Cyber Crime: Báwo ni ìyá kan ṣe rí ẹ̀wọ̀n ọdún márùn-ún he nítorí ọmọ?

Oríṣun àwòrán, EFCC
Ile ẹjọ́ gíga ìjọba àpapọ̀ tó wà ní ìlú Benin, ní ìpínlẹ̀ Edo ti sọ arábìnrin kan, Debest Osarumwense sí ẹ̀wọ̀n ọdún márùn-ún.
Debest Osarumwense ni ìyá ọmọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Endurance Osarumwense, tí ọ̀pọ̀ mọ̀ sí Yahoo boy, eyiun afurasi oníjìbìtì lórí ẹ̀rọ ayélujára.
Onídàjọ́ M. S. Shuaibu, nígbà tó ń gbé ìdájọ́ rẹ̀ kalẹ̀ ní obìnrin náà jẹ̀bi ẹ̀sùn tí wọ́n fi kàn-án wí pé ó gba owó tó lé ní mílíọ́nù lọ́nà mọ́kànléláàdọ́rùn-ún náírà (N91m) lọ́wọ́ ọmọ náà.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ìbọn kò ran Tommy, làwọn afurasí ẹlẹ́gbẹ́ òkùnkùn bá fi àdá ṣa pa - Óṣojúmikòró
- Iléèṣẹ́ aṣojú America bẹ̀rẹ ètò físà fún àwọn ọmọ Naijiria láì ṣe ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò
- Kí ló pa dókítà àjọ FIFA tó kú níbí ìdíje Ghana vs Nigeria ní Abuja? Àjọ NFF sọ̀rọ̀
- Portable Zazzu pàdánù eré tó yẹ kó lọ ṣe ní Canada, ìdí rèé
- Ẹ wo orúkọ àti ojú àwọn èèkànlú tó forí sọta ìkọlù rélùwéè àti ipò tí wọn dì mú
- Adájọ́ gbé ìdájọ́ kalẹ̀ lórí ẹ̀bẹ̀ Rahmon Adedoyin tó ní òun kò ní ẹjọ́ láti jẹ́
- Aráàlú bínú tán l‘Okeho, wọ́n ti iléeṣẹ́ amúnáwá pa torí ségesège iná ọba
Owó yìí ni wọ́n ní ó jẹ́ lára owó jìbìtì tí ọmọ náà lù lórí ayélujára.
Ilé ẹjọ́ wà ju obìnrin náà sẹ́wọ̀n, nígbà tí òun náà gbà pé òun jẹ̀bi ẹ̀sùn tí wọ́n fi kan òun.
Àjọ tó ń gbógunti ìwà àjẹbánu ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, EFCC ló wọ́ ìyá náà lọ sí ilé ẹjọ́ fẹ́sùn wí pé ó ń da aṣọ bo ọmọ rẹ̀ lórí lórí ìwà jìbìtì tí ó ń wù.

Oríṣun àwòrán, EFCC













