
- Ṣé lóòtọ́ ni wọ́n bá ọmọdé nínú àpótí ọlọ́kadà "dispatch rider" l'Ekoo?
- Díẹ̀ lára àwọn òṣèré Nollywood ti wọ́n ti ṣe ìgbéyàwó lẹ́ẹ̀kejì
Ní ìlú Isuaniocha, òpópónà Mgbakwu, Awka, ìjọba ìbílẹ̀ Árìwá Akwa, ìpínlẹ̀ ni olú ilé ìjọsìn Christ Living Hope Church wà.
Bákan náà ni wọ́n ní ẹ̀ka ní ìlú Abuja àti ìpínlẹ̀ Eko.














