Yoruba World Centre: Ìdíje fún sísọ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ Yorùbá nílé ẹ̀kọ́ girama dí "Millionaire" lọ́dọọdún gbéra sọ

Yoruba

Oríṣun àwòrán, @YWC

Idije koriya fun awọn ọmọ ilẹ Oodua to n ṣo ede Yoruba daadaa bẹrẹ.

Ọpọlọpọ owo lo ti wa nilẹ ti yoo sọ awọn akẹkọọ Yoruba di ọlọla lawujọ.

Ní oṣù kẹrin ọdún yìí ni àjọ Yorùbá ní àgbáyé (Yoruba World Centre) yóò bẹ̀rẹ̀ ìdíje láàárín àwọn akẹ́kọ̀ọ́ Yorùbá ní àwọn ìpínlẹ̀ ẹkùn Ìwọ̀ Oòrùn orílẹ̀ èdè yìí, ìpínlẹ̀ Kwara àti Kogi.

Ìdíje náà tí wọ́n pe àkòrí rẹ̀ ní "Àkókò láti gba àwọn ọ̀dọ́ wa padà" jẹ́ ọ̀nà láti pèsè ààyè fún àwọn akẹ́kọ̀ọ́ láti jẹ̀bùn owó àti àwọn nǹkan mìíràn pẹ̀lú bí wọ́n ṣe ń kẹ́kọ̀ọ́.

Awọn wo lo n ṣe agbatẹru eto idagbasoke ede Yoruba naa?

Àwọn aláṣẹ àjọ náà ló kéde ọ̀rọ̀ ọ̀hún nìbi ìpàdé wọn kan pẹ̀lú àwọn adarí Ẹgbẹ́ Akọ́mọlédè ilẹ̀ Nàìjíríà níbi tí gbogbo àwọn alága wọn káàkiri Nàìjíríà péjú pésẹ̀ sí.

Àkọlé fídíò, Ipaniyan Ogun

Alákoso àjọ Yorùbá World Centre, ọ̀gbẹ́ni Alao Adedayo ní ìdíje náà yóò wáyé pẹ̀lú àjọṣepọ̀ ilé iṣẹ́ Odu'a Investment Company Plc. àti DAWN Commission.

Àkọlé fídíò, Cancer: Àṣe ara mi ni iso ti n run gbogbo bí mo ṣe n ṣèrànwọ́ lórí jẹjẹrẹ

Adedayo ní àwọn ti rí àṣẹ gbà lọ́dọ̀ Mínísítà fún ètò ẹ̀kọ́ àti àwọn ìjọba ìpínlẹ̀ ẹkùn Ìwọ̀ Oòrùn orílẹ̀ èdè yìí àti Kwara láti tẹ̀síwájú pẹ̀lú ìdíje náà.

Ó ní ìjọba ìbílẹ̀ ní ìdíje náà yóò ti gbérasọ kó tó bọ́ sí ipele ìjọba ìpínlẹ̀ kó tó kan ipele àṣekágbá.

Àkọlé fídíò, Omi Daji: Odò tó dédé sàn jáde tí kìí gbẹ tòjò tẹ̀ẹ̀rùn, wọn kìí pa tàbí jẹ ẹja inú rẹ̀

Kini Osinbajo ti kọkọ kede ṣaaju?

Ẹ ó rántí pé nínú oṣù kọkànlá ọdún tó kọjá ni igbákejì Ààrẹ orílẹ̀ èdè yìí, ọ̀jọ́gbọ́n Yemi Osinbajo ṣe ìfilọ́lẹ̀ Yorùbá World Centre, tó jẹ́ àkànṣe ètò International Centre for Yoruba Arts and Culture.

Àkọlé fídíò, Akàwégboyè alákàrà

Adedayo ṣèrántí pé lára àfojúsùn àjọ náà ni bí àṣà, ìṣe àti ìgbàgbọ́ tó ti ń bọ́ sọnù lára àwọn ọ̀dọ́ ìwòyí yóò ṣe jẹ́ dídá padà.

Àkọlé fídíò, Ikere Ekiti: Olúkẹ̀ẹ́rẹ́ àti Ògògà tako ara wọn lórí ẹni tíí ṣe aláṣẹ ilú Ikere

Se 2022 nikan ni eto yii yoo waye?

Adadayo wòye pé ìdíje ọlọ́dọọdún yìí yóò jẹ́ ọ̀nà láti tọ́ àwọn ọ̀dọ́ sọ́nà kí ó sì mú ọjọ́ ọ̀la dúró ire pàápàá nípa kíkọ́ nípa ìtàn, àṣà, ìṣe àti èdè Yorùbá.

Àkọlé fídíò, Adebisi Idikan: Òun ló gba Ìbàdàn sílẹ̀ lọ́wọ́ ìyà owó orí sísan

Bákan náà ló ní yóò jẹ́ ọ̀nà láti mú ìgbéga bá àṣà àti èdè Yorùbá bí ìmọ̀ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ yóò ṣe máa lékún síi tí èdè Yorùbá kò sì ní lè parun láéláé.