9ice Marriage: Ẹ ba mi bẹ ìyàwó mi, òun ni igi lẹ́yìn ọgbà mi

Oríṣun àwòrán, 9iceofficial
Gbajugbaja olorin takasufe, Alexander Abolore Adegbola Akande, ti ọpọ eeyan mọ si 9ice ti ke gbajare si awọn ọmọ Naijiria lati ba a bẹ iyawo rẹ ki igbeyawo rẹ ma baa fori sogi.
9ice lo n rawọ ẹbẹ si awọn ololufẹ rẹ bẹẹ ninu fidio kan to fi lede loju opo Instagram rẹ ni irọlẹ ọjọ Abamẹta.
O ni "mo ti ṣe ohun itiju ati ohun to buru jai eyii to fẹ tu ẹbi mi ka."
- Àwọn ìwàásù akọnilẹ́nu hàà tí Prophet Israel Oladele CCC Genesis Global ti ṣe rèé
- Báàgì Ghana Must Go pàwọ̀dà, ó di ohun táwọn ránsọ ránsọ fi ń dárà orísirísi
- Wòlíì míì, tún wọ gàù lẹ́yìn tó tàpá sí ìlànà béèlì tí wọ́n fún un nílé ẹjọ́
- Ṣé Sanwo-Olu, gómìnà Eko yóò farahàn níwájí ìgbìmọ̀ olùwádìí ìṣẹ̀lẹ̀ Lekki Tollgate?
Abolore tẹsiwaju pe oun ko jẹ ohun kankan lai si iyawo oun nitori ọla obinrin naa ni oun jẹ.

Oríṣun àwòrán, 9iceofficial
O ṣalaye pe "Mo tọrọ aforiji lọwọ iyawo mi fun ohun ti mo ṣe, bẹẹ ni mo nilo iranlọwọ yin lati bẹ iyawo mi fun aṣiṣẹ nla yii nitori oun ni igi lẹyin ọgba mi."
Gẹgẹ bo ṣe sọ, o ni oun ti ṣe ọpọlọpọ aṣeyọri nile aye, ṣugbọn oun ko ṣe daadaa to ninu gbeyawo oun.
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post
- Wo àwọn èèkàn, ìlúmọ̀ọ́ka olórin tó ṣàbẹ̀wò sí ijọ Celestial Church ti Genesis Global
- A kò tíì lè sọ pé ọmọ Ọba tuntun ni yóò jẹ Ooni lọ́jọ́ iwájú - Elebuibọn
- Èyí ni bí wọ́n ṣe pín fásitì LAUTECH láàrín ìpínlẹ̀ Oyo àti Osun
- Ọkùnrin tó pe ìyàwó rẹ̀ lájẹ̀ẹ́ tì í mọ́lé fọ́dún mẹ́rin, fún un lóyún nígbà mẹ́ta!
9ice sọ pe bo tilẹ jẹ pe oun ti ṣe ọpọ aṣiṣe, ṣugbọn oun nilo iranlọwọ awọn ọmọ Naijiria lati ba oun bẹ iyawo oun ki igbeyawo naa ma baa tuka.
Bo tilẹ jẹ pe 9ice ko sọ irufẹ ẹṣẹ to ṣẹ iyawo rẹ, eyii to fa ṣabababi ẹbẹ to n bẹ, ṣugbọn awọn eeyan kan ti n ṣo pe ko le e ṣeyin fidio to lu jade lori ayelujara laipẹ yii, eyi to ṣafihan bo ṣe gba obinrin kan mu nigba aya.
Ọpọ eeyan lo gbagbọ pe olorin ọhun kundun obinrin lẹyin ti obinrin mẹta ọtọtọ ti bi ọmọ marun un fun un ko to fẹ iyawo rẹ, Olasunkanmi Akande.
- CCC Genesis Global: Ǹkan mẹ́wàá tí ẹ ò gbọ́ rí nípa Israel Oladele, Woli ìjọ Genesis Global
- DSS ṣèlérí iwadìí tí kò rújú lórí bí òṣìṣẹ́ rẹ̀ kan ṣe yìnbọn pa fẹ́ńdọ̀ lẹ̀yìn Gbajabiamila
- Saka ń wá ọ̀rẹ́ rẹ̀ kan nítorí aṣọ kóòtù ọdún 34 sẹ́yìn
- Bàbá mi, ẹ yé fi mí gba ìràwọ̀, ọmọbìnrin Charly Boy, Dewy Oputa fárígá fún bàbá rẹ̀













